< Luke 4 >

1 And Iesus full of the holy Ghost returned from Iordan, and was led by that Spirit into the wildernes,
Jesu sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó padà ti Jordani wá, a sì ti ọwọ́ Ẹ̀mí darí rẹ̀ sí ijù,
2 And was there fourtie dayes tempted of the deuil, and in those dayes he did eate nothing: but when they were ended, he afterward was hungry.
Ogójì ọjọ́ ni a fi dán an wò lọ́wọ́ èṣù. Kò sì jẹ ohunkóhun ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: nígbà tí wọ́n sì parí, lẹ́yìn náà ni ebi wá ń pa á.
3 Then the deuil saide vnto him, If thou be the Sonne of God, commaund this stone that it be made bread.
Èṣù sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ fún òkúta yìí kí ó di àkàrà.”
4 But Iesus answered him, saying, It is written, That man shall not liue by bread only, but by euery word of God.
Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan.’”
5 Then the deuill tooke him vp into an high mountaine, and shewed him all the kingdomes of the world, in the twinkeling of an eye.
Lójúkan náà, èṣù sì mú un lọ sí orí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé hàn án.
6 And the deuill saide vnto him, All this power will I giue thee, and the glory of those kingdomes: for that is deliuered to mee: and to whomsoeuer I will, I giue it.
Èṣù sì wí fún un pé, “Ìwọ ni èmi ó fi gbogbo agbára yìí àti ògo wọn fún: nítorí á sá ti fi fún mi. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wù mí, èmi a fi í fún.
7 If thou therefore wilt worship mee, they shalbe all thine.
Ǹjẹ́ bí ìwọ bá foríbalẹ̀ fún mi, gbogbo rẹ̀ ni yóò jẹ́ tìrẹ.”
8 But Iesus answered him, and saide, Hence from mee, Satan: for it is written, Thou shalt worship the Lord thy God, and him alone thou shalt serue.
Jesu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani, nítorí tí a kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ìwọ foríbalẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ kí ó sì máa sìn.’”
9 Then hee brought him to Hierusalem, and set him on a pinacle of the Temple, and said vnto him, If thou be the Sonne of God, cast thy selfe downe from hence,
Èṣù sì mú un lọ sí Jerusalẹmu, ó sì gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili, ó sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ láti ibí yìí.
10 For it is written, That hee will giue his Angels charge ouer thee to keepe thee:
A sá ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí rẹ, láti máa ṣe ìtọ́jú rẹ;
11 And with their handes they shall lift thee vp, least at any time thou shouldest dash thy foote against a stone.
àti pé ní ọwọ́ wọn ni wọn ó gbé ọ sókè, kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
12 And Iesus answered, and said vnto him, It is said, Thou shalt not tempt the Lord thy God.
Jesu sì dáhùn ó wí fún un pé, “A ti kọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
13 And when the deuil had ended all the tentation, he departed from him for a litle season.
Nígbà tí èṣù sì parí ìdánwò náà gbogbo, ó fi í sílẹ̀ lọ fun sá à kan.
14 And Iesus returned by the power of the spirite into Galile: and there went a fame of him throughout all the region round about.
Jesu sì fi agbára Ẹ̀mí padà wá sí Galili, òkìkí rẹ̀ sì kàn kálẹ̀ ní gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
15 For he taught in their Synagogues, and was honoured of all men.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn; a ń yìn ín lógo láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ènìyàn wá.
16 And hee came to Nazareth where hee had bene brought vp, and (as his custome was) went into the Synagogue on the Sabbath day, and stoode vp to reade.
Ó sì wá sí Nasareti, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.
