< 1 Chronicles 4 >

1 The sons of Judah; Perez, Hezron, and Carmi, and Hur, and Shobal.
Àwọn ọmọ Juda: Peresi, Hesroni, Karmi, Huri àti Ṣobali.
2 And Reaiah the son of Shobal begat Jahath; and Jahath begat Ahumai and Lahad. These are the families of the Zorathites.
Reaiah ọmọ Ṣobali ni baba Jahati, àti Jahati baba Ahumai àti Lahadi. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀yà ará Sorati.
3 And these were [the sons of] the father of Etam; Jezreel, and Ishma, and Idbash: and the name of their sister was Hazzelelponi:
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Etamu: Jesreeli, Iṣima, Idbaṣi, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Haseleponi
4 and Penuel the father of Gedor, and Ezer the father of Hushah. These are the sons of Hur, the firstborn of Ephrathah, the father of Beth-lehem.
Penueli sì ni baba Gedori, àti Eseri baba Huṣa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata àti baba Bẹtilẹhẹmu.
5 And Ashhur the father of Tekoa had two wives, Helah and Naarah.
Aṣihuri baba Tekoa sì ní aya méjì, Hela àti Naara.
6 And Naarah bare him Ahuzzam, and Hepher, and Temeni, and Haahashtari. These were the sons of Naarah.
Naara sì bí Ahussamu, Heferi Temeni àti Haaṣtari. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Naara.
7 And the sons of Helah were Zereth, Izhar, and Ethnan.
Àwọn ọmọ Hela: Sereti Sohari, Etani,
8 And Hakkoz begat Anub, and Zobebah, and the families of Aharhel the son of Harum.
àti Kosi ẹni tí ó jẹ́ baba Anubu àti Sobeba àti ti àwọn ẹ̀yà Aharheli ọmọ Harumu.
9 And Jabez was more honourable than his brethren: and his mother called his name Jabez, saying, Because I bare him with sorrow.
Jabesi sì ní ọlá ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jabesi wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
10 And Jabez called on the God of Israel, saying, Oh that thou wouldest bless me indeed, and enlarge my border, and that thine hand might be with me, and that thou wouldest keep me from evil, that it be not to my sorrow! And God granted him that which he requested.
Jabesi sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Israẹli wí pé, “Háà, Ìwọ yóò bùkún fún mi, ìwọ yóò sì mú agbègbè mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mi mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
11 And Chelub the brother of Shuhah begat Mehir, which was the father of Eshton.
Kelubu arákùnrin Ṣuha, sì jẹ́ baba Mehiri, ẹni tí ó jẹ́ baba Eṣtoni.
12 And Eshton begat Beth-rapha, and Paseah, and Tehinnah the father of Ir-nahash. These are the men of Recah.
Eṣtoni sì jẹ́ baba Beti-Rafa, Pasea àti Tehina ti baba ìlú Nahaṣi. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Reka.
13 And the sons of Kenaz; Othniel, and Seraiah: and the sons of Othniel; Hathath.
Àwọn ọmọ Kenasi: Otnieli àti Seraiah. Àwọn ọmọ Otnieli: Hatati àti Meonotai.
14 And Meonothai begat Ophrah: and Seraiah begat Joab the father of Ge-harashim; for they were craftsmen.
Meonotai sì ni baba Ofira. Seraiah sì jẹ́ baba Joabu, baba Geharaṣinu. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn oníṣọ̀nà ní ìwọ̀n.
15 And the sons of Caleb the son of Jephunneh; Iru, Elah, and Naam: and the sons of Elah; and Kenaz.
Àwọn ọmọ Kalebu ọmọ Jefunne: Iru, Ela, àti Naamu. Àwọn ọmọ Ela: Kenasi.
16 And the sons of Jehallelel; Ziph, and Ziphah, Tiria, and Asarel.
Àwọn ọmọ Jehaleeli: Sifi, àti Sifa, Tiria àti Asareeli.
17 And the sons of Ezrah; Jether, and Mered, and Epher, and Jalon: and she bare Miriam, and Shammai, and Ishbah the father of Eshtemoa.
Àwọn ọmọ Esra: Jeteri, Meredi, Eferi àti Jaloni. Ọ̀kan lára àwọn aya Meredi sì bí Miriamu, Ṣammai àti Iṣba baba Eṣitemoa.
18 And his wife the Jewess bare Jered the father of Gedor, and Heber the father of Soco, and Jekuthiel the father of Zanoah. And these are the sons of Bithiah the daughter of Pharaoh, which Mered took.
Aya rẹ̀ láti ẹ̀yà Juda sì bí Jaredi baba Gedori, àti Heberi baba Soko àti Jekutieli baba Sanoa. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọbìnrin Farao Bitia, ẹni ti Meredi ti fẹ́.
19 And the sons of the wife of Hodiah, the sister of Naham, were the father of Keilah the Garmite, and Eshtemoa the Maacathite.
Àwọn ọmọ aya Hodiah arábìnrin Nahamu, baba Keila ará Garimu, àti Eṣitemoa àwọn ará Maakati.
20 And the sons of Shimon; Amnon, and Rinnah, Ben-hanan, and Tilon. And the sons of Ishi; Zoheth, and Ben-zoheth.
Àwọn ọmọ Ṣimoni: Amnoni, Rina, Beni-Hanani àti Tiloni. Àwọn ọmọ Iṣi: Soheti àti Beni-Soheti.
