< Chronicles I 4 >

1 And the sons of Juda; Phares, Esrom, and Charmi, and Or, Subal,
Àwọn ọmọ Juda: Peresi, Hesroni, Karmi, Huri àti Ṣobali.
2 and Rada his son; and Subal begot Jeth; and Jeth begot Achimai, and Laad: these [are] the generations of the Arathites.
Reaiah ọmọ Ṣobali ni baba Jahati, àti Jahati baba Ahumai àti Lahadi. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀yà ará Sorati.
3 And these [are] the sons of Aetam; Jezrael and Jesman, and Jebdas: and their sister's name [was] Eselebbon.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Etamu: Jesreeli, Iṣima, Idbaṣi, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Haseleponi
4 And Phanuel the father of Gedor, and Jazer the father of Osan: these [are] the sons of Or, the firstborn of Ephratha, the father of Baethalaen.
Penueli sì ni baba Gedori, àti Eseri baba Huṣa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata àti baba Bẹtilẹhẹmu.
5 And Asur the father of Thecoe had two wives, Aoda and Thoada.
Aṣihuri baba Tekoa sì ní aya méjì, Hela àti Naara.
6 And Aoda bore to him Ochaia, and Ephal, and Thaeman, and Aasther: all these [were] the sons of Aoda.
Naara sì bí Ahussamu, Heferi Temeni àti Haaṣtari. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Naara.
7 And the sons of Thoada; Sereth, and Saar, and Esthanam.
Àwọn ọmọ Hela: Sereti Sohari, Etani,
8 And Coe begot Enob, and Sabatha, and the progeny of the brother of Rechab, the son of Jarin.
àti Kosi ẹni tí ó jẹ́ baba Anubu àti Sobeba àti ti àwọn ẹ̀yà Aharheli ọmọ Harumu.
9 And Igabes was more famous than his brethren; and his mother called his name Igabes, saying, I have born as a sorrowful one.
Jabesi sì ní ọlá ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jabesi wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
10 And Igabes called on the God of Israel, saying, O that you would indeed bless me, and enlarge my coasts, and that your hand might be with me, and that you would make me know that you will not grieve me! And God granted him all that he asked.
Jabesi sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Israẹli wí pé, “Háà, Ìwọ yóò bùkún fún mi, ìwọ yóò sì mú agbègbè mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mi mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
11 And Chaleb the father of Ascha begot Machir; he [was] the father of Assathon.
Kelubu arákùnrin Ṣuha, sì jẹ́ baba Mehiri, ẹni tí ó jẹ́ baba Eṣtoni.
12 He begot Bathraias, and Bessee, and Thaeman the founder of the city of Naas the brother of Eselom the Kenezite: these [were] the men of Rechab.
Eṣtoni sì jẹ́ baba Beti-Rafa, Pasea àti Tehina ti baba ìlú Nahaṣi. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Reka.
13 And the sons of Kenez; Gothoniel, and Saraia: and the sons of Gothoniel; Athath.
Àwọn ọmọ Kenasi: Otnieli àti Seraiah. Àwọn ọmọ Otnieli: Hatati àti Meonotai.
14 And Manathi begot Gophera: and Saraia begot Jobab, the father of Ageaddair, for they were artificers.
Meonotai sì ni baba Ofira. Seraiah sì jẹ́ baba Joabu, baba Geharaṣinu. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn oníṣọ̀nà ní ìwọ̀n.
15 And the sons of Chaleb the son of Jephonne; Er, Ada, and Noom: and the sons of Ada, Kenez.
Àwọn ọmọ Kalebu ọmọ Jefunne: Iru, Ela, àti Naamu. Àwọn ọmọ Ela: Kenasi.
16 And the sons of Aleel, Zib, and Zepha, and Thiria, and Eserel.
Àwọn ọmọ Jehaleeli: Sifi, àti Sifa, Tiria àti Asareeli.
17 And the sons of Esri; Jether, Morad, and Apher, and Jamon: and Jether begot Maron, and Semei, and Jesba the father of Esthaemon.
Àwọn ọmọ Esra: Jeteri, Meredi, Eferi àti Jaloni. Ọ̀kan lára àwọn aya Meredi sì bí Miriamu, Ṣammai àti Iṣba baba Eṣitemoa.
18 And his wife, that [is] Adia, bore Jared the father of Gedor, and Aber the father of Sochon, and Chetiel the father of Zamon: and these [are] the sons of Betthia the daughter of Pharao, whom Mored took.
Aya rẹ̀ láti ẹ̀yà Juda sì bí Jaredi baba Gedori, àti Heberi baba Soko àti Jekutieli baba Sanoa. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọbìnrin Farao Bitia, ẹni ti Meredi ti fẹ́.
19 And the sons of the wife of Iduia the sister of Nachaim the father of Keila; Garmi, and Esthaemon the Nochathite.
Àwọn ọmọ aya Hodiah arábìnrin Nahamu, baba Keila ará Garimu, àti Eṣitemoa àwọn ará Maakati.
20 And the sons of Semon; Amnon, and Ana the son of Phana, and Inon: and the sons of Sei, Zoan, and the sons of Zoab.
Àwọn ọmọ Ṣimoni: Amnoni, Rina, Beni-Hanani àti Tiloni. Àwọn ọmọ Iṣi: Soheti àti Beni-Soheti.
