< Judges 12 >

1 But behold there arose a sedition in Ephraim. And passing towards the north, they said to Jephte: When thou wentest to fight against the children of Ammon, why wouldst thou not call us, that we might go with thee? Therefore we will burn thy house.
Àwọn ọkùnrin Efraimu pe àwọn ológun wọn jáde, wọ́n sì rékọjá sí ìhà àríwá, wọ́n sì bi Jefta pé, “Èéṣe tí o fi lọ bá àwọn ará Ammoni jagun láì ké sí wa láti bá ọ lọ? Àwa yóò sun ilé rẹ mọ́ ọ lórí.”
2 And he answered them: I and my people were at great strife with the children of Ammon: and I called you to assist me, and you would not do it.
Jefta dáhùn pé, “Èmi àti àwọn ènìyàn ní ìyọnu ńlá pẹ̀lú àwọn ará Ammoni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo pè yín, ẹ̀yin kò gbà mí sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn.
3 And when I saw this, I put my life in my own hands, and passed over against the children of Ammon, and the Lord delivered them into my hands. What have I deserved, that you should rise up to fight against me?
Nígbà tí mo rí i pé ẹ̀yin kò gbà mí, mo fi ẹ̀mí mi wéwu. Mó sì gòkè lọ láti bá àwọn ará Ammoni jà, Olúwa sì fún mi ní ìṣẹ́gun lórí wọn, èéṣe báyìí tí ẹ fi dìde wá lónìí láti bá mi jà?”
4 Then calling to him all the men of Galaad, he fought against Ephraim: and the men of Galaad defeated Ephraim, because he had said: Galaad is a fugitive of Ephraim, and dwelleth in the midst of Ephraim and Manasses.
Nígbà náà ni Jefta kó gbogbo ọkùnrin Gileadi jọ, ó sì bá Efraimu jà. Àwọn ọkùnrin Gileadi sì kọlù Efraimu, nítorí wọ́n ti sọtẹ́lẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ará Gileadi jẹ́ àsáwọ̀ àwọn ará Efraimu àti ti Manase.”
5 And the Galaadites secured the fords of the Jordan, by which Ephraim was to return. And when any one of the number of Ephraim came thither in the flight, and said: I beseech you let me pass: the Galaadites said to him: Art thou not an Ephraimite? If he said: I am not:
Àwọn ará Gileadi gba à bá wọ odò Jordani tí wọ́n máa gbà lọ sí Efraimu, nígbàkígbà tí àwọn ará Efraimu bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sálọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gileadi yóò bi í pé, “Ṣé ará Efraimu ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”
6 They asked him: Say then, Scibboleth, which is interpreted, An ear of corn. But he answered, Sibboleth, not being able to express an ear of corn by the same letter. Then presently they took him and killed him in the very passage of the Jordan. And there fell at that time of Ephraim two and forty thousand.
wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣibolẹti.’” Tí ó bá ní, “Sibolẹti,” torí pé kò ní mọ̀ ọ́n pé dáradára, wọ́n á mú un wọn, a sì pa á ni à bá wọ odò Jordani. Àwọn ará Efraimu tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ọkùnrin.
7 And Jephte the Galaadite judged Israel six years: and he died, and was buried in his city of Galaad.
Jefta ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jefta ará Gileadi kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gileadi.
8 After him Abesan of Bethlehem judged Israel:
Lẹ́yìn Jefta, Ibsani ará Bẹtilẹhẹmu ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
9 He had thirty sons, and as many daughters, whom he sent abroad, and gave to husbands, and took wives for his sons of the same number, bringing them into his house. And he judged Israel seven years:
Ó ní ọgbọ̀n ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ibsani ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ọdún méje.
10 And he died, and was buried in Bethlehem.
Lẹ́yìn náà ni Ibsani kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹtilẹhẹmu.
11 To him succeeded Ahialon a Zabulonite: and he judged Israel ten years:
Lẹ́yìn rẹ̀, Eloni ti ẹ̀yà Sebuluni ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́wàá.
12 And he died, and was buried in Zabulon.
Eloni sì kú, wọ́n sì sin ín sí Aijaloni ní ilẹ̀ Sebuluni.
13 After him Abdon, the son of Illel, a Pharathonite, judged Israel:
Lẹ́yìn rẹ̀ ni Abdoni ọmọ Hileli tí Piratoni n ṣe àkóso Israẹli.
14 And he had forty sons, and of them thirty grandsons, mounted upon seventy ass colts, and he judged Israel eight years:
Òun ní ogójì ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọ ọmọ àwọn tí ó ń gun àádọ́rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ó ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́jọ.
15 And he died, and was buried in Pharathon in the land of Ephraim, in the mount of Amalech.
Abdoni ọmọ Hileli sì kú, wọ́n sin ín sí Piratoni ní ilé Efraimu ní ìlú òkè àwọn ará Amaleki.

< Judges 12 >