< Psalms 92 >

1 A psalm. A song for the Sabbath day. How good it is to thank the Lord, to sing praises to you, Most High,
Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 to tell of your trustworthy love in the morning, and your faithfulness in the night,
láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
3 to the music of a ten-stringed harp and the melody of a lyre.
lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 You've made me so happy, Lord, because of all you've done for me! I sing for joy at what you've done!
Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 Lord, what you do is amazing; your thoughts are very profound!
Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 Only senseless people and fools don't know and understand this:
Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 even though the wicked grow up quickly like grass, and even though people who do evil flourish, they will be destroyed forever!
nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
8 But you, Lord, rule on high forever.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 Your enemies, Lord, your enemies will die; everyone who does evil will be destroyed!
Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
10 But you have made me as powerful as a wild bull; you have anointed me with the best olive oil.
Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 My eyes look with pleasure to see my enemies defeated; my ears have heard the downfall of those who tried to attack me.
Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
12 Those who live right flourish like a palm tree; they grow tall like a cedar tree in Lebanon.
Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
13 They are planted in the house of the Lord; they thrive in the courts of our God.
tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 Even when they are old they will still produce fruit, staying fresh and green.
Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 They will declare, “The Lord does what is right! He is my rock! There is no wrong in him!”
láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”

< Psalms 92 >