< Judges 12 >

1 And behold, a sedition rose up in Ephraim. Then, while passing by toward the north, they said to Jephthah: “When you were going to fight against the sons of Ammon, why were you unwilling to summon us, so that we might go with you? Therefore, we will burn down your house.”
Àwọn ọkùnrin Efraimu pe àwọn ológun wọn jáde, wọ́n sì rékọjá sí ìhà àríwá, wọ́n sì bi Jefta pé, “Èéṣe tí o fi lọ bá àwọn ará Ammoni jagun láì ké sí wa láti bá ọ lọ? Àwa yóò sun ilé rẹ mọ́ ọ lórí.”
2 And he answered them: “I and my people were in a great conflict against the sons of Ammon. And I called you, so that you might offer assistance to me. And you were not willing to do so.
Jefta dáhùn pé, “Èmi àti àwọn ènìyàn ní ìyọnu ńlá pẹ̀lú àwọn ará Ammoni, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo pè yín, ẹ̀yin kò gbà mí sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn.
3 And discerning this, I put my life in my own hands, and I crossed to the sons of Ammon, and the Lord delivered them into my hands. What am I guilty of, that you would rise up in battle against me?”
Nígbà tí mo rí i pé ẹ̀yin kò gbà mí, mo fi ẹ̀mí mi wéwu. Mó sì gòkè lọ láti bá àwọn ará Ammoni jà, Olúwa sì fún mi ní ìṣẹ́gun lórí wọn, èéṣe báyìí tí ẹ fi dìde wá lónìí láti bá mi jà?”
4 And so, calling to himself all the men of Gilead, he fought against Ephraim. And the men of Gilead struck down Ephraim, because he had said, “Gilead is a fugitive from Ephraim, and he lives in the midst of Ephraim and Manasseh.”
Nígbà náà ni Jefta kó gbogbo ọkùnrin Gileadi jọ, ó sì bá Efraimu jà. Àwọn ọkùnrin Gileadi sì kọlù Efraimu, nítorí wọ́n ti sọtẹ́lẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ará Gileadi jẹ́ àsáwọ̀ àwọn ará Efraimu àti ti Manase.”
5 And the Gileadites occupied the fords of the Jordan, along which Ephraim was to return. And when anyone from the number of Ephraim had arrived, fleeing, and had said, “I beg that you permit me to pass,” the Gileadites would say to him, “Could you be an Ephraimite?” And if he said, “I am not,”
Àwọn ará Gileadi gba à bá wọ odò Jordani tí wọ́n máa gbà lọ sí Efraimu, nígbàkígbà tí àwọn ará Efraimu bá wí pé, “Jẹ́ kí ń sálọ sí òkè,” lọ́hùn ún àwọn ará Gileadi yóò bi í pé, “Ṣé ará Efraimu ni ìwọ ń ṣe?” Tí ó bá wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́,”
6 they would ask him, then say ‘Shibboleth,’ which is translated as ‘ear of grain.’ But he would answer ‘Sibboleth,’ not being able to express the word for an ear of grain in the same letters. And immediately apprehending him, they would cut his throat, at the same crossing point of the Jordan. And in that time of Ephraim, forty-two thousand fell.
wọ́n ó wí fún un pé, “Ó dá à wí pé ‘Ṣibolẹti.’” Tí ó bá ní, “Sibolẹti,” torí pé kò ní mọ̀ ọ́n pé dáradára, wọ́n á mú un wọn, a sì pa á ni à bá wọ odò Jordani. Àwọn ará Efraimu tí wọn pa ní àkókò yìí jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógójì ọkùnrin.
7 And so Jephthah, the Gileadite, judged Israel for six years. And he died, and he was buried in his city in Gilead.
Jefta ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́fà. Lẹ́yìn náà Jefta ará Gileadi kú, wọ́n sì sin ín sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú Gileadi.
8 After him, Ibzan of Bethlehem judged Israel.
Lẹ́yìn Jefta, Ibsani ará Bẹtilẹhẹmu ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
9 He had thirty sons, and the same number of daughters, whom he sent away to be given to husbands. And he accepted wives for his sons of the same number, bringing them into his house. And he judged Israel for seven years.
Ó ní ọgbọ̀n ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ibsani ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ọdún méje.
10 And he died, and he was buried in Bethlehem.
Lẹ́yìn náà ni Ibsani kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹtilẹhẹmu.
11 After him succeeded Elon, a Zebulunite. And he judged Israel for ten years.
Lẹ́yìn rẹ̀, Eloni ti ẹ̀yà Sebuluni ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́wàá.
12 And he died, and he was buried in Zebulun.
Eloni sì kú, wọ́n sì sin ín sí Aijaloni ní ilẹ̀ Sebuluni.
13 After him, Abdon, the son of Hillel, a Pirathonite, judged Israel.
Lẹ́yìn rẹ̀ ni Abdoni ọmọ Hileli tí Piratoni n ṣe àkóso Israẹli.
14 And he had forty sons, and from them thirty grandsons, all riding upon seventy young donkeys. And he judged Israel for eight years.
Òun ní ogójì ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọ ọmọ àwọn tí ó ń gun àádọ́rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ó ṣe ìdájọ́ Israẹli ní ọdún mẹ́jọ.
15 And he died, and he was buried at Pirathon, in the land of Ephraim, on the mountain of Amalek.
Abdoni ọmọ Hileli sì kú, wọ́n sin ín sí Piratoni ní ilé Efraimu ní ìlú òkè àwọn ará Amaleki.

< Judges 12 >