< Józua 3 >

1 Vstal pak Jozue velmi ráno, a hnuvše se z Setim, přišli až k Jordánu, on i všickni synové Izraelští, a přenocovali tu, prvé nežli šli přes něj.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.
2 I stalo se, že třetího dne správcové šli prostředkem stanů,
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já.
3 A přikazovali lidu, řkouce: Když uzříte truhlu smlouvy Hospodina Boha svého a kněží Levítské, ani ji nesou, vy také hnete se s místa svého a půjdete za ní,
Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.
4 (A však místo mezi vámi a mezi ní bude okolo dvou tisíc loket míry obecné, nepřibližujte se k ní), abyste viděli cestu, kterouž byste jíti měli; nebo nešli jste tou cestou prvé.
Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́.”
5 Řekl pak byl Jozue lidu: Posvěťtež se, zítra zajisté učiní Hospodin divné věci mezi vámi.
Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”
6 Potom řekl Jozue kněžím těmi slovy: Vezměte truhlu smlouvy, a jděte před lidem. I vzali truhlu smlouvy a brali se před lidem.
Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.
7 Nebo řekl byl Hospodin k Jozue: V tento den začnu tebe zvelebovati před očima všeho Izraele, aby poznali, že jakož jsem byl s Mojžíšem, tak budu s tebou.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose.
8 Protož ty přikaž kněžím, kteříž nosí truhlu smlouvy, a rci: Když vejdete na kraj vody Jordánské, zastavte se v Jordáně.
Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà, ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’”
9 Řekl také Jozue synům Izraelským: Přistupte sem, a slyšte slova Hospodina Boha vašeho.
Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
10 I řekl Jozue: Po tomto poznáte, že Bůh silný živý jest u prostřed vás, a že konečně vyžene od tváři vaší Kananejského, Hetejského, Hevejského, Ferezejského, Gergezejského, Amorejského a Jebuzejského:
Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín.
11 Aj, truhla smlouvy Panovníka vší země půjde před vámi přes Jordán.
Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín.
12 Protož nyní vezměte sobě dvanácte mužů z pokolení Izraelských, po jednom muži z každého pokolení.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
13 I bude, že hned jakž se zastaví kněží, nesoucí truhlu Hospodina Panovníka vší země, u vodě Jordánské, vody Jordánu rozdělí se, a vody tekoucí s vrchu zůstanou v jedné hromadě.
Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”
14 Stalo se tedy, když se bral lid z stanů svých, aby šli přes Jordán, a kněží, kteříž nesli truhlu smlouvy, před nimi,
Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.
15 A když ti, kteříž nesli truhlu, přišli až k Jordánu, a kněží, nesoucí truhlu, omočili nohy v kraji vod: (Jordán pak rozvodňuje se a vystupuje ze všech břehů svých v každý čas žně),
Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi,
16 Že se zastavily vody, kteréž s hůry přicházely, a shrnuly se v hromadu jednu velmi daleko od Adam města, kteréž leží k straně Sartan, kteréž pak odcházely k moři dolů, k moři slanému sešly a sběhly, a lid přešel naproti Jerichu.
omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko.
17 Stáli pak kněží, kteříž nesli truhlu smlouvy Hospodinovy na suše u prostřed Jordánu, nehýbajíce se, (a všecken Izrael šel po suše), až se lid všecken přepravil přes Jordán.
Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.

< Józua 3 >