< Proverbs 24 >

1 Be not thou envious against evil men, neither desire to be with them.
Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburú má ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;
2 For their heart studieth destruction, and their lips talk of mischief.
nítorí ọkàn wọn ń gbèrò ohun búburú, ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.
3 Through wisdom is an house builded; and by understanding it is established:
Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́ nípa òye sì ni ó ti fìdímúlẹ̀;
4 And by knowledge shall the chambers be filled with all precious and pleasant riches.
nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kún pẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.
5 A wise man [is] strong; yea, a man of knowledge increaseth strength.
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀, ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára sí i.
6 For by wise counsel thou shalt make thy war: and in multitude of counsellors [there is] safety.
Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà: nínú ìṣẹ́gun ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.
7 Wisdom [is] too high for a fool: he openeth not his mouth in the gate.
Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrè àti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.
8 He that deviseth to do evil shall be called a mischievous person.
Ẹni tí ń pète ibi ni a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.
9 The thought of foolishness [is] sin: and the scorner [is] an abomination to men.
Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.
10 [If] thou faint in the day of adversity, thy strength [is] small.
Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmú báwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!
11 If thou forbear to deliver [them that are] drawn unto death, and [those that are] ready to be slain;
Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ sí ibi ikú là; fa àwọn tó ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lọ sí ibi ìparun padà.
12 If thou sayest, Behold, we knew it not; doth not he that pondereth the heart consider [it]? and he that keepeth thy soul, doth [not] he know [it]? and shall [not] he render to [every] man according to his works?
Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkan kan nípa èyí,” ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsi i? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́n? Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?
13 My son, eat thou honey, because [it is] good; and the honeycomb, [which is] sweet to thy taste:
Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára, oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.
14 So [shall] the knowledge of wisdom [be] unto thy soul: when thou hast found [it], then there shall be a reward, and thy expectation shall not be cut off.
Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹ bí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọ ìrètí rẹ kì yóò sì já ṣófo.
15 Lay not wait, O wicked [man], against the dwelling of the righteous; spoil not his resting place:
Má ṣe ba ní ibùba bí ènìyàn búburú láti gba ibùjókòó olódodo, má ṣe fi ibi ìsinmi rẹ̀ ṣe ìjẹ;
16 For a just [man] falleth seven times, and riseth up again: but the wicked shall fall into mischief.
nítorí bí olódodo ènìyàn bá tilẹ̀ ṣubú ní ìgbà méje, yóò tún padà dìde sá á ni, ṣùgbọ́n ìdààmú yóò fa ènìyàn búburú lulẹ̀.
17 Rejoice not when thine enemy falleth, and let not thine heart be glad when he stumbleth:
Má ṣe yọ̀ nígbà tí ọ̀tá rẹ bá ṣubú; nígbà tí ó bá kọsẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yọ̀.
18 Lest the LORD see [it], and it displease him, and he turn away his wrath from him.
Àìṣe bẹ́ẹ̀ Olúwa yóò rí i yóò sì bínú yóò sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
19 Fret not thyself because of evil [men], neither be thou envious at the wicked;
Má ṣe fòyà nítorí àwọn ènìyàn ibi tàbí jowú àwọn ènìyàn búburú,
20 For there shall be no reward to the evil [man; ] the candle of the wicked shall be put out.
nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájú a ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.
21 My son, fear thou the LORD and the king: [and] meddle not with them that are given to change:
Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi, má sì ṣe darapọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun.
22 For their calamity shall rise suddenly; and who knoweth the ruin of them both?
Nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn, ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?
23 These [things] also [belong] to the wise. [It is] not good to have respect of persons in judgment.
Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n: láti ṣe ojúsàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá.
24 He that saith unto the wicked, Thou [art] righteous; him shall the people curse, nations shall abhor him:
Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre,” àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì kọ̀ ọ́.
25 But to them that rebuke [him] shall be delight, and a good blessing shall come upon them.
Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi, ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.
26 [Every man] shall kiss [his] lips that giveth a right answer.
Ìdáhùn òtítọ́ dàbí ìfẹnukoni ní ẹnu.
27 Prepare thy work without, and make it fit for thyself in the field; and afterwards build thine house.
Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹ sì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára; lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.
28 Be not a witness against thy neighbour without cause; and deceive [not] with thy lips.
Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládùúgbò rẹ láìnídìí, tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.
29 Say not, I will do so to him as he hath done to me: I will render to the man according to his work.
Má ṣe wí pé, “Èmi yóò ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi; Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”
30 I went by the field of the slothful, and by the vineyard of the man void of understanding;
Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ, mo kọjá níbi ọgbà àjàrà aláìgbọ́n ènìyàn;
31 And, lo, it was all grown over with thorns, [and] nettles had covered the face thereof, and the stone wall thereof was broken down.
ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo, koríko ti gba gbogbo oko náà.
32 Then I saw, [and] considered [it] well: I looked upon [it, and] received instruction.
Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsi mo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;
33 [Yet] a little sleep, a little slumber, a little folding of the hands to sleep:
oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera díẹ̀ láti sinmi,
34 So shall thy poverty come [as] one that travelleth; and thy want as an armed man.
òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalè àti àìní bí olè.

< Proverbs 24 >