< Zechariah 2 >

1 And I lifted up my eyes, and saw, and behold a man, with a measuring line in his hand.
Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
2 And I said: Whither goest thou? and he said to me: To measure Jerusalem, and to see how great is the breadth thereof, and how great the length thereof.
Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
3 And behold the angel that spoke in me went forth, and another angel went out to meet him.
Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
4 And he said to him: Run, speak to this young man, saying: Jerusalem shall be inhabited without walls, by reason of the multitude of men, and of the beasts in the midst thereof.
Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
5 And I will be to it, saith the Lord, a wall of fire round about: and I will be in glory in the midst thereof.
Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
6 O, O flee ye out of the land of the north, saith the Lord, for I have scattered you into the four winds of heaven, saith the Lord.
“Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
7 O Sion, flee, thou that dwellest with the daughter of Babylon:
“Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
8 For thus saith the Lord of hosts: After the glory he hath sent me to the nations that have robbed you: for he that toucheth you, toucheth the apple of my eye:
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
9 For behold I lift up my hand upon them, and they shall be a prey to those that served them: and you shall know that the Lord of hosts sent me.
Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
10 Sing praise, and rejoice, O daughter of Sion: for behold I come, and I will dwell in the midst of thee: saith the Lord.
“Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
11 And many nations shall be joined to the Lord in that day, and they shall be my people, and I will dwell in the midst of thee: and thou shalt know that the Lord of hosts hath sent me to thee.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
12 And the Lord shall possess Juda his portion in the sanctified land: and he shall yet choose Jerusalem.
Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
13 Let all flesh be silent at the presence of the Lord: for he is risen up out of his. holy habitation.
Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”

< Zechariah 2 >