17 And there was deliuered vnto him the booke of the Prophet Esaias: and when hee had opened the booke, hee founde the place, where it was written,
A sì fi ìwé wòlíì Isaiah fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:
18 The Spirit of the Lord is vpon mee, because he hath anoynted me, that I should preach the Gospel to the poore: he hath sent mee, that I should heale the broken hearted, that I should preach deliuerance to the captiues, and recouering of sight to the blinde, that I should set at libertie them that are bruised:
“Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi, nítorí tí ó fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì. Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìmúnríran fún àwọn afọ́jú, àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,
19 And that I should preache the acceptable yeere of the Lord.
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”
20 And hee closed the booke, and gaue it againe to the minister, and sate downe: and the eyes of all that were in the Synagogue were fastened on him.
Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú Sinagọgu sì tẹjúmọ́ ọn.
21 Then he began to say vnto them, This day is the Scripture fulfilled in your eares.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wí fún wọn pé, “Lónìí ìwé mímọ́ yìí ṣẹ ní etí yín.”
22 And all bare him witnes, and wondered at the gracious wordes, which proceeded out of his mouth, and said, Is not this Iosephs sonne?
Gbogbo wọn sì jẹ́rìí rẹ̀, háà sì ṣe wọ́n sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ tí ń jáde ní ẹnu rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ọmọ Josẹfu kọ́ yìí?”
23 Then he said vnto them, Ye will surely say vnto mee this prouerbe, Physician, heale thy selfe: whatsoeuer we haue heard done in Capernaum, doe it here likewise in thine owne countrey.
Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó pa òwe yìí sí mi pé, ‘Oníṣègùn, wo ara rẹ̀ sàn! Àwọn ohun tí àwa gbọ́ pé o ti ọwọ́ rẹ ṣe ní Kapernaumu, ṣe é níhìn-ín yìí pẹ̀lú ní ilẹ̀ ara rẹ.’”
24 And he saide, Verely I say vnto you, No Prophet is accepted in his owne countrey.
Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, kò sí wòlíì tí a tẹ́wọ́gbà ní ilẹ̀ baba rẹ̀.
25 But I tell you of a trueth, many widowes were in Israel in the dayes of Elias, when heauen was shut three yeres and sixe moneths, when great famine was throughout all the land:
Ṣùgbọ́n mo wí fún un yín nítòótọ́, opó púpọ̀ ni ó wà ní Israẹli nígbà ọjọ́ wòlíì Elijah, nígbà tí ọ̀run fi sé ní ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà, nígbà tí ìyàn ńlá fi mú ká ilẹ̀ gbogbo.
26 But vnto none of them was Elias sent, saue into Sarepta, a citie of Sidon, vnto a certaine widowe.
Kò sì sí ẹnìkan nínú wọn tí a rán Elijah sí, bí kò ṣe sí obìnrin opó kan ní Sarefati, ìlú kan ní Sidoni.
27 Also many lepers were in Israel, in the time of Eliseus the Prophet: yet none of them was made cleane, sauing Naaman the Syrian.
Adẹ́tẹ̀ púpọ̀ ní sì ń bẹ ní Israẹli nígbà wòlíì Eliṣa; kò sì ṣí ọ̀kan nínú wọn tí a wẹ̀nùmọ́, bí kò ṣe Naamani ará Siria.”
28 Then all that were in the Synagogue, when they heard it, were filled with wrath,
Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó wà nínú Sinagọgu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, inú bi wọ́n gidigidi,
29 And rose vp, and thrust him out of the citie, and led him vnto the edge of the hil, whereon their citie was built, to cast him downe headlong.
wọ́n sì dìde, wọ́n tì í sóde sí ẹ̀yìn ìlú, wọ́n sì fà á lọ sí bèbè òkè níbi tí wọ́n gbé tẹ ìlú wọn dó, kí wọn bá à lè sọ sílẹ̀ ní ògèdèǹgbé.
30 But he passed through the middes of them, and went his way,
Ṣùgbọ́n ó kọjá láàrín wọn, ó bá tirẹ̀ lọ.
31 And came downe into Capernaum a citie of Galile, and there taught them on the Sabbath dayes.
Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Kapernaumu, ìlú kan ní Galili, ó sì ń kọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi.
