< 5 Mojžišova 5 >

1 I svolal Mojžíš všecken lid Izraelský, a řekl jim: Slyš, Izraeli, ustanovení a soudy, kteréž já dnes mluvím v uši vaše; naučte se jim, a v skutku jich ostříhejte.
Mose sì pe gbogbo Israẹli jọ, ó sì wí pé, Gbọ́ ìwọ Israẹli, gbọ́ ìlànà àti òfin tí mo mú wá sí etí ìgbọ́ ọ yín lónìí. Ẹ kọ wọ́n, kí ẹ sì ri dájú pé ẹ̀ ń ṣe wọ́n.
2 Hospodin Bůh náš učinil s námi smlouvu na Orébě.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa dá májẹ̀mú ní Horebu.
3 Ne s otci našimi učinil Hospodin tu smlouvu, ale s námi, kteříž zde jsme nyní my všickni živí.
Kì í ṣe àwọn baba wa ni Olúwa bá dá májẹ̀mú yìí bí kò ṣe àwa, àní pẹ̀lú gbogbo àwa tí a wà láààyè níbí lónìí.
4 Tváří v tvář mluvil Hospodin s vámi na té hoře z prostředku ohně,
Olúwa bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú láàrín iná lórí òkè.
5 (Já jsem pak stál mezi Hospodinem a mezi vámi toho času, abych oznámil vám řeč Hospodinovu; nebo jste se báli ohně, a nevstoupili jste na horu), řka:
(Ní ìgbà yìí, mo wà láàrín ẹ̀yin pẹ̀lú Ọlọ́run láti sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un yín torí pé ẹ̀rù Ọlọ́run ń bà yín, ẹ kò sì lè kọjá lọ sórí òkè.) Ó sì wí pé,
6 Já jsem Hospodin Bůh tvůj, kterýž jsem tě vyvedl z země Egyptské z domu služby.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú un yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti, láti oko ẹrú jáde wá.
7 Nebudeš míti bohů jiných přede mnou.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọlọ́run mìíràn pẹ̀lú mi.
8 Neučiníš sobě rytiny, ani jakého podobenství těch věcí, kteréž jsou na nebi svrchu, ani těch, kteréž na zemi dole, ani těch, kteréž jsou u vodách pod zemí.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ère fún ara yín, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ ní òkè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀.
9 Nebudeš se jim klaněti, ani jich ctíti. Nebo já jsem Hospodin Bůh tvůj, Bůh silný, horlivý, navštěvující nepravost otců na synech do třetího i čtvrtého pokolení těch, kteříž nenávidí mne,
Ìwọ kò gbọdọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n; nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ọlọ́run owú ni mí, tí ń bẹ ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wò lára àwọn ọmọ, láti ìran kẹta títí dé ẹ̀kẹrin nínú àwọn tí ó kórìíra mi.
10 A činící milosrdenství nad tisíci těch, kteříž mne milují, a ostříhají přikázaní mých.
Èmi a sì máa fi àánú hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí ó fẹ́ mi, tí wọ́n sì ń pa òfin mi mọ́.
11 Nevezmeš jména Hospodina Boha svého nadarmo, neboť nenechá bez pomsty Hospodin toho, kdož by bral jméno jeho nadarmo.
Ẹ má ṣe ṣi orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín lò, torí pé ẹnikẹ́ni tí o bá ṣi orúkọ rẹ̀ lò kì yóò lọ láìjẹ̀bi.
12 Ostříhej dne sobotního, abys jej světil, jakož přikázal tobě Hospodin Bůh tvůj.
Rántí ọjọ́ ìsinmi láti yà á sí mímọ́, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín.
13 Šest dní pracovati budeš, a dělati všeliké dílo své;
Ọjọ́ mẹ́fà ni ìwọ yóò fi ṣiṣẹ́, kí ìwọ kí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ.
