< Jeremiah 50 >

1 The word that the Lord has spoken about Babylon and about the land of the Chaldeans, by the hand of Jeremiah the prophet.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 “Announce it among the Gentiles, and make it known. Lift up a sign. Proclaim it and do not conceal it. Say this: ‘Babylon has been captured. Bel has been confounded. Merodach has been conquered. Their graven things have been confounded. Their idols have not survived.’
“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 For a nation has ascended against her from the north, which will set her land in desolation. And there will be no one who may live within it, from man even to beast. For they have been removed and have gone away.
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
4 In those days and in that time, says the Lord, the sons of Israel will advance, they and the sons of Judah together. Weeping as they walk, they will hurry on, and they will seek the Lord their God.
“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 They will ask the way to Zion; their faces will be set toward this place. They will arrive and will be joined to the Lord by an everlasting covenant, which nothing will wipe away into oblivion.
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
6 My people have become a lost flock. Their shepherds have led them astray and have caused them to wander in the mountains. They have crossed from mountain to hill. They have forgotten their resting place.
“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 All whom they have found, they have devoured. And their enemies have said: ‘We have not sinned. For it is they who have sinned against the Lord, the beauty of justice, and against the Lord, the hope of their fathers.’
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 Withdraw from the midst of Babylon, and go forth from the land of the Chaldeans. And be like young goats before the flock.
“Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 For behold, I am raising up, and I will lead against Babylon, a congregation of great nations from the land of the north. And they will be prepared against her, and from there she will be taken. Their arrows, like those of a strong man, a killer, will not return empty.
Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
10 And Chaldea will become a prey. All who lay waste to her will be filled, says the Lord.
A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
11 For you exult and you speak great things, plundering my inheritance. For you have spread out like calves upon the grass, and you have bellowed like bulls.
“Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Your mother has been exceedingly shamed, and she who bore you has become equal to the dust. Behold, she will be the last among the nations, a desert, impassable and dry.
Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 By the wrath of the Lord, it will not be inhabited. Instead, it will be entirely desolate. Everyone who passes by Babylon will be stupefied and will hiss over all her wounds.
Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 Prepare yourselves against Babylon, on every side, all you who bend the bow. Make war against her! You should not spare the arrows, for she has sinned against the Lord.
“Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Cry out against her! For where she has put forth a hand, her foundations have fallen, her walls have been destroyed. For it is the vengeance of the Lord. Take vengeance against her! Just as she has done, do so to her.
Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Destroy the founder from Babylon, and the one who holds the sickle in the time of harvest. Before the face of the sword of the dove, each one will turn back to his people, and every one will flee to his own land.
Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Israel is a scattered flock. The lions have driven him away. First, the king of Assyria devoured him. And last, this Nebuchadnezzar, the king of Babylon, has taken away his bones.
“Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Because of this, thus says the Lord of hosts, the God of Israel: Behold, I will visit the king of Babylon and his land, just as I have visited the king of Assyria.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 And I will lead back Israel to his habitation. And he will pasture on Carmel and Bashan, and his soul will be satiated at mount Ephraim and Gilead.
Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
20 In those days and at that time, says the Lord, the iniquity of Israel will be sought, and there will be none. And the sin of Judah will be sought, and none will be found. For I will be forgiving to them, whom I will leave behind.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 Ascend against the land of the rulers, and visit against its inhabitants! Scatter and destroy whatever has been left behind them, says the Lord, and act according to all that I have instructed you.
“Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 A voice of war in the land, and great destruction!
Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 How has the mallet of the entire earth been broken and crushed? How has Babylon been turned into a desert among the nations?
Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 I have ensnared you, and you have been captured, O Babylon, and you did not realize it. You have been discovered and seized, because you provoked the Lord.
Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 The Lord has opened his storehouse, and he has brought forth the instruments of his wrath. For there is work for the Lord, the God of hosts, within the land of the Chaldeans.
Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Advance against her from the furthest regions! Open, so that those who will trample her may go out! Take stones from the road, and gather them into piles, and destroy her. And let there be nothing left of her.
Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Scatter all her strong ones. Let them descend to the slaughter. Woe to them! For their day has arrived, the time of their visitation.
Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 It is the voice of those who are fleeing and of those who have escaped from the land of Babylon: to announce in Zion the revenge of the Lord our God, the revenge of his Temple.
Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 Announce it to the many in Babylon, to all who bend the bow. Stand together against her all around, and let no one escape. Repay her according to her work. In accord with all that she has done, do to her. For she has raised herself up against the Lord, against the Holy One of Israel.
“Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 For this reason, her young men will fall in her streets. And all her men of war will be silenced, in that day, says the Lord.
Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
31 Behold, I am against you, O proud one, says the Lord, the God of hosts. For your day has arrived, the time of your visitation.
“Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 And the proud one will fall and be ruined. And there will be no one who may lift him up. And I will kindle a fire in his cities, and it will devour everything around him.”
Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
33 Thus says the Lord of hosts: “The sons of Israel and the sons of Judah have endured calumny together. All who have seized them are holding them and refusing to release them.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Their redeemer is strong. The Lord of hosts is his name. He will defend their case in judgment, so that he may terrify the land and disturb the inhabitants of Babylon.
Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 A sword is for the Chaldeans, says the Lord, and for the inhabitants of Babylon, and for her leaders, and for her wise ones.
“Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 A sword is for her diviners, who will be fooled. A sword is for her strong ones, who will be afraid.
Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 A sword is for their horses, and for their chariots, and for all the common people who are in her midst. And they will be like women. A sword is for her storehouses, and they will be plundered.
Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 A drought is over her waters, and they will be dried up. For it is a land of graven images, and they glory in portents.
Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 Because of this, dragons will live there with the fig fauns, and ostriches will live in it. And it will no longer be inhabited, even in perpetuity, nor will it be raised up, even from generation to generation.
“Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Just as the Lord overthrew Sodom and Gomorrah, and their neighboring towns, says the Lord, no man will live there, and a son of man will not tend it.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
41 Behold, a people arrives from the north, and a great nation. And many kings will rise up from the ends of the earth.
“Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 They will take up the bow and the shield. They are cruel and merciless. Their voice will sound out, like the sea, and they will ride upon horses, like a man prepared for battle against you, O daughter of Babylon.
Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 The king of Babylon has heard the report about them, and his hands have been weakened. Anguish has overtaken him, like the pains of a woman giving birth.
Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Behold, he will ascend like a lion from the arrogance of the Jordan to the robust beauty. For I will cause him to rush upon her suddenly. And who will be the elect one, whom I may appoint over her? For who is like me? And who can endure me? And who is that pastor who can withstand my countenance?”
Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Because of this, listen to the counsel of the Lord, which he has conceived in his mind against Babylon, and to his thoughts, which he has devised against the land of the Chaldeans: “Certainly the little ones of the flocks will pull them down, unless their habitation will have been destroyed with them.
Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
46 At the voice of the captivity of Babylon, the earth has been moved, and an outcry has been heard among the nations.”
Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Jeremiah 50 >