21 The sons of Shelah the son of Judah; Er the father of Lecah, and Laadah the father of Mareshah, and the families of the house of them that wrought fine linen, of the house of Ashbea;
Àwọn ọmọ Ṣela ọmọ Juda: Eri baba Leka, Lada baba Meraṣa àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń hun aṣọ oníṣẹ́ ní Beti-Aṣibea.
22 and Jokim, and the men of Cozeba, and Joash, and Saraph, who had dominion in Moab, and Jashubi-lehem. And the records are ancient.
Jokimu, ọkùnrin Koseba, àti Joaṣi àti Sarafi, olórí ní Moabu àti Jaṣubi Lehemu. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́.)
23 These were the potters, and the inhabitants of Netaim and Gederah: there they dwelt with the king for his work.
Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Netaimu àti Gedera; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ fún ọba.
24 The sons of Simeon; Nemuel, and Jamin, Jarib, Zerah, Shaul:
Àwọn ọmọ Simeoni: Nemueli, Jamini, Jaribi, Sera àti Saulu;
25 Shallum his son, Mibsam his son, Mishma his son.
Ṣallumu sì jẹ́ ọmọ Saulu, Mibsamu ọmọ rẹ̀ Miṣima ọmọ rẹ̀.
26 And the sons of Mishma; Hammuel his son, Zaccur his son, Shimei his son.
Àwọn ọmọ Miṣima: Hamueli ọmọ rẹ̀ Sakkuri ọmọ rẹ̀ àti Ṣimei ọmọ rẹ̀.
27 And Shimei had sixteen sons and six daughters; but his brethren had not many children, neither did all their family multiply, like to the children of Judah.
Ṣimei sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Juda.
28 And they dwelt at Beer-sheba, and Moladah, and Hazar-shual;
Wọ́n sì ń gbé ní Beerṣeba, Molada, Hasari-Ṣuali,
29 and at Bilhah, and at Ezem, and at Tolad;
àti ní Biliha, àti ní Esemu, àti ní Toladi,
30 and at Bethuel, and at Hormah, and at Ziklag;
Betueli, Horma, Siklagi,
31 and at Beth-marcaboth, and Hazar-susim, and at Beth-biri, and at Shaaraim. These were their cities unto the reign of David.
Beti-Markaboti Hormah; Hasari Susimu, Beti-Biri àti Ṣaraimi. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dafidi,
32 And their villages were Etam, and Ain, Rimmon, and Tochen, and Ashan, five cities:
agbègbè ìlú wọn ni Etamu, Aini, Rimoni, Tokeni, Aṣani àwọn ìlú márùn-ún,
33 and all their villages that were round about the same cities, unto Baal. These were their habitations, and they have their genealogy.
àti gbogbo ìletò wọn, tí ó wà yí ìlú náà ká, dé Baali. Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn. Àti ìtàn ìdílé wọ́n.
34 And Meshobab, and Jamlech, and Joshah the son of Amaziah;
Meṣobabu àti Jamleki, Josa ọmọ Amasiah,
35 and Joel, and Jehu the son of Joshibiah, the son of Seraiah, the son of Asiel;
Joẹli, Jehu ọmọ Josibiah, ọmọ Seraiah, ọmọ Asieli,
36 and Elioenai, and Jaakobah, and Jeshohaiah, and Asaiah, and Adiel, and Jesimiel, and Benaiah;
àti pẹ̀lú Elioenai, Jaakoba, Jeṣohaiah, Asaiah, Adieli, Jesimieli, Benaiah,
37 and Ziza the son of Shiphi, the son of Allon, the son of Jedaiah, the son of Shimri, the son of Shemaiah;
àti Sisa ọmọ Ṣifi ọmọ Alloni, ọmọ Jedaiah, ọmọ Ṣimri ọmọ Ṣemaiah.
38 these mentioned by name were princes in their families: and their fathers’ houses increased greatly.
Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ sí i gidigidi,
39 And they went to the entering in of Gedor, even unto the east side of the valley, to seek pasture for their flocks.
wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gedori. Lọ títí dé ìlà-oòrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn.
40 And they found fat pasture and good, and the land was wide, and quiet, and peaceable; for they that dwelt there aforetime were of Ham.
Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ọmọ Hamu ni ó ti ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
41 And these written by name came in the days of Hezekiah king of Judah, and smote their tents, and the Meunim that were found there, and destroyed them utterly, unto this day, and dwelt in their stead: because there was pasture there for their flocks.
Àwọn ọkùnrin tí a kọ orúkọ rẹ̀ sókè, dé ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Wọ́n sì kọlu àwọn ará Hamu ní àgọ́ wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Mehuni tí a rí níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátápátá títí di òní yìí. Wọ́n sì ń gbé ní ipò wọn, nítorí pé koríko ń bẹ níbẹ̀ fún agbo ẹran wọn.
42 And some of them, even of the sons of Simeon, five hundred men, went to mount Seir; having for their captains Pelatiah, and Neariah, and Rephaiah, and Uzziel, the sons of Ishi.
Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Simeoni, lábẹ́ ìdarí pẹ̀lú Pelatiah, Neariah, Refaiah àti Usieli, àwọn ọmọ Iṣi, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Seiri.
43 And they smote the remnant of the Amalekites that escaped, and dwelt there, unto this day.
Wọ́n sì pa àwọn ará Amaleki tí ó kù, àwọn tí ó ti sálà, wọ́n sì ti ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.

< 1 Chronicles 4 >