< Proverbs 23 >

1 When you sit to eat with a ruler, consider diligently what is before you;
Nígbà tí ìwọ bá jókòó láti bá ìjòyè jẹun, kíyèsi ohun tí ó wà níwájú rẹ gidigidi.
2 put a knife to your throat if you are a man given to appetite.
Ìwọ a sì fi ọ̀bẹ lé ara rẹ ní ọ̀fun, bí ìwọ bá jẹ́ òkúndùn ènìyàn.
3 Do not be desirous of his dainties, since they are deceitful food.
Má ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀: nítorí pé oúnjẹ ẹ̀tàn ni.
4 Do not weary yourself to be rich. In your wisdom, show restraint.
Má ṣe ṣe làálàá láti lọ́rọ̀: ṣíwọ́ kúrò nínú ọgbọ́n ara rẹ.
5 Why do you set your eyes on that which is not? For it certainly sprouts wings like an eagle and flies in the sky.
Ìwọ ó ha fi ojú rẹ lépa ohun tí kò sí? Nítorí tí ọ̀rọ̀ hu ìyẹ́ apá fún ara rẹ̀, ó sì ń fò bí idì ní ojú ọ̀run.
6 Do not eat the food of him who has a stingy eye, and do not crave his delicacies,
Má ṣe jẹ oúnjẹ ẹni tí ó háwọ́, bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe fẹ́ oúnjẹ dídùn rẹ̀.
7 for as he thinks about the cost, so he is. “Eat and drink!” he says to you, but his heart is not with you.
Nítorí pé bí ẹni tí ń ṣírò ní ọkàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí: “Máa jẹ, kí o sì máa mu,” ni ó ń wí fún ọ; ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ kò pẹ̀lú rẹ.
8 You will vomit up the morsel which you have eaten and waste your pleasant words.
Òkèlè tí ìwọ jẹ ni ìwọ ó pọ̀ jáde, ìwọ a sì sọ ọ̀rọ̀ dídùn rẹ̀ nù.
9 Do not speak in the ears of a fool, for he will despise the wisdom of your words.
Má ṣe sọ̀rọ̀ ní etí aṣiwèrè; nítorí tí yóò gan ọgbọ́n ọ̀rọ̀ rẹ.
10 Do not move the ancient boundary stone. Do not encroach on the fields of the fatherless,
Má ṣe ṣí ààlà àtijọ́ kúrò; má sì ṣe bọ́ sínú oko aláìní baba.
11 for their Defender is strong. He will plead their case against you.
Nítorí pé Olùràpadà wọn lágbára; yóò gba ìjà wọn jà sí ọ.
12 Apply your heart to instruction, and your ears to the words of knowledge.
Fi àyà sí ẹ̀kọ́, àti etí rẹ sí ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
13 Do not withhold correction from a child. If you punish him with the rod, he will not die.
Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé, nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.
14 Punish him with the rod, and save his soul from Sheol (Sheol h7585).
Bí ìwọ fi pàṣán nà án, ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run àpáàdì. (Sheol h7585)
15 My son, if your heart is wise, then my heart will be glad, even mine.
Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n, ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.
16 Yes, my heart will rejoice when your lips speak what is right.
Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.
17 Do not let your heart envy sinners, but rather fear the LORD all day long.
Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa, ní ọjọ́ gbogbo.
18 Indeed surely there is a future hope, and your hope will not be cut off.
Nítorí pé ìgbẹ̀yìn ń bẹ nítòótọ́; ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.
19 Listen, my son, and be wise, and keep your heart on the right path!
Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n, kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.
20 Do not be among ones drinking too much wine, or those who gorge themselves on meat;
Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí; àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;
21 for the drunkard and the glutton shall become poor; and drowsiness clothes them in rags.
nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di tálákà; ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.
22 Listen to your father who gave you life, and do not despise your mother when she is old.
Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ, má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó.
23 Buy the truth, and do not sell it. Get wisdom, discipline, and understanding.
Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á; ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́ àti òye.
24 The father of the righteous has great joy. Whoever fathers a wise child delights in him.
Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi: ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n, yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.
25 Let your father and your mother be glad! Let her who bore you rejoice!
Jẹ́ kí baba rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀, sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.
26 My son, give me your heart; and let your eyes keep in my ways.
Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi, kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú dídùn sí ọ̀nà mi.
27 For a prostitute is a deep pit; and a wayward wife is a narrow well.
Nítorí pé panṣágà obìnrin ọ̀gbun jíjìn ni; àti àjèjì obìnrin kànga híhá ni.
28 Yes, she lies in wait like a robber, and increases the unfaithful among men.
Òun á sì ba ní bùba bí olè, a sì sọ àwọn olùrékọjá di púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn.
29 Who has woe? Who has sorrow? Who has strife? Who has complaints? Who has needless bruises? Who has bloodshot eyes?
Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́? Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni asọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?
30 Those who stay long at the wine; those who go to seek out mixed wine.
Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí wáìnì; àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.
31 Do not look at the wine when it is red, when it sparkles in the cup, when it goes down smoothly.
Ìwọ má ṣe wò ọtí wáìnì nígbà tí ó pọ́n, nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago, tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.
32 In the end, it bites like a snake, and poisons like a viper.
Níkẹyìn òun á bu ni ṣán bí ejò, a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.
33 Your eyes will see strange things, and your mind will imagine confusing things.
Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin, àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ̀ àyídáyidà.
34 Yes, you will be as he who lies down in the middle of the sea, or as he who lies on top of the rigging:
Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárín Òkun, tàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.
35 “They hit me, and I was not hurt! They beat me, and I do not feel it! When will I wake up? I can do it again. I will look for more.”
Ìwọ ó sì wí pé, “Wọ́n lù mí; kò dùn mí; wọ́n lù mí, èmi kò sì mọ̀: nígbà wo ni èmi ó jí? Èmi ó tún máa wá òmíràn láti mu.”

< Proverbs 23 >