< Acts 19 >

1 And it came to passe, while Apollos was at Corinthus, that Paul when he passed thorow the vpper coasts, came to Ephesus, and found certaine disciples,
Nígbà ti Apollo wà ni Kọrinti, ti Paulu kọjá lọ sí apá òkè ìlú, ó sì wá sí Efesu, o sì rí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kan;
2 And saide vnto them, Haue ye receiued the holy Ghost since ye beleeued? And they saide vnto him, Wee haue not so much as heard whether there be an holy Ghost.
o wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ha gba Ẹ̀mí Mímọ́ náà nígbà tí ẹ̀yin gbàgbọ́?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò gbọ́ rárá pé Ẹ̀mí Mímọ́ kan wà.”
3 And he said vnto them, Vnto what were ye then baptized? And they saide, Vnto Iohns baptisme.
Ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ irú bamitiisi wo ni a bamitiisi yín sí?” Wọ́n sì wí pé, “Sí bamitiisi tí Johanu.”
4 Then saide Paul, Iohn verely baptized with the baptisme of repentance, saying vnto the people, that they shoulde beleeue in him, which should come after him, that is, in Christ Iesus.
Paulu sí wí pé, “Nítòótọ́, ní Johanu fi bamitiisi tí ìrònúpìwàdà bamitiisi, ó ń wí fún àwọn ènìyàn pé, kí wọ́n gba ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn òun gbọ́, èyí sì ni Kristi Jesu.”
5 And when they heard it, they were baptized in the Name of the Lord Iesus.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, a bamitiisi wọn lórúkọ Jesu Olúwa.
6 So Paul layde his handes vpon them, and the holy Ghost came on them, and they spake the tongues, and prophecied.
Nígbà tí Paulu sì gbé ọwọ́ lé wọn, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn, wọ́n sì ń fọ́ èdè mìíràn, wọ́n sì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀.
7 And all the men were about twelue.
Iye àwọn ọkùnrin náà gbogbo tó méjìlá.
8 Moreouer he went into the Synagogue, and spake boldly for the space of three moneths, disputing and exhorting to the things that appertaine to the kingdome of God.
Nígbà tí ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀ ni oṣù mẹ́ta, ó ń fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀, ó sì ń yí wọn lọ́kàn padà sí nǹkan tí i ṣe tí ìjọba Ọlọ́run.
9 But when certaine were hardened, and disobeyed, speaking euill of the way of God before the multitude, hee departed from them, and separated the disciples, and disputed dayly in the schoole of one Tyrannus.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn àwọn mìíràn nínú wọn di líle, tí wọn kò sì gbàgbọ́, tí wọn ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọ̀nà náà níwájú ìjọ ènìyàn, ó lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì ya àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sọ́tọ̀, ó sì ń sọ àsọyé lójoojúmọ́ ni ilé ìwé Tirannusi.
10 And this was done by the space of two yeeres, so that all they which dwelt in Asia, heard the word of ye Lord Iesus, both Iewes and Grecians.
Èyí n lọ bẹ́ẹ̀ fún ìwọ̀n ọdún méjì; tó bẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn tí ń gbé Asia gbọ́ ọ̀rọ̀ Jesu Olúwa, àti àwọn Júù àti àwọn Giriki.
11 And God wrought no small miracles by the handes of Paul,
Ọlọ́run sì tí ọwọ́ Paulu ṣe àwọn àkànṣe iṣẹ́ ìyanu,
12 So that from his body were brought vnto the sicke, kerchefs or handkerchefs, and the diseases departed from them, and the euill spirits went out of them.
tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń mú aṣọ àti aṣọ ìnuwọ́ rẹ̀ tọ àwọn ọlọkùnrùn lọ, ààrùn sì fi wọ́n sílẹ̀, àwọn ẹ̀mí búburú sì jáde kúrò lára wọn.
13 Then certaine of the vagabond Iewes, exorcistes, tooke in hand to name ouer them which had euil spirits, the Name of the Lord Iesus, saying, We adiure you by Iesus, whom Paul preacheth.
Ṣùgbọ́n àwọn Júù kan n lọ káàkiri láti máa le ẹ̀mí èṣù jáde, wọn dáwọ́lé àdábọwọ́ ara wọn, láti pé orúkọ Jesu Olúwa sí àwọn tí ó ni ẹ̀mí búburú, wí pé, “Àwa fi orúkọ Jesu tí Paulu ń wàásù fi yín bú.”
14 (And there were certaine sonnes of Sceua a Iewe, the Priest, about seuen which did this)
Àwọn méje kan sì wà, tí wọn ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn ọmọ ẹnìkan tí a ń pè ni Sikẹfa, tí í ṣe olórí àlùfáà gíga láàrín àwọn Júù.
15 And the euil spirit answered, and said, Iesus I acknowledge, and Paul I know: but who are ye?
Ẹ̀mí búburú náà sì dáhùn, ó ní “Jesu èmi mọ̀ ọ́n, mo sì mọ Paulu pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin?”
16 And the man in whome the euil spirit was, ranne on them, and ouercame them, and preuailed against them, so that they fledde out of that house, naked, and wounded.
