< John 1 >

1 In [the] beginning was the Word, and the Word was with God, and God was the Word.
Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
2 He was in [the] beginning with God.
Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
3 All things through Him came into being, and without Him came into being not even one [thing] that has come into being.
Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
4 In Him life was, and the life was the light of men,
Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
5 And the Light in the darkness shines, and the darkness it not grasped [it].
ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
6 There came a man sent from God, [the] name to Him [was] John.
Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
7 He came as a witness that he may testify concerning the Light, that all may believe through him.
Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
8 Not was He the Light, but that he may witness concerning the Light.
Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
9 Was the Light true who enlightens every man coming into the world.
Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
10 In the world He was, and the world through Him came into being, and the world Him not knew.
Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
11 To [His] own He came, and [His] own Him not received.
Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
12 As many as however received Him, He gave to them authority children of God to be, to those believing in the name of Him,
Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
13 who not [born] of blood nor [born] of will of flesh nor [born] of will of man but of God were born.
Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
14 And the Word flesh became and He dwelt among us, and we beheld the glory of Him, a glory as of an only begotten from [the] Father, full of grace and truth.
Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
15 John witnesses concerning Him and he has cried out saying; This was He (of whom I was saying; *NK+o) The [One] after me coming precedence over me has, because before me He was.’
Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
16 (For *N+KO) from the fullness of Him we ourselves all have received then grace for grace.
Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
17 For the law through Moses was given, grace and truth through Jesus Christ came.
Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
18 God no [one] has seen ever yet; (the *ko) only begotten (God *N+KO) who is being in the bosom of the Father, He has made [Him] known.
Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
19 And this is the testimony of John when sent (to him *no) the Jews from Jerusalem priests and Levites that they may ask him; You yourself who are?
Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
20 And he confessed and not denied but confessed that I myself not am the Christ.
Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
21 And they asked him; What then? You yourself Elijah are And he says; Not I am. The prophet are you yourself? And he answered; No.
Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
22 They said therefore to him; Who are you? That an answer we may give to those having sent us; what say you about yourself?
Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
23 He was saying; I myself [am] a voice crying in the wilderness; do make straight the way of [the] Lord; even as said Isaiah the prophet.
Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
24 And (those *k) sent were out from the Pharisees
Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
25 And they asked him and they said to him; Why then baptize you if you yourself not are the Christ (nor *N+kO) Elijah (nor *N+kO) the prophet?
bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
26 Answered them John saying; I myself baptize with water; [in the] midst (now *k) of you (he has stood *NK+o) whom you yourselves not know,
Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
27 (he himself is *k) the [One] after me coming, (who before me has been; *K) of whom not am I myself worthy that I may untie of Him the strap of the sandal.
Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
28 These things in (Bethany *N+kO) took place across the Jordan where was John baptizing.
Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
29 On the next day he sees (John *k) Jesus coming to him and says; Behold the Lamb of God, who is taking away the sin of the world.
Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
30 He it is (concerning *N+kO) whom I myself said; After me comes a man who precedence over me has because before me He was.
Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
31 And I myself And I myself not knew Him, but that He may be revealed to Israel, because of this came I myself with water baptizing.
Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
32 And bore witness John saying that I have beheld the Spirit descending (as *N+kO) a dove out of heaven, and it remained upon Him.
Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
33 And I myself And I myself not knew Him, but the [One] having sent me to baptize with water, He to me said; Upon whom maybe you may see the Spirit descending and abiding on Him, He is the [One] baptizing with [the] Spirit Holy.
Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
34 And I myself And I myself have seen and have borne witness that this is the (Son *NK+O) of God.
Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
35 On the next day again had stood John and of the disciples of him two.
Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
36 And having looked at Jesus walking he says; Behold the Lamb of God!
Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
37 And heard the two disciples of Him [Him] speaking and they followed Jesus.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
38 Having turned then Jesus and having beheld them following He says to them; What seek you? And they said to Him; Rabbi which is to say (meaning *N+kO) Teacher — where are You staying?
Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
39 He says to them; do come and (you will behold. *N+kO) They went (therefore *NO) and saw where He abides, and with Him they stayed the day that; [The] hour (now *k) was about [the] tenth.
Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
40 Was Andrew the brother of Simon Peter one of the two which having heard from John and having followed Him.
Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
41 Finds he (first *N+kO) the brother [his] own Simon and he says to him; We have found the Messiah, which is being translated Christ.
Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
42 (and *k) He led him to Jesus. Having looked at (now *k) him Jesus said; You yourself are Simon the son (of John; *N+KO) You yourself will be called Cephas which means Peter.
Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
43 On the next day He desired to go forth into Galilee And He finds Philip And says to him Jesus; do follow Me.
Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
44 Was now Philip from Bethsaida, from the city of Andrew and Peter.
Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
45 Finds Philip Nathanael and says to him; [Him] whom wrote of Moses in the Law also the prophets, we have found, Jesus son of Joseph of Nazareth.
Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
46 And said to him Nathanael; Out of Nazareth is able any good thing to be? Says to him Philip; do come and do see.
Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
47 Saw Jesus Nathanael coming to Him and He says concerning him; Behold truly an Israelite in whom deceit not there is.
Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
48 Says to Him Nathanael; From where me know You? Answered Jesus and said to him; Before you Philip calling being under the fig tree I saw you.
Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
49 Answered to him Nathanael (and says: *k) Rabbi, You yourself are the Son of God, You yourself King are of Israel.
Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
50 Answered Jesus and said to him; Because I said to you (that *no) I saw you under the fig tree, believe you? Greater things than these You will see.
Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
51 And He says to him; Amen Amen I say to all of you (from now *K) you will behold the heaven having opened and the angels of God ascending and descending on the Son of Man.
Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”

< John 1 >