< Numbers 23 >

1 Then said Balaam unto Balak: Build me here seven altars, —and prepare me here, seven bullocks and seven rams.
Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
2 And Balak did as Balaam had spoken, —and Balak and Balaam caused to ascend a bullock and a ram on each altar.
Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
3 Then said Balaam unto Balak: Station thyself by thine ascending-sacrifice, and let me go my way—peradventure Yahweh may come and meet me, and what thing soever he may show me, I will tell thee. So he went his way to a bare height.
Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
4 And God came unto Balaam, —so he said unto him The seven altars, have I built in a row, and have caused to ascend, bullock and a ram on each altar.
Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
5 And Yahweh put a word into the mouth of Balaam, —and said—Return unto Balak, and, thus, shalt thou speak.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
6 So he returned unto him, and lo! he was stationed by his ascending-sacrifice, —he, and all the princes of Moab.
Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
7 So he took up his parable and said, —From Aram, doth Balak conduct me, The king of Moab, from the mountains of the East, Come thou! curse me Jacob, Yea, come thou! rage on Israel.
Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
8 How can I revile one whom GOD hath not reviled? Yea, how can I rage on one on whom Yahweh hath not raged?
Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
9 Surely from the head of the rocks, do I see him, Yea, from the hills, do I observe him, —Lo! a people, who alone doth dwell, And among the nations, he doth not reckon himself.
Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
10 Who hath counted the dust of Jacob? Or who hath numbered the fourth part of Israel? Let me die the death of the upright, And let my hereafter be like his!
Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
11 Then said Balak unto Balaam, What hast thou done for me? To revile mine enemies, I summoned thee, and lo! thou hast kept on blessing.
Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
12 And he answered and said, —Was it not to be so that whatsoever Yahweh should put into my mouth, the same, should I take heed to speak?
Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
13 Then said Balak unto him—Come, I pray thee, with me unto another place, from whence thou mayest see him, nothing but his utmost part, shalt thou see, but all of him, shalt thou not see, —and so revile me him from thence.
Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
14 And he took him to the field of Zophim, unto the head of Pisgah, —and built seven altars, and caused to ascend a bullock and a ram on each altar.
Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
15 Then said he to Balak, Station thyself here by thine ascending-sacrifice, —while, I, meet him yonder.
Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
16 And Yahweh met Balaam, and put a word into his mouth, —and said—Return unto Balak and thus shalt thou speak.
Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
17 So he came in unto him and, there he was-stationed by his ascending-sacrifice, and the princes of Moab with him. And Balak said unto him, What hath Yahweh spoken?
Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
18 Then took he up his parable and said, —Rise, Balak, and hear, Give ear unto me son of Zippor!
Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
19 GOD is, not a man, that he should lie, Nor a son of Adam, that he should repent, —Hath, he, said, and will not perform? Yea spoken, and will not make it stand fast?
Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
20 Lo! to bless, have I received [command], —And I will bless, nor will I take it back.
Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
21 He hath not discovered trouble in Jacob, Neither hath he seen wretchedness in Israel, —Yahweh, his God, is with him, And, the acclaim of a king, in his midst:
“Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
22 GOD having brought them forth out of Egypt, The very horns of the buffalo, are his:
Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
23 Surely, there is no enchantment against Jacob, Nor divination against Israel, —Now, shall it be said—Of Jacob and of Israel, What hath GOD wrought!
Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
24 Lo, a people, like a lioness, shall rise, And like a strong lion, shall rouse himself up; He will not lie down till he eat the torn, And the blood of the slain, he drink.
Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
25 Then said Balak unto Balaam, Thou shalt neither revile, him, —nor bless him.
Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
26 And Balaam responded, and said unto Balak, —Spake I not unto thee, saying, All that Yahweh shall speak, that, must I do?
Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
27 And Balak said unto Balaam, Come, I pray thee! let me take thee unto another place, —peradventure, it may be right in the eyes of God, that thou revile me him. from thence.
Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
28 So Balak took Balaam, —unto the head of Peor, that looketh over the face of the Jeshimon.
Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
29 And Balaam said unto Balak, Build me here, seven altars, —and prepare me here, seven bullocks and seven rams.
Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
30 And Balak did as Balaam said, —and caused to ascend a bullock and a ram on each altar.
Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.

< Numbers 23 >