< Lamentations 3 >

1 I am the man who has seen affliction by the rod of his wrath.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 He has led me and caused me to walk in darkness, and not in light.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Surely he turns his hand against me again and again all day long.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 He has made my flesh and my skin old. He has broken my bones.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 He has built against me, and surrounded me with bitterness and hardship.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 He has made me dwell in dark places, as those who have been long dead.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 He has walled me about, so that I cannot go out. He has made my chain heavy.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Yes, when I cry, and call for help, he shuts out my prayer.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 He has walled up my ways with cut stone. He has made my paths crooked.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 He is to me as a bear lying in wait, as a lion in hiding.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 He has turned away my path, and pulled me in pieces. He has made me desolate.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 He has bent his bow, and set me as a mark for the arrow.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 He has caused the shafts of his quiver to enter into my kidneys.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 I have become a derision to all my people, and their song all day long.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 He has filled me with bitterness. He has stuffed me with wormwood.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 He has also broken my teeth with gravel. He has covered me with ashes.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 You have removed my soul far away from peace. I forgot prosperity.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 I said, “My strength has perished, along with my expectation from the LORD.”
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Remember my affliction and my misery, the wormwood and the bitterness.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 My soul still remembers them, and is bowed down within me.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 This I recall to my mind; therefore I have hope.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 It is because of the LORD’s loving kindnesses that we are not consumed, because his mercies do not fail.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 They are new every morning. Great is your faithfulness.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 “The LORD is my portion,” says my soul. “Therefore I will hope in him.”
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 The LORD is good to those who wait for him, to the soul who seeks him.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 It is good that a man should hope and quietly wait for the salvation of the LORD.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 It is good for a man that he bear the yoke in his youth.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Let him sit alone and keep silence, because he has laid it on him.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Let him put his mouth in the dust, if it is so that there may be hope.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Let him give his cheek to him who strikes him. Let him be filled full of reproach.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 For the Lord will not cast off forever.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 For though he causes grief, yet he will have compassion according to the multitude of his loving kindnesses.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 For he does not afflict willingly, nor grieve the children of men.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 To crush under foot all the prisoners of the earth,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 to turn away the right of a man before the face of the Most High,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 to subvert a man in his cause, the Lord does not approve.
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Who is he who says, and it comes to pass, when the Lord does not command it?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Does not evil and good come out of the mouth of the Most High?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Why should a living man complain, a man for the punishment of his sins?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Let us search and try our ways, and turn again to the LORD.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Let’s lift up our heart with our hands to God in the heavens.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 “We have transgressed and have rebelled. You have not pardoned.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 “You have covered us with anger and pursued us. You have killed. You have not pitied.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 You have covered yourself with a cloud, so that no prayer can pass through.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 You have made us an off-scouring and refuse in the middle of the peoples.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 “All our enemies have opened their mouth wide against us.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Terror and the pit have come on us, devastation and destruction.”
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 My eye runs down with streams of water, for the destruction of the daughter of my people.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 My eye pours down and does not cease, without any intermission,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 until the LORD looks down, and sees from heaven.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 My eye affects my soul, because of all the daughters of my city.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 They have chased me relentlessly like a bird, those who are my enemies without cause.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 They have cut off my life in the dungeon, and have cast a stone on me.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Waters flowed over my head. I said, “I am cut off.”
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 I called on your name, LORD, out of the lowest dungeon.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 You heard my voice: “Do not hide your ear from my sighing, and my cry.”
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 You came near in the day that I called on you. You said, “Do not be afraid.”
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Lord, you have pleaded the causes of my soul. You have redeemed my life.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 LORD, you have seen my wrong. Judge my cause.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 You have seen all their vengeance and all their plans against me.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 You have heard their reproach, LORD, and all their plans against me,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 the lips of those that rose up against me, and their plots against me all day long.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 You see their sitting down and their rising up. I am their song.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 You will pay them back, LORD, according to the work of their hands.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 You will give them hardness of heart, your curse to them.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 You will pursue them in anger, and destroy them from under the heavens of the LORD.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

< Lamentations 3 >