< Psalms 60 >

1 Unto the end, for them that shall be changed, for the inscription of a title, to David himself, for doctrine, When he set fire to Mesopotamia of Syria and Sobal and Joab returned and slew of Edom, in the vale of the saltpits, twelve thousand men. O God, thou hast cast us off, and hast destroyed us; thou hast been angry, and hast had mercy on us.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
2 Thou hast moved the earth, and hast troubled it: heal thou the breaches thereof, for it has been moved.
Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
3 Thou hast shewn thy people hard things; thou hast made us drink wine of sorrow.
Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
4 Thou hast given a warning to them that fear thee: that they may flee from before the bow: That thy beloved may be delivered.
Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
5 Save me with thy right hand, and hear me.
Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
6 God hath spoken in his holy place: I will rejoice, and I will divide Sichem; and will mete out the vale of tabernacles.
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
7 Galaad is mine, and Manasses is mine: and Ephraim is the strength of my head. Juda is my king:
Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
8 Moab is the pot of my hope. Into Edom will I stretch out my shoe: to me the foreigners are made subject.
Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
9 Who will bring me into the strong city? who will lead me into Edom?
Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
10 Wilt not thou, O God, who hast cast us off? and wilt not thou, O God, go out with our armies?
Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
11 Give us help from trouble: for vain is the salvation of man.
Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
12 Through God we shall do mightily: and he shall bring to nothing them that afflict us.
Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

< Psalms 60 >