21 The sons of Selom the son of Juda; Er the father of Lechab, and Laada the father of Marisa, and the offspring of the family of Ephrathabac [belonging to] the house of Esoba.
Àwọn ọmọ Ṣela ọmọ Juda: Eri baba Leka, Lada baba Meraṣa àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń hun aṣọ oníṣẹ́ ní Beti-Aṣibea.
22 And Joakim, and the men of Chozeba, and Joas, and Saraph, who lived in Moab, and he changed their names to Abederin and Athukiim.
Jokimu, ọkùnrin Koseba, àti Joaṣi àti Sarafi, olórí ní Moabu àti Jaṣubi Lehemu. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́.)
23 These [are] the potters who lived in Ataim and Gadira with the king: they grew strong in his kingdom, and lived there.
Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Netaimu àti Gedera; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ fún ọba.
24 The sons of Semeon; Namuel, and Jamin, Jarib, Zares, Saul:
Àwọn ọmọ Simeoni: Nemueli, Jamini, Jaribi, Sera àti Saulu;
25 Salem his son, Mabasam his son, Masma his son:
Ṣallumu sì jẹ́ ọmọ Saulu, Mibsamu ọmọ rẹ̀ Miṣima ọmọ rẹ̀.
26 Amuel his son, Sabud his son, Zacchur his son, Semei his son.
Àwọn ọmọ Miṣima: Hamueli ọmọ rẹ̀ Sakkuri ọmọ rẹ̀ àti Ṣimei ọmọ rẹ̀.
27 Semei [had] sixteen sons, and six daughters; and his brethren had not many sons, neither did all their families multiply as the sons of Juda.
Ṣimei sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Juda.
28 And they lived in Bersabee, and Molada, and in Esersual,
Wọ́n sì ń gbé ní Beerṣeba, Molada, Hasari-Ṣuali,
29 and in Balaa, and in Aesem, and in Tholad,
àti ní Biliha, àti ní Esemu, àti ní Toladi,
30 and in Bathuel, and in Herma, and in Sikelag,
Betueli, Horma, Siklagi,
31 and in Baethmarimoth, and Hemisuseosin, and the house of Baruseorim: these [were] their cities until [the time of] king David.
Beti-Markaboti Hormah; Hasari Susimu, Beti-Biri àti Ṣaraimi. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dafidi,
32 And their villages [were] Aetan, and En, Remnon, and Thocca, and Aesar, five cities.
agbègbè ìlú wọn ni Etamu, Aini, Rimoni, Tokeni, Aṣani àwọn ìlú márùn-ún,
33 And all their villages [were] round about these cities, as far as Baal: this [was] their possession, and their distribution.
àti gbogbo ìletò wọn, tí ó wà yí ìlú náà ká, dé Baali. Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn. Àti ìtàn ìdílé wọ́n.
34 And Mosobab, and Jemoloch, and Josia the son of Amasia;
Meṣobabu àti Jamleki, Josa ọmọ Amasiah,
35 and Joel, and Jeu the son of Asabia, the son of Sarau, the son of Asiel;
Joẹli, Jehu ọmọ Josibiah, ọmọ Seraiah, ọmọ Asieli,
36 and Elionai, and Jocaba, and Jasuia, and Asaia, and Jediel, and Ismael, and Banaias;
àti pẹ̀lú Elioenai, Jaakoba, Jeṣohaiah, Asaiah, Adieli, Jesimieli, Benaiah,
37 and Zuza the son of Saphai, the son of Alon, the son of Jedia, the son of Semri, the son of Samaias.
àti Sisa ọmọ Ṣifi ọmọ Alloni, ọmọ Jedaiah, ọmọ Ṣimri ọmọ Ṣemaiah.
38 These went by the names of princes in their families, and they increased abundantly in their fathers' households.
Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ sí i gidigidi,
39 And they went till they came to Gerara, to the east of Gai, to seek pasture for their cattle.
wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gedori. Lọ títí dé ìlà-oòrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn.
40 And they found abundant and good pastures, and the land before them [was] wide, and [there was] peace and quietness; for [there were] some of the children of Cham who lived there before.
Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ọmọ Hamu ni ó ti ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
41 And these who are written by name came in the days of Ezekias king of Juda, and they struck the people's houses, and the Minaeans whom they found there, and utterly destroyed them until this day: and they lived in their place, because [there was] pasture there for their cattle.
Àwọn ọkùnrin tí a kọ orúkọ rẹ̀ sókè, dé ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Wọ́n sì kọlu àwọn ará Hamu ní àgọ́ wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Mehuni tí a rí níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátápátá títí di òní yìí. Wọ́n sì ń gbé ní ipò wọn, nítorí pé koríko ń bẹ níbẹ̀ fún agbo ẹran wọn.
42 And some of them, [even] of the sons of Symeon, went to mount Seir, [even] five hundred men; and Phalaettia, and Noadia, and Raphaia, and Oziel, sons of Jesi, [were] their rulers.
Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Simeoni, lábẹ́ ìdarí pẹ̀lú Pelatiah, Neariah, Refaiah àti Usieli, àwọn ọmọ Iṣi, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Seiri.
43 And they struck the remnant that were left of Amalec, until this day.
Wọ́n sì pa àwọn ará Amaleki tí ó kù, àwọn tí ó ti sálà, wọ́n sì ti ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.

< Chronicles I 4 >