< Nehemiah 12 >

1 Now these are the priests and the Levites who ascended with Zerubbabel, the son of Shealtiel, and Jeshua: Seraiah, Jeremiah, Ezra,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
2 Amariah, Malluch, Hattush,
Amariah, Malluki, Hattusi,
3 Shecaniah, Rehum, Meremoth,
Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
4 Iddo, Ginnethon, Abijah,
Iddo, Ginetoni, Abijah,
5 Mijamin, Maadiah, Bilgah,
Mijamini, Moadiah, Bilgah,
6 Shemaiah, and Joiarib, Jedaiah, Sallu, Amok, Hilkiah, Jedaiah.
Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
7 These were the leaders of the priests and of their brothers, in the days of Jeshua.
Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
8 And the Levites, Jeshua, Binnui, Kadmiel, Sherebiah, Judah, Mattaniah, they and their brothers were over the hymns,
Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
9 with Bakbukiah, as well as Hannai, and their brothers, each one in his office.
Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
10 Now Jeshua conceived Joiakim, and Joiakim conceived Eliashib, and Eliashib conceived Joiada,
Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
11 and Joiada conceived Jonathan, and Jonathan conceived Jaddua.
Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
12 And in the days of Joiakim, the priests and the leaders of the families were: of Seraiah, Meraiah; of Jeremiah, Hananiah;
Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
13 of Ezra, Meshullam; of Amariah, Jehohanan;
ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
14 of Maluchi, Jonathan; of Shebaniah, Joseph;
ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
15 of Harim, Adna; of Meraioth, Helkai;
ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
16 of Adaiah, Zechariah; of Ginnethon, Meshullam;
ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
17 of Abijah, Zichri; of Mijamin and Moadiah, Piltai;
ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
18 of Bilgah, Shammua; of Shemaiah, Jehonathan;
ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
19 of Joiarib, Mattenai; of Jedaiah, Uzzi;
ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
20 of Sallai, Kallai; of Amok, Eber;
ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
21 of Hilkiah, Hashabiah; of Jedaiah, Nethanel.
ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
22 The Levites, in the days of Eliashib, and Joiada, and Johanan, and Jaddua, and the priests, were written according to the leaders of the families, during the reign of Darius the Persian.
Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
23 The sons of Levi, according to the leaders of the families, were written in the book of the words of those days, even to the days of Johanan, the son of Eliashib.
Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
24 Now the leaders of the Levites were Hashabiah, Sherebiah, and Jeshua, the son of Kadmiel, and their brothers, in their turns, so that they would praise and confess, according to the precept of David, the man of God. And they served equally and in order.
Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
25 Mattaniah, and Bakbukiah, Obadiah, Meshullam, Talmon, Akkub, were keepers of the gates and of the vestibules before the gates.
Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
26 These were in the days of Joiakim, the son of Jeshua, the son of Jozadak, and in the days of Nehemiah, the governor, and of Ezra, the priest and scribe.
Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
27 Now at the dedication of the wall of Jerusalem, they sought the Levites from all their places, so that they might bring them to Jerusalem, and so that they might keep the dedication, and rejoice with thanksgiving, and with singing, and with cymbals, psalteries, and lyres.
Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
28 Now the sons of the singing men were gathered from the plains surrounding Jerusalem, and from the villages of Netophati,
A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
29 and from the house of Gilgal, and from the regions of Geba and Azmaveth. For the singing men had built villages for themselves around Jerusalem.
láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
30 And the priests and the Levites were cleansed, and they cleansed the people, and the gates, and the wall.
Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
31 Then I caused the leaders of Judah to ascend the wall, and I appointed two great choirs to give praise. And they went to the right upon the wall, toward the dung gate.
Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
32 And after them went Hoshaiah, and one half part of the leadership of Judah,
Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
33 and Azariah, Ezra, and Meshullam,
àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
34 Judah, and Benjamin, and Shemaiah, and Jeremiah.
Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
35 And some of the sons of the priests went forth with trumpets: Zachariah, the son of Jonathan, the son of Shemaiah, the son of Mattaniah, the son of Micaiah, the son of Zaccur, the son of Asaph.
pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
36 And his brothers, Shemaiah, and Azarel, Milalai, Gilalai, Maai, Nethanel, and Judah, and Hanani, went forth with the canticles of David, the man of God. And Ezra, the scribe, was before them at the fountain gate.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
37 And opposite them, they ascended by the steps of the city of David, at the ascent of the wall above the house of David, and as far as the water gate to the east.
Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
38 And the second choir of those who gave thanks went forth on the opposite side, and I went after them, and one half part of the people were upon the wall, and upon the tower of the furnaces, as far as the widest wall,
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
39 and above the gate of Ephraim, and above the ancient gate, and above the fish gate, and the tower of Hananel, and the tower of Hamath, and as far as the flock gate. And they stood still at the watch gate.
kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
40 And the two choirs of those who gave praise stood still at the house of God, with myself and one half part of the magistrates who were with me.
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
41 And the priests, Eliakim, Maaseiah, Mijamin, Micaiah, Elioenai, Zechariah, Hananiah, went forth with trumpets,
àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
42 with Maaseiah, and Shemaiah, and Eleazar, and Uzzi, and Jehohanan, and Malchijah, and Elam, and Ezer. And the singers were singing clearly, and Jezrahiah was their foremost leader.
Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
43 And on that day, they immolated great sacrifices, and they rejoiced. For God had caused them to rejoice with great joy. And their wives and children also were glad. And the rejoicing of Jerusalem was heard from far away.
Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
44 On that day also, they enrolled men over the storehouses of the treasury, for the libations, and for the first-fruits, and for the tithes, so that the leaders of the city might bring these in, by them, with proper thanksgiving, for the priests and the Levites. For Judah was rejoicing in the priests and the Levites who were assisting.
Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
45 And they kept the vigil of their God, and the vigil of expiation, with the singing men and the gatekeepers, in accord with the precept of David, and of Solomon, his son.
Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
46 For in the days of David and Asaph, from the beginning, there were leaders appointed over the singers, to give praise in verses, and to confess to God.
Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
47 And all of Israel, in the days of Zerubbabel, and in the days of Nehemiah, gave portions to the singing men and to the gatekeepers, for each day, and they sanctified the Levites, and the Levites sanctified the sons of Aaron.
Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.

< Nehemiah 12 >