< Psalms 3 >

1 [A Psalm by David, when he fled from Absalom his son.] LORD, how my adversaries have increased. Many rise up against me.
Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu. Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí! Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
2 Many there are who say of my soul, "There is no salvation for him in God." (Selah)
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé “Ọlọ́run kò nígbà á là.” (Sela)
3 But you, LORD, are a shield around me, my glory, and the one who lifts up my head.
Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa; ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
4 I cried out to the LORD with my voice, and he answered me from his holy mountain. (Selah)
Olúwa ni mo kígbe sókè sí, ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. (Sela)
5 I lay down and slept. I awoke, for the LORD sustains me.
Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn; mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.
6 I am not afraid of ten thousands of people who have set themselves against me on every side.
Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.
7 Arise, LORD. Save me, my God. For you slap all my enemies in the face. You break the teeth of the wicked.
Dìde, Olúwa! Gbà mí, Ọlọ́run mi! Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n; kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.
8 Salvation belongs to the LORD. Your blessing is upon your people. (Selah)
Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá. Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. (Sela)

< Psalms 3 >