< Johannes 16 >

1 "Dette har jeg talt til eder, for at I ikke skulle forarges.
“Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, kí a má ba à mú yín yapa kúrò.
2 De skulle udelukke eder af Synagogerne, ja, den Tid skal komme, at hver den, som slår eder ihjel, skal mene, at han viser Gud en Dyrkelse.
Wọ́n ó yọ yín kúrò nínú Sinagọgu: àní, àkókò ń bọ̀, tí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa yín, yóò rò pé òun ń ṣe ìsìn fún Ọlọ́run.
3 Og dette skulle de gøre, fordi de hverken kende Faderen eller mig.
Nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ó sì ṣe, nítorí tí wọn kò mọ Baba, wọn kò sì mọ̀ mí.
4 Men dette har jeg talt til eder, for at I, når Timen kommer, skulle komme i Hu, at jeg har sagt eder det; men dette sagde jeg eder ikke fra Begyndelsen, fordi jeg var hos eder.
Ṣùgbọ́n nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín, pé nígbà tí wákàtí wọn bá dé, kí ẹ lè rántí wọn pé mo ti wí fún yín. Ṣùgbọ́n èmi kò sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ wá, nítorí tí mo wà pẹ̀lú yín.
5 Men nu går jeg hen til ham, som sendte mig, og ingen af eder spørger mig: Hvor går du hen?
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi ń lọ sọ́dọ̀ ẹni tí ó rán mi; kò sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó bi mí lérè pé, ‘Níbo ni ìwọ ń lọ?’
6 Men fordi jeg har talt dette til eder, har Bedrøvelsen opfyldt eders Hjerte.
Ṣùgbọ́n nítorí mo sọ nǹkan wọ̀nyí fún yín, ìbìnújẹ́ kún ọkàn yín.
7 Men jeg siger eder Sandheden: Det er eder gavnligt, at jeg går bort, thi går jeg ikke bort, kommer Talsmanden ikke til eder; men går jeg bort, så vil jeg sende ham til eder.
Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni èmi ń sọ fún yín; àǹfààní ni yóò jẹ́ fún yín bí èmi bá lọ, nítorí bí èmi kò bá lọ, Olùtùnú kì yóò tọ̀ yín wá; ṣùgbọ́n bí mo bá lọ, èmi ó rán an sí yín.
8 Og når han kommer, skal han overbevise Verden om Synd og om Retfærdighed og om Dom.
Nígbà tí òun bá sì dé, yóò fi òye yé aráyé ní ti ẹ̀ṣẹ̀, àti ní ti òdodo, àti ní ti ìdájọ́,
9 Om Synd, fordi de ikke tro på mig;
ní ti ẹ̀ṣẹ̀, nítorí tí wọn kò gbà mí gbọ́;
10 men om Retfærdighed, fordi jeg går til min Fader, og I se mig ikke længer;
ní ti òdodo, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba, ẹ̀yin kò sì mọ̀ mí.
11 men om Dom, fordi denne Verdens Fyrste er dømt.
Ní ti ìdájọ́, nítorí tí a ti ṣe ìdájọ́ ọmọ-aládé ayé yìí.
12 Jeg har endnu meget at sige eder; men I kunne ikke bære det nu.
“Mo ní ohun púpọ̀ láti sọ fún yín pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ẹ kò lè gbà wọ́n nísinsin yìí.
13 Men når han, Sandhedens Ånd, kommer, skal han vejlede eder til hele Sandheden; thi han skal ikke tale af sig selv, men hvad som helst han hører, skal han tale, og de kommende Ting skal han forkynde eder.
Ṣùgbọ́n nígbà tí òun, àní Ẹ̀mí òtítọ́ náà bá dé, yóò tọ́ yín sí ọ̀nà òtítọ́ gbogbo, nítorí kì yóò sọ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó bá gbọ́, òun ni yóò máa sọ, yóò sì sọ ohun tí ń bọ̀ fún yín.
14 Han skal herliggøre mig; thi han skal tage af mit og forkynde eder.
Òun ó máa yìn mí lógo, nítorí tí yóò gbà nínú ti èmi, yóò sì máa sọ ọ́ fún yín.
15 Alt, hvad Faderen har, er mit; derfor sagde jeg, at han skal tage af mit og forkynde eder.
Ohun gbogbo tí Baba ní tèmi ni, nítorí èyí ni mo ṣe wí pé, òun ó gba nínú tèmi, yóò sì sọ ọ́ fún yín.
16 Om en liden Stund skulle I ikke se mig længer, og atter om en liden Stund skulle I se mig."
“Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ ó sì rí mi, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba.”
17 Da sagde nogle af hans Disciple til hverandre: "Hvad er dette, som han siger os: Om en liden Stund skulle I ikke se mig, og atter om en liden Stund skulle I se mig, og: Jeg går hen til Faderen?"
Nítorí náà díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bá ara wọn sọ pé, “Kín ni èyí tí o wí fún wa yìí, ‘Nígbà díẹ̀, ẹ̀yin ó sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ ẹ̀wẹ̀, ẹ̀yin kì yóò rí mi, àti, nítorí tí èmi ń lọ sọ́dọ̀ Baba’?”
18 De sagde altså: "Hvad er dette, han siger: Om en liden Stund? Vi forstå ikke, hvad han taler."
Nítorí náà wọ́n wí pé, kín ni, nígbà díẹ̀? Àwa kò mọ̀ ohun tí ó wí.
19 Jesus vidste, at de vilde spørge ham, og han sagde til dem: "I spørge hverandre om dette, at jeg sagde: Om en liden Stund skulle I ikke se mig, og atter om en liden Stund skulle I se mig.
