< Numbers 34 >

1 And the LORD spoke to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Command the children of Israel, and say to them, When you come into the land of Canaan; (this is the land that shall fall to you for an inheritance, even the land of Canaan with the coasts thereof: )
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 Then your south quarter shall be from the wilderness of Zin along by the coast of Edom, and your south border shall be the outmost coast of the salt sea eastward:
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 And your border shall turn from the south to the ascent of Akrabbim, and pass on to Zin: and the going forth thereof shall be from the south to Kadeshbarnea, and shall go on to Hazaraddar, and pass on to Azmon:
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 And the border shall fetch a compass from Azmon to the river of Egypt, and the goings out of it shall be at the sea.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 And as for the western border, you shall even have the great sea for a border: this shall be your west border.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 And this shall be your north border: from the great sea you shall point out for you mount Hor:
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 From mount Hor you shall point out your border to the entrance of Hamath; and the goings forth of the border shall be to Zedad:
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 And the border shall go on to Ziphron, and the goings out of it shall be at Hazarenan: this shall be your north border.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 And you shall point out your east border from Hazarenan to Shepham:
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 And the coast shall go down from Shepham to Riblah, on the east side of Ain; and the border shall descend, and shall reach to the side of the sea of Chinnereth eastward:
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 And the border shall go down to Jordan, and the goings out of it shall be at the salt sea: this shall be your land with the coasts thereof round about.
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 And Moses commanded the children of Israel, saying, This is the land which you shall inherit by lot, which the LORD commanded to give to the nine tribes, and to the half tribe:
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 For the tribe of the children of Reuben according to the house of their fathers, and the tribe of the children of Gad according to the house of their fathers, have received their inheritance; and half the tribe of Manasseh have received their inheritance:
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 The two tribes and the half tribe have received their inheritance on this side Jordan near Jericho eastward, toward the sun rise.
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 And the LORD spoke to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 These are the names of the men which shall divide the land to you: Eleazar the priest, and Joshua the son of Nun.
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 And you shall take one prince of every tribe, to divide the land by inheritance.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 And the names of the men are these: Of the tribe of Judah, Caleb the son of Jephunneh.
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 And of the tribe of the children of Simeon, Shemuel the son of Ammihud.
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 Of the tribe of Benjamin, Elidad the son of Chislon.
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 And the prince of the tribe of the children of Dan, Bukki the son of Jogli.
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 The prince of the children of Joseph, for the tribe of the children of Manasseh, Hanniel the son of Ephod.
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 And the prince of the tribe of the children of Ephraim, Kemuel the son of Shiphtan.
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 And the prince of the tribe of the children of Zebulun, Elizaphan the son of Parnach.
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 And the prince of the tribe of the children of Issachar, Paltiel the son of Azzan.
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 And the prince of the tribe of the children of Asher, Ahihud the son of Shelomi.
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 And the prince of the tribe of the children of Naphtali, Pedahel the son of Ammihud.
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 These are they whom the LORD commanded to divide the inheritance to the children of Israel in the land of Canaan.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.

< Numbers 34 >