< Psalms 54 >

1 For the Leader; with string-music. Maschil of David: when the Ziphites came and said to Saul: 'Doth not David hide himself with us?' O God, save me by Thy name, and right me by Thy might.
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
2 O God, hear my prayer; give ear to the words of my mouth.
Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
3 For strangers are risen up against me, and violent men have sought after my soul; they have not set God before them. (Selah)
Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
4 Behold, God is my helper; the Lord is for me as the upholder of my soul.
Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
5 He will requite the evil unto them that lie in wait for me; destroy Thou them in Thy truth.
Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
6 With a freewill-offering will I sacrifice unto Thee; I will give thanks unto Thy name, O LORD, for it is good.
Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
7 For He hath delivered me out of all trouble; and mine eye hath gazed upon mine enemies.
Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.

< Psalms 54 >