Jesu sá à ti mọ̀ pé, wọ́n ń fẹ́ láti bi òun léèrè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ń bi ara yín léèrè ní ti èyí tí mo wí pé, nígbà díẹ̀, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti nígbà díẹ̀ si, ẹ̀yin ó sì rí mi?
20 Sandelig, sandelig, siger jeg eder, I skulle græde og jamre, men Verden skal glæde sig; I skulle være bedrøvede, men eders Bedrøvelse skal blive til Glæde.
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé, ẹ̀yin yóò máa sọkún ẹ ó sì máa pohùnréré ẹkún, ṣùgbọ́n àwọn aráyé yóò máa yọ̀: ṣùgbọ́n, ìbànújẹ́ yín yóò di ayọ̀.
21 Når Kvinden føder, har hun Bedrøvelse, fordi hendes Time er kommen; men når hun har født Barnet, kommer hun ikke mere sin Trængsel i Hu af Glæde over, at et Menneske er født til Verden.
Nígbà tí obìnrin bá ń rọbí, a ní ìbìnújẹ́, nítorí tí wákàtí rẹ̀ dé: ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá ti bí ọmọ náà tán, òun kì í sì í rántí ìrora náà mọ́, fún ayọ̀ nítorí a bí ènìyàn sí ayé.
22 Også I have da vel nu Bedrøvelse, men jeg skal se eder igen, og eders Hjerte skal glædes, og ingen tager eders Glæde fra eder.
Nítorí náà ẹ̀yin ní ìbànújẹ́ nísinsin yìí, ṣùgbọ́n èmi ó tún rí yín, ọkàn yín yóò sì yọ̀, kò sì sí ẹni tí yóò gba ayọ̀ yín lọ́wọ́ yín.
23 Og på den Dag skulle I ikke spørge mig om noget. Sandelig, sandelig, siger jeg eder, hvad som helst I bede Faderen om, skal han give eder i mit Navn.
Àti ní ọjọ́ náà ẹ̀yin kì ó bi mí lérè ohunkóhun. Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá béèrè lọ́wọ́ Baba ní orúkọ mi, òhun ó fi fún yín.
24 Hidindtil have I ikke bedt om noget i mit Navn; beder, og I skulle få, for at eders Glæde må blive fuldkommen.
Títí di ìsinsin yìí ẹ kò tí ì béèrè ohunkóhun ní orúkọ mi, ẹ béèrè, ẹ ó sì rí gbà, kí ayọ̀ yín kí ó lè kún.
25 Dette har jeg talt til eder i Lignelser; der kommer en Time, da jeg ikke mere skal tale til eder i Lignelser, men frit ud forkynde eder om Faderen.
“Nǹkan wọ̀nyí ni mo fi òwe sọ fún yín: ṣùgbọ́n àkókò dé, nígbà tí èmi kì yóò fi òwe bá yín sọ̀rọ̀ mọ́, ṣùgbọ́n èmi ó sọ nípa ti Baba fún yín gbangba.
26 På den Dag skulle I bede i mit Navn, og jeg siger ikke til eder, at jeg vil bede Faderen for eder;
Ní ọjọ́ náà, ẹ̀yin ó béèrè ní orúkọ mi, èmi kò sì wí fún yín pé, èmi ó béèrè lọ́wọ́ Baba fún yín.
27 thi Faderen selv elsker eder, fordi I have elsket mig og troet, at jeg er udgået fra Gud.
Nítorí tí Baba tìkára rẹ̀ fẹ́ràn yín, nítorí tí ẹ̀yin ti fẹ́ràn mi, ẹ sì ti gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni èmi ti jáde wá.
28 Jeg udgik fra Faderen og er kommen til Verden; jeg forlader Verden igen og går til Faderen."
Mo ti ọ̀dọ̀ Baba jáde wá, mo sì wá sí ayé, àti nísinsin yìí mo fi ayé sílẹ̀, mo sì lọ sọ́dọ̀ Baba.”
29 Hans Disciple sige til ham: "Se, nu taler du frit ud og siger ingen Lignelse.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Wò ó, nígbà yìí ni ìwọ ń sọ̀rọ̀ gbangba, ìwọ kò sì sọ ohunkóhun ní òwe.
30 Nu vide vi, at du ved alle Ting og ikke har nødig, at nogen spørger dig; desårsag tro vi, at du er udgået fra Gud."
Nígbà yìí ni àwa mọ̀ pé, ìwọ mọ̀ ohun gbogbo, ìwọ kò ní kí a bi ọ́ léèrè: nípa èyí ni àwa gbàgbọ́ pé, lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ìwọ ti jáde wá.”
31 Jesus svarede dem: "Nu tro I!
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin gbàgbọ́ wàyí?
32 Se, den Time kommer, og den er kommen, da I skulle adspredes hver til sit og lade mig alene; dog, jeg er ikke alene, thi Faderen er med mig.
Kíyèsi i, wákàtí ń bọ̀, àní ó dé tan nísinsin yìí, tí a ó fọ́n yín ká kiri, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀; ẹ ó sì fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò sì ṣe èmi nìkan, nítorí tí Baba ń bẹ pẹ̀lú mi.
33 Dette har jeg talt til eder, for at I skulle have Fred i mig. I Verden have I Trængsel; men værer frimodige, jeg har overvundet Verden."
“Nǹkan wọ̀nyí ni mo ti sọ fún yín tẹ́lẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó lè ní àlàáfíà nínú mi. Nínú ayé, ẹ̀yin ó ní ìpọ́njú; ṣùgbọ́n ẹ tújúká; mo ti ṣẹ́gun ayé.”

< Johannes 16 >