< Joshua 12 >

1 These are the kings, whom the children of Israel slew and possessed their land beyond the Jordan towards the rising of the sun, from the torrent Arnon unto mount Hermon, and all the east country that looketh towards the wilderness.
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
2 Sehon king of the Amorrhites, who dwelt in Hesebon, and had dominion from Aroer, which is seated upon the bank of the torrent Arnon, and of the middle part in the valley, and of half Galaad, as far as the torrent Jaboc, which is the border of the children of Ammon.
Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
3 And from the wilderness, to the sea of Ceneroth towards the east, and to the sea of the wilderness, which is the most salt sea, on the east side by the way that leadeth to Bethsimoth: and on the south side that lieth under Asedoth, Phasga.
Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
4 The border of Og the king of Basan, of the remnant of the Raphaims who dwelt in Astaroth, and in Edrai, and had dominion in mount Hermon, and in Salecha, and in all Basan, unto the borders
Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
5 Of Gessuri and Machati, and of half Galaad: the borders of Sehon the king of Hesebon.
Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
6 Moses the servant of the Lord, and the children of Israel slew them, and Moses delivered their land in possession to the Rubenites, and Gadites, and the half tribe of Manasses.
Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
7 These are the kings of the land, whom Josue and the children of Israel slew beyond the Jordan on the west side from Baalgad in the held of Libanus, unto the mount, part of which goeth up into Seir: and Josue delivered it in possession to the tribes of Israel, to every one their divisions,
Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
8 As well in the mountains as in the plains and the champaign countries. In Asedoth, and in the wilderness, and in the south was the Hethite and the Amorrhite, the Chanaanite and the Pherezite, the Hevite and the Jebusite.
ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
9 The king of Jericho one: the king of Hai, which is on the side of Bethel, one:
Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
10 The king of Jerusalem one, the king of Hebron one.
ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
11 The king of Jerimoth one, the king of Lachis one,
ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
12 The king of Eglon one, the king of Gazer one,
ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
13 The king of Dabir one, the king of Gader one,
ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
14 The king of Herma one, the king of Hered one,
ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
15 The king of Lebna one, the king of Odullam one,
ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
16 The king of Maceda one, the king of Bethel one,
ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
17 The king of Taphua one, the king of Opher one,
ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
18 The king of Aphec one, the king of Saron one,
ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
19 The king of Madon one, the king of Asor one,
ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
20 The king of Semeron one, the king of Achsaph one,
ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
21 The king of Thenac one, the king of Megeddo one,
ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
22 The king of Cades one, the king of Jachanan of Carmel one,
ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
23 The king of Dor, and of the province of Dor one, the king of the nations of Galgal one,
ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
24 The king of Thersa one: all the kings thirty and one.
ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.

< Joshua 12 >