< Psalms 92 >

1 A psalm of a canticle on the sabbath day. It is good to give praise to the Lord: and to sing to thy name, O most High.
Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
2 To shew forth thy mercy in the morning, and thy truth in the night:
láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
3 Upon an instrument of ten strings, upon the psaltery: with a canticle upon the harp.
lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
4 For thou hast given me, O Lord, a delight in thy doings: and in the works of thy hands I shall rejoice.
Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
5 O Lord, how great are thy works! thy thoughts are exceeding deep.
Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
6 The senseless man shall not know: nor will the fool understand these things.
Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
7 When the wicked shall spring up as grass: and all the workers of iniquity shall appear: That they may perish for ever and ever:
nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
8 But thou, O Lord, art most high for evermore.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
9 For behold thy enemies, O Lord, for behold thy enemies shall perish: and all the workers of iniquity shall be scattered.
Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
10 But my horn shall be exalted like that of the unicorn: and my old age in plentiful mercy.
Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
11 My eye also hath looked down upon my enemies: and my ear shall hear of the downfall of the malignant that rise up against me.
Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
12 The just shall flourish like the palm tree: he shall grow up like the cedar of Libanus.
Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
13 They that are planted in the house of the Lord shall flourish in the courts of the house of our God.
tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
14 They shall still increase in a fruitful old age: and shall be well treated,
Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
15 That they may shew, That the Lord our God is righteous, and there is no iniquity in him.
láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”

< Psalms 92 >