< Acts 11 >

1 Nowe the Apostles and the brethren that were in Iudea, heard, that the Gentiles had also receiued the worde of God.
Àwọn aposteli àti àwọn arákùnrin ti ó wà ni Judea sì gbọ́ pé àwọn aláìkọlà pẹ̀lú ti gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
2 And when Peter was come vp to Hierusalem, they of the circumcision contended against him,
Nígbà tí Peteru sì gòkè wá sí Jerusalẹmu, àwọn ti ìkọlà ń bá a wíjọ́
3 Saying, Thou wentest in to men vncircumcised, and hast eaten with them.
wí pé, “Ìwọ wọlé tọ àwọn ènìyàn aláìkọlà lọ, ó sì bá wọn jẹun.”
4 Then Peter beganne, and expounded the thing in order to them, saying,
Ṣùgbọ́n Peteru bẹ̀rẹ̀ sí là á yé wọn lẹ́sẹẹsẹ, wí pé,
5 I was in the citie of Ioppa, praying, and in a trance I sawe this vision, A certaine vessell comming downe as it had bene a great sheete, let downe from heauen by the foure corners, and it came to me.
“Èmi wà ni ìlú Joppa, mo ń gbàdúrà, mo rí ìran kan lójúran. Ohun èlò kan sọ̀kalẹ̀ bí ewé tákàdá ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá; ó sì wá títí de ọ̀dọ̀ mi.
6 Towarde the which when I had fastened mine eyes, I considered, and sawe foure footed beastes of the earth, and wilde beastes, and creeping things, and foules of the heauen.
Mo tẹjúmọ́ ọn, mo sì fiyèsí i, mo sí rí ẹran ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin, àti ẹranko igbó, àti ohun tí ń rákò, àti ẹyẹ ojú ọ̀run.
7 Also I heard a voyce, saying vnto me, Arise, Peter: slay and eate.
Mo sì gbọ́ ohùn kan ti ó fọ̀ sí mi pé, ‘Dìde, Peteru: máa pa, kí ó sì máa jẹ.’
8 And I said, God forbid, Lord: for nothing polluted or vncleane hath at any time entred into my mouth.
“Ṣùgbọ́n mo dáhùn wí pé, ‘Rara Olúwa! Nítorí ohun èèwọ̀ tàbí ohun aláìmọ́ kan kò wọ ẹnu mi rí láéláé.’
9 But the voyce answered me the seconde time from heauen, The things that God hath purified, pollute thou not.
“Ṣùgbọ́n ohùn kan dáhùn nígbà ẹ̀ẹ̀kejì láti ọ̀run wá pé, ‘Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, kí ìwọ má ṣe pè é ní àìmọ́.’
10 And this was done three times, and all were taken vp againe into heauen.
Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà mẹ́ta; a sì tún fa gbogbo rẹ̀ sókè ọ̀run.
11 Then behold, immediatly there were three men already come vnto the house where I was, sent from Cesarea vnto me.
“Sì wò ó, lójúkan náà ọkùnrin mẹ́ta dúró níwájú ilé ti a gbé wà, ti a rán láti Kesarea sí mi.
12 And the Spirit saide vnto me, that I should go with them, without doubting: moreouer these sixe brethren came with me, and we entred into the mans house.
Ẹ̀mí sì wí fún mi pé, kí èmi bá wọn lọ, ki èmi má ṣe kọminú ohunkóhun. Àwọn arákùnrin mẹ́fà wọ̀nyí sì bá mi lọ, a sì wọ ilé ọkùnrin náà.
13 And he shewed vs, howe he had seene an Angel in his house, which stoode and said to him, Send men to Ioppa, and call for Simon, whose surname is Peter.
Ó sì sọ fún wa bí òun ti rí angẹli kan tí ó dúró ní ilé rẹ̀, tí ó sì wí pé, ‘Ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni tí àpèlé rẹ̀ jẹ́ Peteru;
14 He shall speake wordes vnto thee, whereby both thou and all thine house shalbe saued.
ẹni tí yóò sọ ọ̀rọ̀ fún ọ, nípa èyí tí a ó fi gba ìwọ àti gbogbo ilé rẹ là.’
15 And as I began to speake, the holy Ghost fell on them, euen as vpon vs at the beginning.
“Bí mo sì ti bẹ̀rẹ̀ sì sọ, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti bà lé wa ni àtètèkọ́ṣe.
16 Then I remembred the word of the Lord, howe he said, Iohn baptized with water, but ye shalbe baptized with the holy Ghost.
Nígbà náà ni mo rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí pé, ‘Johanu fi omi bamitiisi nítòótọ́; ṣùgbọ́n a ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.’
17 For as much then as God gaue them a like gift, as he did vnto vs, when we beleeued in the Lord Iesus Christ, who was I, that I coulde let God?
Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run sì ti fi irú ẹ̀bùn kan náà fún wọn bí ó ti fi fún àwa pẹ̀lú nígbà tí a gba Jesu Kristi Olúwa gbọ́, ta ni èmi tí n ó fi rò pé mo le è de Ọlọ́run ní ọ̀nà?”
18 When they heard these things, they helde their peace, and glorified God, saying, Then hath God also to the Gentiles graunted repentance vnto life.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì pa ẹnu wọn mọ́, wọ́n sì yin Ọlọ́run ògo wí pé, “Ǹjẹ́ Ọlọ́run fi ìrònúpìwàdà sí ìyè fún àwọn aláìkọlà pẹ̀lú!”
19 And they which were scattered abroade because of the affliction that arose about Steuen, went throughout till they came vnto Phenice and Cyprus, and Antiochia, preaching the worde to no man, but vnto the Iewes onely.
Nítorí náà àwọn tí a sì túká kiri nípasẹ̀ inúnibíni tí ó dìde ní ti Stefanu, wọ́n rìn títí de Fonisia, àti Saipurọsi, àti Antioku, wọn kò sọ ọ̀rọ̀ náà fún ẹnìkan bí kò ṣe fún kìkì àwọn Júù.
20 Now some of them were men of Cyprus and of Cyrene, which when they were come into Antiochia, spake vnto the Grecians, and preached the Lord Iesus.
Ṣùgbọ́n àwọn kan ń bẹ nínú wọn tí ó jẹ́ ará Saipurọsi àti Kirene; nígbà tí wọ́n dé Antioku, wọ́n sọ̀rọ̀ fún àwọn Helleni pẹ̀lú, wọ́n ń wàásù ìròyìn ayọ̀ nípa Jesu Olúwa.
21 And the hand of the Lord was with them, so that a great number beleeued and turned vnto the Lord.
Ọwọ́ Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn sì gbàgbọ́, wọ́n sì yípadà sí Olúwa.
22 Then tydings of those things came vnto the eares of the Church, which was in Hierusalem, and they sent foorth Barnabas, that he should goe vnto Antiochia.
Ìròyìn nípa wọn sì dé etí ìjọ ti ó wà ni Jerusalẹmu; wọ́n sì rán Barnaba lọ títí dé Antioku;
23 Who when he was come and had seene the grace of God, was glad, and exhorted all, that with purpose of heart they would continue in the Lord.
Nígbà ti ó dé ti ó sì rí ẹ̀rí oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run, ó yọ̀, ó sì gba gbogbo wọn níyànjú pé, pẹ̀lú ìpinnu ọkàn ni kí wọn fi ara mọ́ Olúwa.
24 For he was a good man, and full of the holy Ghost, and faith, and much people ioyned them selues vnto the Lord.
Nítorí òun jẹ́ ènìyàn rere, ó sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àti fún ìgbàgbọ́; ènìyàn púpọ̀ ni a sì kà kún Olúwa.
25 Then departed Barnabas to Tarsus to seeke Saul:
Barnaba sì jáde lọ sí Tarsu láti wá Saulu,
26 And when he had founde him, he brought him vnto Antiochia: and it came to passe that a whole yere they were conuersant with ye Church, and taught much people, in so much that the disciples were first called Christians in Antiochia.
nígbà tí ó sì rí i, ó mú un wá sí Antioku. Fún ọdún kan gbáko ni wọ́n fi ń bá ìjọ péjọpọ̀, tí wọ́n sì kọ́ ènìyàn púpọ̀. Ní Antioku ni a sì kọ́kọ́ ti pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ni “Kristiani.”
27 In those dayes also came Prophets from Hierusalem vnto Antiochia.
Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni àwọn wòlíì sì ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ wá sí Antioku.
28 And there stoode vp one of them named Agabus, and signified by the Spirit, that there should be great famine throughout all the world, which also came to passe vnder Claudius Cesar.
Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn, ti a ń pè ni Agabu sí dìde, ó ti ipa Ẹ̀mí sọ pé, ìyàn ńlá yóò mú yíká gbogbo ilẹ̀ Romu. (Èyí sì ṣẹlẹ̀ nígbà ìṣèjọba Kilaudiu.)
29 Then the disciples, euery man according to his ability, purposed to sende succour vnto the brethren which dwelt in Iudea.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì pinnu, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ ti tó, láti rán ìrànlọ́wọ́ sí àwọn arákùnrin tí ó wà ní Judea.
30 Which thing they also did, and sent it to the Elders, by the hand of Barnabas and Saul.
Wọn sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọn sì fi ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí àwọn àgbà láti ọwọ́ Barnaba àti Saulu.

< Acts 11 >