< Jeremias 51 >

1 Så siger HERREN: Jeg opvækker en ødelæggelsens ånd mod Babel og dem, som bor i "mine Modstanderes Hjerte".
Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
2 Og jeg sender til Babel Kastere, de skal kaste det og tømme dets Land, thi fra alle Hanter er de over det på Ulykkens Dag.
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
3 Ingen skal spænde sin Bue eller rejse sig i Brynje. Spar ikke dets Ynglinge, læg Band på hele dets Hær!
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
4 Dræbte Mænd skal falde i Kaldæernes Land og gennemborede i Gaderne;
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
5 thi Israel og Juda er ikke forladt af deres Gud, Hærskarers HERRE, men deres Land var fuldt af Skyld mod Israels Hellige.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
6 Fly ud af Babel, enhver redde sit Liv, at I ikke skal omkomme for dets Brøde! Thi det er Hævnens Tid for HERREN, han øver Gengæld imod det.
“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
7 Et gyldent Bæger var Babel i HERRENs Hånd, det gjorde al Jorden drukken; Folkene drak af Vinen, derfor blev Folkene galne.
Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
8 Babel faldt i et Nu, det knustes; jamrer over det! Hent Balsam hid til dets Sår, om det muligt kan læges!
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
9 Vi vilde læge Babel, men det lod sig ikke læge. Gå fra det og lad os drage hver til sit Land, thi dets Straffedom når til Himmelen, løfter sig til Skyerne.
“‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
10 HERREN har bragt vor Ret for Lyset; kom, lad os kundgøre HERREN vor Guds Værk i Zion!
“‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
11 Hvæs Pilene, gør Skjoldene blanke! HERREN har vakt Mederkongens Ånd, thi hans Hu står til at ødelægge Babel; thi det er HERRENs Hævn, Hævn for hans Tempel.
“Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Løft Banner mod Babels Mure, forstærk Vagten, sæt Vagtposter ud, læg Baghold! Thi HERREN har et Råd for og gør, hvad han har talet mod Babels Indbyggere.
Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 Du, som bor ved de mange Vande, rig på Skatte, din Ende er kommet, den Alen, hvor man skære dig af.
Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 Hærskarers Herre har svoret ved sig selv: Jeg vil fylde dig med Mennesker som Græshopper, og de skal istemme Vinperserråbet over dig.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
15 Han skabte Jorden i sin Vælde, grundfæstede Jorderig i sin Visdom, og i sin indsigt udspændte han Himmelen.
“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Når han løfter sin Røst, bruser Vandene i Himmelen, og han lader Skyer stige op fra Jordens Ende; han får Lynene til at give Regn og sender Stormen ud af sine Forrådskamre.
Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 Dumt er hvert Menneske, uden Indsigt, hver Guldsmed får Skam af sit Billede; thi Løgn er hans Støbning, der er ingen Ånd i dem;
“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
18 Tomhed er de, et dårende Værk; når deres Hjemsøgelses Tid kommer, er det ude med dem.
Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Jakobs Arvelod er ikke som de; thi han, der har skabt alt, er dets Arvelod; Hærskarers HERRE er hans Navn.
Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
20 Du var mig en Stridshammer, et Våben; med dig knuste jeg Folk, med dig ødelagde jeg Riger;
“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 med dig knuste jeg Hest og Rytter, med dig knuste jeg Vogn og Vognstyrer,
Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
22 med dig knuste jeg Mand og Kvinde med dig knuste jeg gammel og ung, med dig knuste jeg Yngling og Jomfru,
pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 med dig knuste jeg Hyrde og Hjord, med dig knuste jeg Agerdyrker og Oksespand, med dig knuste jeg Statholder og Landshøvding.
Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
24 Men jeg vil gengælde Babel og alle Kaldæas Indbyggere alt det onde, de gjorde mod Zion for eders Øjne, lyder det fra HERREN.
“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
25 Se, jeg kommer over dig, du ødelæggende Bjerg, lyder det fra HERREN, du, som ødelægger hele Jorden; jeg udrækker Hånden imod dig og vælter dig ned fra Klipperne og gør dig til et afsvedet Bjerg;
“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 man skal ikke fra dig hente Sten til Tinder eller Grundvolde, thi du skal blive en evig Ørken, lyder det fra HERREN.
A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
27 Løft Banner på Jorden, stød i Horn blandt Folkene, vi Folkene til Kamp imod det, opbyd Ararats, Minnis og Asjkenazs Riger imod det, indsæt en Tipsar, lad Hestene fare frem som lodne Græshopper;
“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 vi Folkene til Strid imod det, Mederkongen, hans Statholdere og alle hans Landshøvdinger og hele det Land, han råder over!
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 Jorden skal skælve og vride sig, thi HERRENs Tanker mod Babel fuldbyrdes, at gøre Babels Land til en Ørken, hvor ingen bor.
Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Babels Helte opgiver Kampen, de sidder stille i Borgene, deres kraft ebber ud, de er blevet til Kvinder; dets Boliger afbrændes, dets Portstænger knækkes.
Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Løber iler Løber i Møde, og Bud iler Bud i Møde for at melde Babels Konge, at hans By er indtaget fra Ende til anden,
Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 Overgangsstederne taget, Borgene brændt og Krigsfolkene rædselslagne.
Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
33 Thi så siger Hærskarers HERRE, Israels Gud: Babels Datter er som en Tærskeplads, når den stampes endnu en liden Stund, så kommer Høstens Tid for den.
Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
34 Kong Nebukadrezar af Babel har fortæret mig, oprevet mig, sat mig til Side som et tomt kar. Som en Drage har han slugt mig, fyldt sin Vom med mine Lækkerbidskener og drevet mig bort.
“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 Den Vold, jeg led, og min Overlast komme over Babel, siger de, som bor i Zion, mit Blod over Kaldæas Indbyggere, siger Jerusalem.
Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
36 Derfor, så siger HERREN: Se, jeg fører din Sag og giver digHævn, jeg lægger dets Hav tørt og udtørrer dets Kilde.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 Babel skal blive en Grushob, Sjakalers Bolig, til Rædsel og Spot, så ingen bor der.
Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 De brøler alle som Løver, knurrer som Løveunger i deres Vildskab.
Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
39 Jeg holder et Drikkelag for dem og gør dem drukne, så de døves og falder i evig Søvn uden at vågne, lyder det fra HERREN.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
40 Jeg fører dem ned til af slagtes som Får, som Vædre sammen med Bukke.
“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
41 Hvor Sjesjak blev fanget og grebet, al Jordens Stolthed, hvor Babel dog blev til Rædsel imellem Folkene!
“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Havet steg over Babel, af dets Bølgers Brus blev det skjult.
Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Dets Byer er blevet en Ørken, øde Land og Ødemark; intet Menneske bor i dem, intet Menneskebarn færdes i dem.
Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 Jeg hjemsøger Bel i Babel, river ud af hans Mund, hvad han slugte, til ham skal ej Folkeslag strømme mer. Også Babels Mur er faldet.
Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
45 Drag ud deraf, mit Folk, enhver redde sit Liv for HERRENs glødende Harme.
“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
46 Lad ikke eders Hjerter blive modfaldne og frygt ikke ved de Tidender, der høres på Jorden, når der i det ene År kommer een Tidende og i det næste en anden, når der er Voldsfærd på Jorden og Hersker følger på Hersker.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 Se, derfor skal Dage komme, da jeg hjemsøger Babels Gudebilleder, og alt dets Land bliver til Skamme, og alle deri skal falde på Valen.
Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 Jubl over Babel, Himmel og Jord med alt, hvad i dem er, thi fra Nord kommer Hærværksmænd over det, lyder det fra HERREN.
Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
49 Også Babel skal falde for de dræbte af Israels Skyld, ligesom dræbte på hele Jorden faldt for Babel.
“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 I, som undslap Sværdet, drag bort, stands ikke, kom HERREN i Hu i det fjerne, lad Jerusalem komme frem i eders Tanker!
Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
51 Vi blev til Skamme, thi Smædeord måtte vi høre; Blusel lagde sig over vore Ansigter, thi fremmede overfaldt HERRENs Huss Helligdomme.
“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52 Se, derfor skal Dage komme, lyder det fra HERREN, da jeg hjemsøger dets Gudebilleder, og sårede skal stønne i hele dets Land.
“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
53 Selv om Babel stiger op til Himmelen, og selv om det gør sin Borg utilgængelig i det høje, fra mig skal der komme Hærværksmænd over det, lyder det fra HERREN.
Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
54 Der lyder Skrig fra Babel, et vældigt Sammenbrud fra Kaldæernes Land.
“Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Thi HERREN hærger Babel og gør Ende på den vældige Larm der; deres Bølger bruser som mange Vande, deres Brag lyder højt.
Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Thi en Hærværksmand kommer over Babel, og dets Helte skal fanges, deres Buer knækkes; thi en Gengældelsens Gud er HERREN, han giver fuld Løn.
Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
57 Jeg gør dets Fyrster og Vismænd, dets Statholdere, Landshøvdinger og Helte drukne, og de skal falde i evig Søvn uden at vågne, lyder det fra kongen, hvis Navn er Hærskarers HERRE.
Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
58 Så siger Hærskarers HERRE: Babels brede Mur skal nedbrydes til Grunden og dets høje Porte opbrændes. Folkeslagenes Møje er spildt, og Folkefærdene slider sig trætte for Ilden.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
59 Det Ord, som Profefen Jeremias sendte med Seraja, en Søn at Masejas Søn Nerija, da han rejste, til Babel med Kong Zedekias af Juda i hans fjerde Regeringsår; Seraja sørgede for Nattely til Kongen, når han var på Rejse.
Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60 Jeremias optegnede al den Ulykke, som skulde komme over Babel, i en og samme Bog, alle disse Ord, der er skrevet mod Babel;
Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61 og Jeremias sagde til Seraja: "Når du kommer til Babel og ser Lejlighed dertil, skal du oplæse alle disse Ord
Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62 og sige: HERRE, du truede selv dette Sted med Udryddelse, så der ikke bliver nogen, som bor der, - hverken Folk eller Fæ, men det skal blive en evig Ørken.
Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63 Og når du er til Ende med at oplæse denne Bog, skal du binde en Sten til den, kaste den i Eufrat
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64 og sige: Således skal Babel gå til Bunds og ikke mere komme op for al den Ulykke, jeg sender over det!" Til Ordene "slider sig trætte for Ilden går Jeremiass Ord.
Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

< Jeremias 51 >