< 2 Chronicles 28 >

1 Achaz was twenty years old when he began to reign, and he reigned sixteen years in Jerusalem: he did not that which was right in the sight of the Lord as David his father had done,
Ahasi sì jẹ́ ẹni ogún ọdún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Gẹ́gẹ́ bí i Dafidi baba rẹ̀ kò sì ṣe ohun rere ní ojú Olúwa.
2 But walked in the ways of the kings of Israel; moreover also he cast statues for Baalim.
Ó sì rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli ó sì ṣe ère dídá fún ìsìn Baali
3 It was he that burnt incense in the valley of Benennom, and consecrated his sons in the fire according to the manner of the nations, which the Lord slew at the coming of the children of Israel.
Ó sì sun ẹbọ ní àfonífojì Hinnomu, ó sì sun àwọn ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli
4 He sacrificed also, and burnt incense in the high places, and on the hills, and under every green tree.
Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní ibi gíga wọ́n nì lórí òkè kékeré àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
5 And the Lord his God delivered him into the hands of the king of Syria, who defeated him, and took a great booty out of his kingdom, and carried it to Damascus: he was also delivered into the hands of the king of Israel, who overthrew him with a great slaughter.
Nítorí náà, Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fi lé ọba Siria lọ́wọ́. Àwọn ará Siria sì pa á run, wọ́n sì kó púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, wọ́n sì kó wọn wá sí Damasku. Ó sì tún fi lé ọwọ́ ọba Israẹli pẹ̀lú, ẹni tí ó kó wọn ní ìgbèkùn púpọ̀ tí ó sì pa wọ́n ní ìpakúpa.
6 For Phacee the son of Romelia slew of Juda a hundred and twenty thousand in one day, all valiant men: because they had forsaken the Lord the God of their fathers.
Ní ọjọ́ kan Peka, ọmọ Remaliah, pa ọ̀kẹ́ mẹ́fà àwọn ọmọ-ogun ní Juda nítorí Juda ti kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀.
7 At the same time Zechri a powerful man of Ephraim, slew Maasias the king’s son, and Ezricam the governor of his house, and Elcana who was next to the king.
Sikri àti Efraimu alágbára sì pa Maaseiah ọmọ ọba, Aṣrikamu ìjòyè tí ó wà ní ìkáwọ́ ilé ọba, àti Elkana igbákejì ọba.
8 And the children of Israel carried away of their brethren two hundred thousand women, boys, and girls, and an immense booty: and they brought it to Samaria.
Àwọn ọmọ Israẹli sì kó ní ìgbèkùn lára àwọn arákùnrin wọn ọ̀kẹ́ mẹ́wàá àwọn aya wọn, àwọn ọmọkùnrin àti obìnrin wọn sì tún kó ọ̀pọ̀ ìkógun, èyí tí wọn kó padà lọ sí Samaria.
9 At that time there was a prophet of the Lord there, whose name was Oded: and he went out to meet the army that came to Samaria, and said to them: Behold the Lord the God of your fathers being angry with Juda, hath delivered them into your hands, and you have butchered them cruelly, so that your cruelty hath reached up to heaven.
Ṣùgbọ́n wòlíì Olúwa tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Odedi wà níbẹ̀, ó sì jáde lọ láti lọ pàdé ogun nígbà tí ó padà sí Samaria. Ó sì wí fún wọn pé, “Nítorí Olúwa, Ọlọ́run baba yín bínú sí Juda ó sì fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin pa wọ́n ní ìpa oró tí ó de òkè ọ̀run.
10 Moreover you have a mind to keep under the children of Juda and Jerusalem for your bondmen and bondwomen, which ought not to be done: for you have sinned in this against the Lord your God.
Nísinsin yìí, ẹ̀yin ń pète láti mú ọkùnrin àti obìnrin Juda àti Jerusalẹmu ṣe gẹ́gẹ́ bí ẹrú yín, ẹ̀yin kò ha jẹ̀bi Olúwa Ọlọ́run yín, àní ẹ̀yin?
11 But hear ye my counsel, and release the captives that you have brought of your brethren, because a great indignation of the Lord hangeth over you.
Nísinsin yìí ẹ gbọ́ tèmi! Ẹ rán àwọn ìgbèkùn tí ẹ̀yin ti mú gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹlẹ́wọ̀n padà nítorí ìbínú kíkan Olúwa ń bẹ lórí yín.”
12 Then some of the chief men of the sons of Ephraim, Azarias the son of Johanan, Barachias the son of Mosollamoth, Ezechias the son of Sellum, and Amasa the son of Adali, stood up against them that came from the war.
Lẹ́yìn náà, díẹ̀ nínú àwọn olórí ní Efraimu, Asariah ọmọ Jehohanani, Berekiah ọmọ Meṣilemoti, Jehiskiah ọmọ Ṣallumu, àti Amasa ọmọ Hadlai, dìde sí àwọn tí o ti ogun náà bọ̀.
13 And they said to them: You shall not bring in the captives hither, lest we sin against the Lord. Why will you add to our sins, and heap up upon our former offences? for the sin is great, and the fierce anger of the Lord hangeth over Israel.
Wọn si wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ mú àwọn ẹlẹ́wọ̀n wá síbí,” “tàbí àwa ti jẹ̀bi níwájú Olúwa, ṣe ẹ̀yin ń gbèrò láti fi kún ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹ̀bi wa ni: nítorí tí ẹ̀bi wa ti tóbi púpọ̀, ìbínú rẹ̀ kíkan sì wà lórí Israẹli.”
