< Lamentations 3 >

1 Aleph. I am the man that see my poverty by the rod of his indignation.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Aleph. He hath led me, and brought me into darkness, and not into light.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Aleph. Only against me he hath turned, and turned again his hand all the day.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Beth. My skin and my flesh he hath made old, he hath broken my bones.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Beth. He hath built round about me, and he hath compassed me with gall and labour.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Beth. He hath set me in dark places as those that are dead for ever.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Ghimel. He hath built against me round about, that I may not get out: he hath made my fetters heavy.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Ghimel. Yea, and when I cry, and entreat, he hath shut out my prayer.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Ghimel. He hath shut up my ways with square stones, he hath turned my paths upside down.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Daleth. He is become to me as a bear lying in wait: as a lion in secret places.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Daleth. He hath turned aside my paths, and hath broken me in pieces, he hath made me desolate.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Daleth. He hath bent his bow, and set me as a mark for his arrows.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 He. He hath shot into my reins the daughters of his quiver.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 He. I am made a derision to all my people, their song all the day long.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 He. He hath filled me with bitterness, he hath inebriated me with wormwood.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Vau. And he hath broken my teeth one by one, he hath fed me with ashes.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Vau. And my soul is removed far off from peace, I have forgotten good things.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Vau. And I said: My end and my hope is perished from the Lord.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Zain. Remember my poverty, and transgression, the wormwood, and the gall.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Zain. I will be mindful and remember, and my soul shall languish within me.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Zain. These things I shall think over in my heart, therefore will I hope.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Heth. The mercies of the Lord that we are not consumed: because his commiserations have not failed.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Heth. They are new every morning, great is thy faithfulness.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Heth. The Lord is my portion, said my soul: therefore will I wait for him.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Teth. The Lord is good to them that hope in him, to the soul that seeketh him.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Teth. It is good to wait with silence for the salvation of God.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Teth. It is good for a man, when he hath borne the yoke from his youth.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Jod. He shall sit solitary, and hold his peace: because he hath taken it up upon himself.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Jod. He shall put his mouth in the dust, if so be there may be hope.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Jod. He shall give his cheek to him that striketh him, he shall be filled with reproaches.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Caph. For the Lord will not cast off for ever.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Caph. For if he hath cast off, he will also have mercy, according to the multitude of his mercies.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Caph. For he hath not willingly afflicted, nor cast off the children of men.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Lamed. To crush under his feet all the prisoners of the land,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Lamed. To turn aside the judgment of a man before the face of the most High,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 Lamed. To destroy a man wrongfully in his judgment, the Lord hath not approved.
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Mem. Who is he that hath commanded a thing to be done, when the Lord commandeth it not?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Mem. Shall not both evil and good proceed out of the mouth of the Highest?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Mem. Why hath a living man murmured, man suffering for his sins?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Nun. Let us search our ways, and seek, and return to the Lord.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Nun. Let us lift up our hearts with our hands to the Lord in the heavens.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Nun. We have done wickedly, and provoked thee to wrath: therefore thou art inexorable.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Samech. Thou hast covered in thy wrath, and hast struck us: thou hast killed and hast not spared.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Samech. Thou hast set a cloud before thee, that our prayer may not pass through.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Samech. Thou hast made me as an outcast, and refuse in the midst of the people.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Phe. All our enemies have opened their mouths against us.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Phe. Prophecy is become to us a fear, and a snare, and destruction.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Phe. My eye hath run down with streams of water, for the destruction of the daughter of my people.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Ain. My eye is afflicted, and hath not been quiet, because there was no rest:
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 Ain. Till the Lord regarded and looked down from the heavens.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Ain. My eye hath wasted my soul because of all the daughters of my city.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Sade. My enemies have chased me and caught me like a bird, without cause.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Sade. My life is fallen into the pit, and they have laid a stone over me.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Sade. Waters have flowed over my head: I said: I am cut off.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Coph. I have called upon thy name, O Lord, from the lowest pit.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Coph. Thou hast heard my voice: turn not away thy ear from my sighs, and cries.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Coph. Thou drewest near in the day, when I called upon thee, thou saidst: Fear not.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Res. Thou hast judged, O Lord, the cause of my soul, thou the Redeemer of my life.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Res. Thou hast seen, O Lord, their iniquity against me: judge thou my judgment.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Res. Thou hast seen all their fury, and all their thoughts against me.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Sin. Thou hast heard their reproach, O Lord, all their imaginations against me.
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Sin. The lips of them that rise up against me: and their devices against me all the day.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Sin. Behold their sitting down, and their rising up, I am their song.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Thau. Thou shalt render them a recompense, O Lord, according to the works of their hands.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Thau. Thou shalt give them a buckler of heart, thy labour.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Thau. Thou shalt persecute them in anger, and shalt destroy them from under the heavens, O Lord.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Lamentations 3 >