< Psalms 5 >

1 To the Chief Musician. For the Flutes. A Melody of David. To my words, give ear, O Yahweh, Understand thou my softly murmured prayer:
Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi. Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa, kíyèsi àròyé mi.
2 Attend to the voice of my cry, my King and my God, for, unto thee, do I pray.
Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́, ọba mi àti Ọlọ́run mi, nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.
3 O Yahweh! in the morning, shalt thou hear my voice, In the morning, will I set in order unto thee, and keep watch;
Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi; ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀ èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
4 For, not a GOD finding pleasure in lawlessness, art thou, and wrong can be no guest of thine:
Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú; bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
5 Boasters, shall not station themselves, before thine eyes, —Thou hatest all workers of iniquity:
Àwọn agbéraga kò le è dúró níwájú rẹ̀. Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;
6 Thou wilt destroy them who speak falsehood, —The man of bloodshed and of deceit, Yahweh abhorreth.
ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run. Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn ni Olúwa yóò kórìíra.
7 But, I, in the abounding of thy lovingkindness, will enter thy house, I will bow down towards thy holy temple, in reverence of thee:
Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀, èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀; ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.
8 O Yahweh! lead me in thy righteousness, because of mine adversaries, Make even, before me, thy way:
Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi, mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.
9 For in his mouth is nothing worthy of trust, Their inward purpose, is engulphing ruin, —An opened sepulchre, is their throat, With their tongue, speak they smooth things.
Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́; ọkàn wọn kún fún ìparun. Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀; pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
10 Declare them guilty, O God, Let them fall by their own counsels, —Into the throng of their own transgressions, thrust them down, For they have rebelled against thee: —
Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run! Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn. Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
11 That all may rejoice who seek refuge in thee, to times age-abiding, may shout in triumph, that thou wilt protect them, and they may leap for joy in thee who are lovers of thy Name.
Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀; jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí. Tan ààbò rẹ sórí wọn, àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.
12 For, thou, wilt bless the righteous man, O Yahweh, As with an all-covering shield—with good pleasure, wilt thou encompass him.
Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo; ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.

< Psalms 5 >