14 So the soldiers left the spoils, and all that they had taken, before the princes and all the multitude.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ológun tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n àti ìkógun sílẹ̀ níwájú àwọn ìjòyè àti gbogbo ìjọ ènìyàn.
15 And the men, whom we mentioned above, rose up and took the captives, and with the spoils clothed all them that were naked: and when they had clothed and shed them, and refreshed them with meat and drink, and anointed them because of their labour, and had taken care of them, they set such of them as could not walk, and were feeble, upon beasts, and brought them to Jericho the city of palm trees to their brethren, and they returned to Samaria.
Àwọn ọkùnrin tí a pè pẹ̀lú orúkọ náà sì dìde, wọn sì mú àwọn ìgbèkùn náà, wọ́n sì fi ìkógun náà wọ̀ gbogbo àwọn tí ó wà ní ìhòhò nínú wọn, wọ́n sì wọ̀ wọ́n ní aṣọ, wọ́n sì bọ̀ wọ́n ní bàtà, wọ́n sì fún wọn ní oúnjẹ àti ohun mímu, wọ́n sì fi òróró kùn wọ́n ní ara, wọ́n sì kó gbogbo àwọn tí ó jẹ́ aláìlera nínú wọ́n sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kó wọn padà sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Jeriko, ìlú ọ̀pẹ, wọ́n sì padà sí Samaria.
16 At that time king Achaz sent to the king of the Assyrians asking help.
Ní àkókò ìgbà náà, ọba Ahasi ránṣẹ́ sí ọba Asiria fún ìrànlọ́wọ́.
17 And the Edomites came and slew many of Juda, and took a great booty.
Àwọn ará Edomu sì tún padà wá láti kọlu Juda kí wọn sì kó àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ.
18 The Philistines also spread themselves among the cities of the plains, and to the south of Juda: and they took Bethsames, and Aialon, and Gaderoth, and Socho, and Thamnan, and Gamzo, with their villages, and they dwelt in them.
Nígbà tí àwọn ará Filistini sì ti jagun ní ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n nì àti síhà gúúsù Juda. Wọ́n ṣẹ́gun wọ́n sì gba Beti-Ṣemeṣi, Aijaloni àti Gederoti, àti Soko, Timna, a ri Gimiso, pẹ̀lú ìletò wọn.
19 For the Lord had humbled Juda because of Achaz the king of Juda, for he had stripped it of help, and had contemned the Lord.
Olúwa sì rẹ Juda sílẹ̀ nítorí Ahasi ọba Israẹli, nítorí ó sọ Juda di aláìní ìrànlọ́wọ́, ó sì ṣe ìrékọjá gidigidi sí Olúwa.
20 And he brought, against him Thelgathphalnasar king of the Assyrians, who also afflicted him, and plundered him without any resistance.
Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó fún ní ìpọ́njú dípò ìrànlọ́wọ́.
21 And Achaz stripped the house of the Lord, and the house of the kings, and of the princes, and gave gifts to the king of the Assyrians, and yet it availed him nothing.
Ahasi mú díẹ̀ nínú ìní ilé Olúwa àti láti ilé ọba àti láti ọ̀dọ̀ ọba ó sì fi wọ́n fún ọba Asiria: ṣùgbọ́n èyí kò ràn wọ́n lọ́wọ́.
22 Moreover also in the time of his distress he increased contempt against the Lord: king Achaz himself by himself,
Ní àkókò ìpọ́njú rẹ̀ ọba Ahasi sì di aláìṣòótọ́ sí Olúwa.
23 Sacrificed victims to the gods of Damascus that struck him, and he said: The gods of the kings of Syria help them, and I will appease them with victims, and they will help me; whereas on the contrary they were the ruin of him, and of all Israel.
Ó sì rú ẹbọ sí òrìṣà àwọn Damasku, ẹni tí ó ṣẹ́gun wọn, nítorí ó rò wí pé, “Nítorí àwọn òrìṣà àwọn ọba Siria ti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọn kí ó bà lè ràn mí lọ́wọ́.” Ṣùgbọ́n àwọn ni ìparun rẹ̀ àti ti gbogbo Israẹli.
24 Then Achaz having taken away all the vessels of the house of God, and broken them, shut up the doors of the temple of God, and made himself altars in all the corners of Jerusalem.
Ahasi sì kó gbogbo ohun èlò láti ilé Olúwa jọ ó sì kó wọn lọ. Ó sì ti ìlẹ̀kùn ilé Olúwa ó sì tẹ́ pẹpẹ fún ara rẹ̀ ní gbogbo igun Jerusalẹmu.
25 And in all the cities of Juda he built altars to burn frankincense, and he provoked the Lord the God of his fathers to wrath.
Ní gbogbo ìlú Juda ó sì kọ́ ibi gíga láti sun ẹbọ fún àwọn ọlọ́run mìíràn. Kí ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn bínú.
26 But the rest of his acts, and all his works first and last are written in the book of the kings of Juda and Israel.
Ìyókù iṣẹ́ ìjọba rẹ̀ àti gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Juda àti ti Israẹli.
27 And Achaz slept with his fathers, and they buried him in the city of Jerusalem: for they received him not into the sepulchres of the kings of Israel. And Ezechias his son reigned in his stead.
Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní ìlú Jerusalẹmu ṣùgbọ́n wọn kò mú un wá sínú àwọn isà òkú àwọn ọba Israẹli. Hesekiah ọmọ rẹ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< 2 Chronicles 28 >