Nígbà tí ọkùnrin tí ẹ̀mí búburú náà wà lára rẹ̀ sì fò mọ́ wọn, ó pa kúúrù mọ́ wọn, ó sì borí wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sá jáde kúrò ní ilé náà ní ìhòhò pẹ̀lú ni ìfarapa.
17 And this was knowen to all the Iewes and Grecians also, which dwelt at Ephesus, and feare came on them all, and the Name of the Lord Iesus was magnified,
Ìròyìn yìí sì di mí mọ̀ fún gbogbo àwọn Júù àti àwọn ará Giriki pẹ̀lú tí ó ṣe àtìpó ní Efesu; ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn, a sì gbé orúkọ Jesu Olúwa ga.
18 And many that beleeued, came and confessed, and shewed their workes.
Ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ sì wá, wọ́n jẹ́wọ́, wọ́n sì fi iṣẹ́ wọn hàn.
19 Many also of them which vsed curious artes, brought their bookes, and burned them before all men: and they counted the price of them, and found it fiftie thousand pieces of siluer.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn tí ń ṣe alálúpàyídà ni ó kó ìwé wọn jọ, wọ́n dáná sun wọ́n lójú gbogbo ènìyàn. Wọ́n sì ṣírò iye wọn, wọ́n sì rí i, ó jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìwọ̀n fàdákà.
20 So the worde of God grewe mightily, and preuailed.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ Olúwa gbèrú tí o sí gbilẹ̀ si í gidigidi.
21 Nowe when these things were accomplished, Paul purposed by the Spirite to passe through Macedonia and Achaia, and to goe to Hierusalem, saying, After I haue bene there, I must also see Rome.
Ǹjẹ́ bí nǹkan wọ̀nyí tí parí tan, Paulu pinnu nínú ọkàn rẹ̀ pé, nígbà tí òun bá kọjá ní Makedonia àti Akaia, òun ó lọ sí Jerusalẹmu, ó wí pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo bá dé ibẹ̀, èmi kò lè ṣàìmá dé Romu pẹ̀lú.”
22 So sent hee into Macedonia two of them that ministred vnto him, Timotheus and Erastus, but he remained in Asia for a season.
Nígbà tí ó sì tí rán méjì nínú àwọn tí ń ṣe ìránṣẹ́ fún un lọ sí Makedonia, Timotiu àti Erastu, òun tìkára rẹ̀ dúró díẹ̀ ní ilẹ̀ Asia.
23 And the same time there arose no small trouble about that way.
Ní àkókò náà ìrúkèrúdò díẹ̀ kan wà nítorí ọ̀nà náà.
24 For a certaine man named Demetrius a siluersmith, which made siluer temples of Diana, brought great gaines vnto the craftesmen,
Nítorí ọkùnrin kan tí a ń pè ní Demetriusi, alágbẹ̀dẹ fàdákà, tí o máa ń fi fàdákà ṣe ilé òrìṣà fún Artemisi, ó mú ère tí kò mọ níwọ̀n wá fún àwọn oníṣọ̀nà.
25 Whom he called together, with the workemen of like things, and saide, Syrs, ye knowe that by this craft we haue our goods:
Nígbà tí ó pè wọ́n jọ, àti irú àwọn oníṣẹ́-ọnà bẹ́ẹ̀, ó wí pé, “Alàgbà, ẹ̀yin mọ̀ pé nípa iṣẹ́ ọnà yìí ni àwa fi ní ọrọ̀ wa.
26 Moreouer ye see and heare, that not alone at Ephesus, but almost throughout all Asia this Paul hath perswaded, and turned away much people, saying, That they be not gods which are made with handes.
Ẹ̀yin sì rí i, ẹ sì gbọ́ pé, kì í ṣe ni Efesu nìkan ṣoṣo ni, ṣùgbọ́n ó fẹ́rẹ jẹ́ gbogbo Asia ni Paulu yìí ń yí ọ̀pọ̀ ènìyàn lọ́kàn padà, tí ó sì ń dárí wọn wí pé, ohun tí a fi ọwọ́ ṣe, kì í ṣe Ọlọ́run.
27 So that not onely this thing is dangerous vnto vs, that this our portion shall be reproued, but also that the temple of the great goddesse Diana should be nothing esteemed, and that it would come to passe that her magnificence, which all Asia and the world worshippeth, should be destroyed.
Kì í sì ṣe pé kìkì iṣẹ́ ọnà wa yìí ni ó wà nínú ewu dídí asán; ṣùgbọ́n tẹmpili Artemisi òrìṣà ńlá yóò di gígàn pẹ̀lú, àti gbogbo ọláńlá rẹ̀ yóò sì run, ẹni tí gbogbo Asia àti gbogbo ayé ń bọ.”
28 Now when they heard it, they were full of wrath, and cried out, saying, Great is Diana of the Ephesians.
Nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n kún fún ìbínú, wọ́n kígbe, wí pé, “Òrìṣà ńlá ni Artemisi ti ará Efesu!”
