< Exodus 35 >

1 And Moses assembled all the congregation of the children of Israel, and said unto them, These are the words which the LORD hath commanded, that ye should do them.
Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe.
2 Six days shall work be done, but on the seventh day there shall be to you an holy day, a sabbath of solemn rest to the LORD: whosoever doeth any work therein shall be put to death.
Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa.
3 Ye shall kindle no fire throughout your habitations upon the sabbath day.
Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
4 And Moses spake unto all the congregation of the children of Israel, saying, This is the thing which the LORD commanded, saying,
Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ.
5 Take ye from among you an offering unto the LORD: whosoever is of a willing heart, let him bring it, the LORD’S offering; gold, and silver, and brass;
Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
6 and blue, and purple, and scarlet, and fine linen, and goats’ [hair];
aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;
7 and rams’ skins dyed red, and sealskins, and acacia wood;
awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kasia;
8 and oil for the light, and spices for the anointing oil, and for the sweet incense;
òróró olifi fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;
9 and onyx stones, and stones to be set, for the ephod, and for the breastplate.
òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
10 And let every wise hearted man among you come, and make all that the LORD hath commanded;
“Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:
11 the tabernacle, its tent, and its covering, its clasps, and its boards, its bars, its pillars, and its sockets;
“àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;
12 the ark, and the staves thereof, the mercy-seat, and the veil of the screen;
Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó síji bò ó.
13 the table, and its staves, and all its vessels, and the shewbread;
Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà.
14 the candlestick also for the light, and its vessels, and its lamps, and the oil for the light;
Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná.
15 and the altar of incense, and its staves, and the anointing oil, and the sweet incense, and the screen for the door, at the door of the tabernacle;
Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn; aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà.
16 the altar of burnt offering, with its grating of brass, its staves, and all its vessels, the laver and its base;
Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀; agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
17 the hangings of the court, the pillars thereof, and their sockets, and the screen for the gate of the court;
Aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
18 the pins of the tabernacle, and the pins of the court, and their cords;
Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn.
19 the finely wrought garments, for ministering in the holy place, the holy garments for Aaron the priest, and the garments of his sons, to minister in the priest’s office.
Aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”
20 And all the congregation of the children of Israel departed from the presence of Moses.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose,
21 And they came, every one whose heart stirred him up, and every one whom his spirit made willing, [and] brought the LORD’S offering, for the work of the tent of meeting, and for all the service thereof, and for the holy garments.
olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà.
22 And they came, both men and women, as many as were willing hearted, [and] brought brooches, and earrings, and signet-rings, and armlets, all jewels of gold; even every man that offered an offering of gold unto the LORD.
Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa.
23 And every man, with whom was found blue, and purple, and scarlet, and fine linen, and goats’ [hair], and rams’ skins dyed red, and sealskins, brought them.
Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá.
24 Every one that did offer an offering of silver and brass brought the LORD’S offering: and every man, with whom was found acacia wood for any work of the service, brought it.
Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá.
25 And all the women that were wise hearted did spin with their hands, and brought that which they had spun, the blue, and the purple, the scarlet, and the fine linen.
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
26 And all the women whose heart stirred them up in wisdom spun the goats’ [hair].
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́.
27 And the rulers brought the onyx stones, and the stones to be set, for the ephod, and for the breastplate;
Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
28 and the spice, and the oil; for the light, and for the anointing oil, and for the sweet incense.
Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn.
29 The children of Israel brought a freewill offering unto the LORD; every man and woman, whose heart made them willing to bring for all the work, which the LORD had commanded to be made by the hand of Moses.
Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.
30 And Moses said unto the children of Israel, See, the LORD hath called by name Bezalel the son of Uri, the son of Hur, of the tribe of Judah;
Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
31 and he hath filled him with the spirit of God, in wisdom, in understanding, and in knowledge, and in all manner of workmanship;
Ó sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
32 and to devise cunning works, to work in gold, and in silver, and in brass,
Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ,
33 and in cutting of stones for setting, and in carving of wood, to work in all manner of cunning workmanship.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
34 And he hath put in his heart that he may teach, both he, and Oholiab, the son of Ahisamach, of the tribe of Dan.
Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù.
35 Them hath he filled with wisdom of heart, to work all manner of workmanship, of the engraver, and of the cunning workman, and of the embroiderer, in blue, and in purple, in scarlet, and in fine linen, and of the weaver, even of them that do any workmanship, and of those that devise cunning works.
Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.

< Exodus 35 >