< Esther 2 >

1 After these things, when the wrath of King Ahasuerus was appeased, he remembered Vashti, and what she had done, and what was decreed against her.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Ahaswerusi ọba sì dáwọ́ ìbínú un rẹ̀ dúró, ó rántí i Faṣti àti ohun tí ó ti ṣe àti àṣẹ tí ó pa nípa tirẹ̀.
2 Then said the young men of the king, who waited upon him, —Let them seek out for the king young virgins, of pleasing appearance;
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ ọba tí ó wà ní ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a wá ọmọbìnrin arẹwà tí kò ì ti mọ ọkùnrin rí fún ọba.
3 and let the king appoint officers throughout all the provinces of his kingdom, and let them gather together every young virgin of pleasing appearance unto Shusan the palace, unto the house of the women, into the custody of Hegai eunuch of the king, keeper of the women, and let there be given the things needed for their purification;
Àti pé kí ọba kí ó yan àwọn aláṣẹ ní gbogbo agbègbè ilẹ̀ ọba láti kó gbogbo àwọn arẹwà ọmọbìnrin wọ̀nyí jọ sí ilé àwọn obìnrin ní ilé ìṣọ́ Susa. Kí a kó wọn fún ìtọ́jú Hegai, ìwẹ̀fà ọba, ẹni tí ó ṣe olùtọ́jú àwọn obìnrin; kí a ṣe ìtọ́jú u wọn dáradára.
4 and, the maiden that is pleasing in the eyes of the king, let her be queen instead of Vashti. And the thing seemed good in the eyes of the king, and he did so.
Nígbà náà kí ọmọbìnrin tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn kí ó jẹ́ ayaba dípò Faṣti.” Ìmọ̀ràn yìí tẹ́ ọba lọ́rùn, ó sì tẹ̀lé e.
5 A certain Jew, there was, in Shusan the palace, —whose, name, was Mordecai, son of Jair, son of Shimei, son of Kish, a man of Benjamin;
Ó sì ṣe ní ìgbà náà ará a Júù kan wà ní ilé ìṣọ́ ti Susa, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mordekai ọmọ Jairi, ọmọ Ṣimei, ọmọ Kiṣi, ẹ̀yà Benjamini,
6 who had been exiled from Jerusalem, with the exiles who were carried away with Jeconiah king of Judah, —whom, Nebuchadnezzar king of Babylon, exiled.
ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti gbé lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu, lára àwọn tí wọ́n kó ní ìgbèkùn pẹ̀lú ọba Jekoniah ọba Juda.
7 And it came to pass, that he was bringing up Hadassah, the same, was Esther, his uncle’s daughter, for she had neither father nor mother, —and, the maiden, was of beautiful form and pleasing appearance, and when her father and mother died, Mordecai took her for his own daughter.
Mordekai ní arákùnrin kan ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Hadassa, ẹni tí ó tọ́ dàgbà nítorí tí kò ní baba bẹ́ẹ̀ sì ni kò ní ìyá. Obìnrin yìí, ẹni tí a tún mọ̀ sí Esteri, ó dára ó sì lẹ́wà, Mordekai mú u gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ nígbà tí baba àti ìyá rẹ̀ ti kú.
8 So it came to pass, when the king’s command and decree was heard, and there had been gathered together many maidens unto Shusan the palace, unto the custody of Hegai, that Esther was taken into the house of the king, unto the custody of Hegai, keeper of the women;
Nígbà tí a ti kéde òfin àti àṣẹ ọba, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọbìnrin ni a kó wá sí ilé ti ìṣọ́ Susa, sí abẹ́ ìtọ́jú Hegai. A sì mú Esteri náà wá sí ààfin ọba pẹ̀lú, a fà á lé Hegai lọ́wọ́, ẹni tí ó jẹ́ alábojútó ilé àwọn obìnrin.
9 and the maiden was pleasing in his eyes, and she received lovingkindness before him, and he hastened to give her, the things needed for her purification, and things apportioned her, and to give her, seven select maidens, out of the house of the king, —and he removed her and her maidens to the best place in the house of the women.
Ọmọbìnrin náà sì wù ú, ó sì rí ojúrere rẹ̀, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ó pèsè àwọn ohun tí ó dára àti oúnjẹ pàtàkì fún un. Ó sì yan àwọn ìránṣẹ́bìnrin wúńdíá méje láti ààfin ọba òun àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà lọ sí ibi tí ó dára jù nínú ilé àwọn obìnrin.
10 Esther had not told of her people, nor of her kindred, —for, Mordecai, had laid charge upon her, that she should not tell.
Esteri kò tí ì sọ nípa àwọn ènìyàn àti ìdílé e rẹ̀, nítorí Mordekai ti pàṣẹ fún un pé kí ó má ṣe sọ ọ́.
11 And, throughout every day, Mordecai, used to walk to and fro, before the court of the house of the women, —to get to know the welfare of Esther, and what would be done with her.
Ní ojoojúmọ́ ni Mordekai máa ń rìn ní iwájú ilé àwọn obìnrin láti wo bí Esteri ṣe wà ní àlàáfíà àti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.