29 And the whole citie was full of confusion, and they rushed into the common place with one assent, and caught Gaius, and Aristarchus, men of Macedonia, and Pauls companions of his iourney.
Gbogbo ìlú náà sì kún fún ìrúkèrúdò: wọ́n sì fi ọkàn kan rọ́ wọn sí inú ilé ìṣeré, wọ́n sì mú Gaiusi àti Aristarku ara Makedonia, àwọn ẹlẹgbẹ́ Paulu nínú ìrìnàjò.
30 And when Paul would haue entred in vnto the people, the disciples suffred him not.
Nígbà ti Paulu sì ń fẹ́ wọ àárín àwọn ènìyàn lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kọ̀ fún un.
31 Certaine also of the chiefe of Asia which were his friendes, sent vnto him, desiring him that hee woulde not present him selfe in the Common place.
Àwọn olórí kan ara Asia, tí i ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ránṣẹ́ sí i, wọ́n bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó má ṣe fi ara rẹ̀ wéwu nínú ilé ìṣeré náà.
32 Some therefore cried one thing, and some another: for the assemblie was out of order, and the more part knewe not wherefore they were come together.
Ǹjẹ́ àwọn kan ń wí ohun kan, àwọn mìíràn ń wí òmíràn: nítorí àjọ di rúdurùdu; ọ̀pọ̀ ènìyàn ni kò sì mọ̀ ìdí ohun tí wọ́n tilẹ̀ fi péjọpọ̀.
33 And some of the company drew foorth Alexander, the Iewes thrusting him forwards. Alexander then beckened with the hande, and woulde haue excused the matter to the people.
Àwọn kan nínú àwùjọ Júù ti Aleksanderu síwájú, wọn si pàṣẹ fun láti sọ̀rọ̀. Ó juwọ́ sí wọn láti dákẹ́ kí ó ba lè wí tẹnu rẹ̀ fun àwọn ènìyàn.
34 But when they knew that he was a Iewe, there arose a shoute almost for the space of two houres, of all men crying, Great is Diana of the Ephesians.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n mọ̀ pé Júù ni, gbogbo wọn ni ohùn kan, bẹ̀rẹ̀ sí kígbe fún bi wákàtí méjì pé, “Òrìṣà ńlá ni Artemisi tí ará Efesu!”
35 Then the towne clearke when hee had stayed the people, saide, Ye men of Ephesus, what man is it that knoweth not howe that the citie of the Ephesians is a worshipper of the great goddesse Diana, and of the image, which came downe from Iupiter?
Nígbà tí akọ̀wé ìlú sì mú kí ìjọ ènìyàn dákẹ́, “Ẹ̀yin ará Efesu, ta ni ẹni tí ó wà tí kò mọ̀ pé, ìlú Efesu ní í ṣe olùsìn Artemisi òrìṣà ńlá, àti tí ère tí ó ti ọ̀dọ̀ Jupiteri bọ́ sílẹ̀?
36 Seeing then that no man can speake against these things, ye ought to be appeased, and to doe nothing rashly.
Ǹjẹ́ bi a kò tilẹ̀ sọ̀rọ̀-òdì sí nǹkan wọ̀nyí, ó yẹ kí ẹ dákẹ́, kí ẹ̀yin má ṣe fi ìkanra ṣe ohunkóhun.
37 For yee haue brought hither these men, which haue neither committed sacrilege, neither doe blaspheme your goddesse.
Nítorí ti ẹ̀yin mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí wá, wọn kò ja ilé òrìṣà lólè, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀-òdì sí òrìṣà wa.
38 Wherefore, if Demetrius and the craftes men which are with him, haue a matter against any man, the lawe is open, and there are Deputies: let them accuse one another.
Ǹjẹ́ nítorí náà tí Demetriusi, àti àwọn oníṣẹ́-ọnà tí o wà pẹ̀lú rẹ̀ bá ní gbólóhùn asọ̀ kan sí ẹnikẹ́ni, ilé ẹjọ́ ṣí sílẹ̀, àwọn onídàájọ́ sì ń bẹ: jẹ́ kí wọn lọ fi ara wọn sùn.
39 But if ye inquire any thing cocerning other matters, it may be determined in a lawful assembly.
Ṣùgbọ́n bí ẹ ba ń wádìí ohun kan nípa ọ̀ràn mìíràn, a ó parí rẹ̀ ni àjọ tí ó tọ́.
40 For we are euen in ieopardie to be accused of this dayes sedition, for as much as there is no cause, whereby we may giue a reason of this concourse of people.
Nítorí àwa ṣa wà nínú ewu, nítorí rògbòdìyàn tí ó bẹ́ sílẹ̀ lónìí yìí; kò ṣáá ní ìdí kan tí rògbòdìyàn yìí fi bẹ́ sílẹ̀, nítorí èyí àwa kì yóò lè dáhùn fún ìwọ́jọ yìí.”
41 And when he had thus spoken, hee let the assembly depart.
Nígbà tí ó sì ti sọ bẹ́ẹ̀ tan, ó tú ìjọ náà ká.

< Acts 19 >