< Job 30 >

1 But, now, they who are of fewer days than I, have poured derision upon me; whose fathers I refused—to set with the dogs of my flock.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
2 Even the strength of their hands, wherefore was it mine? Upon them, vigour was lost;
Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
3 In want and hunger, they were lean, —who used to gnaw the dry ground, a dark night of desolation!
Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
4 Who used to pluck off the mallow by the bushes, with the root of the broom for their food;
Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
5 Out of the midst, were they driven, men shouted after them, as after a thief;
A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
6 In the fissures, of the ravines had they to dwell, in holes of dust and crags;
A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
7 Among the bushes, used they to shriek, Under the bramble, were they huddled together:
Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
8 Sons of the base, yea sons of the nameless, they were scourged out of the land.
Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
9 But, now, their song, have I become, Yea I serve them for a byword;
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
10 They abhor me—have put themselves far from me, and, from my face, have not withheld—spittle!
Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
11 Because, my girdle, he had loosened and had humbled me, therefore, the bridle—in my presence, cast they off;
Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
12 On my right hand, the young brood rose up, —My feet, they thrust aside, and cast up against me their earthworks of destruction;
Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
13 They brake up my path, —My engulfing ruin, they helped forward, unaided;
Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
14 As through a wide breach, came they on, with a crashing noise, they rolled themselves along.
Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
15 There are turned upon me terrors, —Chased away as with a wind, is mine abundance, and, as a cloud, hath passed away my prosperity.
Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
16 Now, therefore, over myself, my soul poureth itself out, There seize me days of affliction:
“Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
17 Night, boreth, my bones, all over me, —and, my sinews, find no rest;
Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
18 Most effectually, is my skin disfigured, —Like the collar of my tunic, it girdeth me about:
Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
19 He hath cast me into the mire, and I have become like dust and ashes.
Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
20 I cry out for help unto thee, and thou dost not answer, I stand still, and thou dost gaze at me;
“Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
21 Thou art turned to become a cruel one unto me, With the might of thy hand, thou assailest me;
Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
22 Thou liftest up me to the wind, thou carriest me away, and the storm maketh me faint;
Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
23 For I know that, unto death, thou wilt bring me back, even unto the house of meeting for every one living.
Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
24 Only, against a heap of ruins, will one not thrust a hand! Surely, when one is in calamity—for that very reason, is there an outcry for help.
“Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
25 Verily I wept, for him whose lot was hard, Grieved was my soul, for the needy.
Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
26 Surely, for good, I looked, but there came in evil, And I waited for light, but there came in darkness;
Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
27 I boiled within me, and rested not, There confronted me—days of affliction;
Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
28 In gloom, I walked along, without sun, I arose—in the convocation, I cried out for help;
Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
29 A brother, became I to the brutes that howl, and a companion to the birds that screech:
Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
30 My skin, turned black, and peeled off me, and, my bones, burned with heat:
Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
31 Thus is attuned to mourning—my lyre, and my flute, to the noise of them who weep.
Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.

< Job 30 >