< Psalms 136 >

1 Give thanks to the Lord for his goodness: for his kindness endures forever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
2 Give thanks to the God of gods: for his kindness endures forever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
3 Give thanks to the Lord of lords: for his kindness endures forever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
4 To him who alone does great wonders: for his kindness endures forever.
Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
5 Whose wisdom created the heavens: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
6 Who spread forth the earth on the waters: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
7 Who made great lights: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
8 The sun to rule over the day: for his kindness endures forever.
Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
9 Moon and stars to rule over the night: for his kindness endures forever.
Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
10 Who struck the firstborn of Egypt: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
11 And brought Israel out from their midst: for his kindness endures forever.
Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
12 With strong hand and outstretched arm: for his kindness endures forever.
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
13 Who cut the Red Sea in pieces: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
14 And brought Israel right through the midst: for his kindness endures forever.
Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
15 And shook Pharaoh with all his host into the sea for his kindness endures forever.
Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
16 Who led his people through the desert: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
17 Who struck down great kings: for his kindness endures forever.
Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
18 And slew noble kings: for his kindness endures forever.
Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
19 Sihon, king of the Amorites: for his kindness endures forever.
Sihoni, ọba àwọn ará Amori
20 And Og, king of Bashan: for his kindness endures forever.
Àti Ogu, ọba Baṣani;
21 Who gave their land for possession: for his kindness endures forever.
Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
22 Possession to Israel his servant: for his kindness endures forever.
Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
23 Who remembered our low estate: for his kindness endures forever.
Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
24 And rescued us from our foes: for his kindness endures forever.
Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
25 Who gives to all flesh food: for his kindness endures forever.
Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
26 Give thanks to the God of heaven: for his kindness endures forever.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;

< Psalms 136 >