12 Now, when the turn of each maiden came, to go in unto King Ahasuerus, after it had been done to her according to the law of the women for twelve months, for, so, were filled the days of their purification, —six months with oil of myrrh, and six months with perfumes, and with things for the purification of the women,
Kí àkókò tó tó fún obìnrin kọ̀ọ̀kan láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Ahaswerusi, ó ní láti lo ohun èlò tí ń mú ara lẹ́wà tí a yàn fún àwọn obìnrin fún oṣù méjìlá, yóò lo òróró òjìá fún oṣù mẹ́fà, yóò sì lo ohun èlò olóòórùn dídùn tùràrí àti ìpara fún oṣù mẹ́fà pẹ̀lú.
13 then, indeed, the maiden came in unto the king, —whatsoever she might mention, was given her, to go with her, out of the house of the women up to the house of the king:
Báyìí ni yóò ṣe lọ síwájú ọba: ohunkóhun tí ó bá béèrè ni wọ́n fi fún un láti inú ilé àwọn obìnrin lọ sí ààfin ọba.
14 in the evening, she went in, and, in the morning, she returned—unto the second house of the women, unto the custody of Shaashgaz the king’s eunuch, who kept the concubines, —she went not in again unto the king, except the king delighted in her, and she were called by name.
Ní alẹ́ ni yóò lọ síbẹ̀, tí ó bá sì di òwúrọ̀ yóò padà sí ilé kejì nínú ilé àwọn obìnrin ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣaaṣigasi ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó máa ń ṣe ìtọ́jú àwọn àlè. Òun kò ní lọ sí ọ̀dọ̀ ọba mọ́ àyàfi tí inú ọba bá dùn sí i, tí ó sì ránṣẹ́ pé ó ní orúkọ obìnrin.
15 But, when the turn came for Esther daughter of Abihail the uncle of Mordecai—who had taken her as his own daughter—to go in unto the king, she requested nothing, save what Hegai the king’s eunuch who kept the women might direct, —but so it was, that Esther obtained favour in the eyes of all who beheld her.
Nígbà tí ó kan Esteri (ọmọbìnrin tí Mordekai gbà ṣe ọmọ, ọmọbìnrin arákùnrin rẹ̀ tí ó ń jẹ́ Abihaili) láti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, wọn kò béèrè fún ohunkóhun ju èyí tí Hegai, ìwẹ̀fà ọba ẹni tí ó jẹ́ olùtọ́jú ilé àwọn obìnrin sọ pé kí ó ṣe lọ. Esteri sì rí ojúrere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn tí ó rí i.
16 So then Esther was taken unto King Ahasuerus, into his royal house, in the tenth month, the same, was the month Tebeth, —in the seventh year of his reign.
A mú Esteri lọ síwájú ọba Ahaswerusi ní ibùgbé ọba ní oṣù kẹwàá, tí ó jẹ́ oṣù Tebeti, ní ọdún keje ìjọba rẹ̀.
17 And the king loved Esther above all the women, and she obtained favour and lovingkindness before him, above all the virgins, —so that he set the royal crown upon her head, and made her queen, instead of Vashti.
Esteri sì wu ọba ju àwọn obìnrin tókù lọ, Ó sì rí ojúrere àti oore-ọ̀fẹ́ gbà ju ti àwọn wúńdíá tókù lọ. Nítorí náà ó fi adé ọba dé e ní orí ó sì fi ṣe ayaba dípò Faṣti.
18 Then the king made a great banquet, for all his rulers and his servants, the banquet of Esther, —and, a remission, for all the provinces, made he, and gave a present, according to the bounty of a king.
Ọba sì ṣe àsè ńlá, àsè Esteri, fún gbogbo àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì kéde ìsinmi jákèjádò ìgbèríko ó sì pín ẹ̀bùn fún wọn pẹ̀lú bí ọba ṣe lawọ́ tó.
19 Now, when virgins were gathered together second time, then, Mordecai, was sitting in the gate of the king.
Nígbà tí àwọn wúńdíá tún péjọ ní ìgbà kejì, Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba.
20 Esther had not told of her kindred, nor her people, as, Mordecai, had laid charge upon her, —and, the command of Mordecai, Esther performed, like as when she was being brought up with him.
Ṣùgbọ́n Esteri pa àṣírí ìdílé e rẹ̀ àti ibi tí ó ti wá mọ́ gẹ́gẹ́ bí Mordekai ṣe sọ fún un pé kí ó ṣe, nítorí tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ tí Mordekai fún un gẹ́gẹ́ bí ó ṣe máa ń ṣe nígbà tí ó wà ní ọ̀dọ̀ Mordekai.
21 In those days, when, Mordecai, was sitting in the gate of the king, Bigthan and Teresh, two of the eunuchs of the king who guarded the threshold, were wroth, and sought to thrust a hand upon King Ahasuerus;
Ní àsìkò tí Mordekai jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba, Bigitana àti Tereṣi, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n máa ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà, wọ́n bínú, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa ọba Ahaswerusi.
22 but the thing became known to Mordecai, who told it unto Esther the queen, —and Esther told it unto the king, in the name of Mordecai.
Ṣùgbọ́n Mordekai sì mọ̀ nípa ọ̀tẹ̀ náà, ó sọ̀ fún ayaba Esteri, Esteri sì sọ fún ọba, wọ́n sì fi ọlá fún Mordekai.
23 And, when the thing was searched into and found [true], then were they two hanged upon the gallows, and it was written, in the book of the chronicles, before the king.
Nígbà tí wọ́n sì wádìí ọ̀rọ̀ náà tí ó sì jásí òtítọ́, a sì so àwọn ìjòyè méjèèjì náà kọ́. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni a kọ sínú ìwé ìtàn ní iwájú ọba.

< Esther 2 >