32 And they were astonied at his doctrine: for his worde was with authoritie.
Ẹnu sì yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ̀: nítorí tàṣẹtàṣẹ ni ọ̀rọ̀ rẹ̀.
33 And in the Synagogue there was a man which had a spirit of an vncleane deuill, which cryed with a loude voyce,
Ọkùnrin kan sì wà nínú Sinagọgu, ẹni tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, ó kígbe ní ohùn rara,
34 Saying, Oh, what haue we to doe with thee, thou Iesus of Nazareth? art thou come to destroy vs? I know who thou art, euen the holy one of God.
“Ó wí pé, kín ni ṣe tàwa tìrẹ, Jesu ará Nasareti? Ìwọ́ wá láti pa wá run bí? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.”
35 And Iesus rebuked him, saying, Holde thy peace, and come out of him. Then the deuill throwing him in the middes of them, came out of him, and hurt him nothing at all.
Jesu sì bá a wí gidigidi, ó wí fun pe, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí o sì jáde lára rẹ̀.” Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà sì gbé e ṣánlẹ̀ ní àwùjọ, ó jáde kúrò lára rẹ̀, kò sì pa á lára.
36 So feare came on them all, and they spake among themselues, saying, What thing is this: for with authoritie and power he commaundeth the foule spirits, and they come out?
Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ wí pé, “Irú ẹ̀kọ́ kín ni èyí? Nítorí pẹ̀lú àṣẹ àti agbára ni ó fi bá àwọn ẹ̀mí àìmọ́ wí, wọ́n sì jáde kúrò.”
37 And ye fame of him spred abroad throughout all the places of the countrey round about.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn níbi gbogbo ní agbègbè ilẹ̀ náà yíká.
38 And he rose vp, and came out of the Synagogue, and entred into Simons house. And Simons wiues mother was taken with a great feuer, and they required him for her.
Nígbà tí ó sì dìde kúrò nínú Sinagọgu, ó sì wọ̀ ilé Simoni lọ; ibà sì ti dá ìyá ìyàwó Simoni dùbúlẹ̀, wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ nítorí rẹ̀.
39 Then he stoode ouer her, and rebuked the feuer, and it left her, and immediatly she arose, and ministred vnto them.
Ó sì súnmọ́ ọ, ó bá ibà náà wí; ibà sì náà sì fi sílẹ̀. O sì dìde lọ́gán, ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
40 Now at the sunne setting, all they that had sicke folkes of diuers diseases, brought them vnto him, and he layd his hands on euery one of them, and healed them.
Nígbà tí oòrùn sì ń wọ̀, àwọn ènìyàn gbe àwọn aláìsàn, tó ní onírúurú àìsàn wá sọ́dọ̀ Jesu; ó sì fi ọwọ́ lé olúkúlùkù wọn, ó sì mú wọn láradá.
41 And deuils also came out of many, crying, and saying, Thou art that Christ that Sonne of God: but he rebuked them, and suffered them not to say that they knewe him to be that Christ.
Àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde lára ẹni púpọ̀ pẹ̀lú, wọ́n ń kígbe, wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run!” Ó sì ń bá wọn wí kò sì jẹ́ kí wọn kí ó fọhùn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé Òun ni Kristi náà.
42 And when it was day, he departed, and went foorth into a desart place, and the people sought him, and came to him, and kept him that he should not depart from them.
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, Jesu sì jáde lọ, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀. Ìjọ ènìyàn sì ń wá a kiri, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì dá a dúró, nítorí kí ó má ba à lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
43 But he sayd vnto them, Surely I must also preach the kingdome of God to other cities: for therefore am I sent.
Ṣùgbọ́n ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò lè ṣàìmá wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú mìíràn pẹ̀lú, nítorí náà ni a sá ṣe rán mi.”
44 And hee preached in the Synagogues of Galile.
Ó sì ń wàásù nínú Sinagọgu ti Judea.

< Luke 4 >