< Psalms 116 >

1 I love the LORD, because he listens to my voice, and my cries for mercy.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Because he has turned his ear to me, therefore I will call on him as long as I live.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 The cords of death surrounded me, the pains of Sheol got a hold of me. I found trouble and sorrow. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 Then I called on the name of the LORD: "LORD, I beg you, deliver my soul."
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 The LORD is Gracious and righteous. Yes, our God is merciful.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 The LORD preserves the simple. I was brought low, and he saved me.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Return to your rest, my soul, for the LORD has dealt bountifully with you.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 For you have delivered my soul from death, my eyes from tears, and my feet from falling.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 I will walk before the LORD in the land of the living.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 I believed, therefore I said, "I am greatly afflicted."
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 I said in my haste, "All men are liars."
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 What will I give to the LORD for all his benefits toward me?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 I will take the cup of salvation, and call on the name of the LORD.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 I will pay my vows to the LORD, yes, in the presence of all his people.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Precious in the sight of the LORD is the death of his faithful ones.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 LORD, truly I am your servant. I am your servant, the son of your handmaid. You have freed me from my chains.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 I will offer to you the sacrifice of thanksgiving, and will call on the name of the LORD.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 I will pay my vows to the LORD, yes, in the presence of all his people,
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 in the courts of the LORD's house, in the midst of you, Jerusalem. Praise the LORD.
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psalms 116 >