14 Ale dne sedmého odpočinutí jest Hospodina Boha tvého. Nebudeš dělati žádného díla, ty i syn tvůj i dcera tvá, i služebník tvůj i děvka tvá, vůl i osel tvůj i všeliké hovado tvé, i příchozí tvůj, kterýž jest v branách tvých, aby odpočinul služebník tvůj a děvka tvá jako i ty.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi Olúwa Ọlọ́run rẹ: nínú rẹ̀ ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan: ìwọ, àti ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin, àti akọ màlúù rẹ, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, àti ohun ọ̀sìn rẹ kan, àti àlejò tí ń bẹ nínú ibodè rẹ; kí ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ọkùnrin àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ obìnrin kí ó lè sinmi gẹ́gẹ́ bí ìwọ.
15 A pamatuj, že jsi byl služebníkem v zemi Egyptské, a vyvedl tě Hospodin Bůh tvůj odtud v ruce silné, a v rameni vztaženém. Protož přikázal tobě Hospodin Bůh tvůj, abys světil den sváteční.
Sì rántí pé, ìwọ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yọ ọ́ kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe pàṣẹ fún ọ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
16 Cti otce svého i matku svou, jakož přikázal tobě Hospodin Bůh tvůj, aby se prodleli dnové tvoji, a aby tobě dobře bylo na zemi, kterouž Hospodin Bůh tvůj dá tobě.
Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún ọ, kí ọjọ́ rẹ kí ó lè pẹ́, àti kí ó lè dára fún ọ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ.
17 Nezabiješ.
Ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn.
18 Nesesmilníš.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà.
19 Nepokradeš.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jalè.
20 Nepromluvíš proti bližnímu svému křivého svědectví.
Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ́rìí èké sí ẹnìkejì rẹ.
21 Nepožádáš manželky bližního svého, aniž požádáš domu bližního svého, pole jeho, neb služebníka jeho, aneb děvky jeho, vola jeho neb osla jeho, aneb čehokoli z těch věcí, kteréž jsou bližního tvého.
Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí aya ẹnìkéjì rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò sí ilé ẹnìkéji rẹ, oko rẹ̀, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, akọ màlúù rẹ̀ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, àti ohun gbogbo tí í ṣe ti ẹnìkéji rẹ.”
22 Ta slova mluvil Hospodin ke všemu shromáždění vašemu na hoře z prostředku ohně, oblaku a mrákoty, hlasem velikým, a nepřidal nic více, a napsal je na dvou dskách kamenných, kteréž mně dal.
Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrín iná, ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri, kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú wàláà méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
23 Vy pak když jste uslyšeli hlas z prostředku tmy, (nebo hora ohněm hořela, ) přistoupili jste ke mně všickni vůdcové pokolení vašich a starší vaši,
Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọ iná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn àgbàgbà yín tọ̀ mí wá.
24 A řekli jste: Ej, ukázal nám Hospodin Bůh náš slávu svou a velikost svou, a slyšeli jsme hlas jeho z prostředku ohně; dnešního dne viděli jsme, že Bůh mluvil s člověkem, a on živ zůstal.
Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárín iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láààyè lẹ́yìn tí Ọlọ́run bá bá a sọ̀rọ̀.
25 Protož nyní proč máme zemříti? Nebo sežral by nás oheň veliký tento; jestli více slyšeti budeme hlas Hospodina Boha našeho, zemřeme.
Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.
26 Nebo co jest všeliké tělo, aby slyše hlas Boha živého mluvícího z prostředku ohně, jako my, mělo živo býti?
Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Ọlọ́run alààyè láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?
27 Přistup ty a slyš všecky věci, kteréž mluviti bude Hospodin Bůh náš; potom ty mluviti budeš nám, což by koli řekl tobě Hospodin Bůh náš, a my slyšeti i činiti budeme.
Súnmọ́ tòsí ibẹ̀ kí o sì gbọ́ gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò sọ, nígbà náà sọ ohunkóhun tí Olúwa Ọlọ́run wa sọ fún ọ fún wa. A ó sì fetísílẹ̀, a ó sì gbọ́rọ̀.”
28 Uslyšev pak Hospodin hlas řečí vašich, když jste mluvili ke mně, řekl mi Hospodin: Slyšel jsem hlas řeči lidu tohoto, kterouž mluvili tobě. Cožkoli mluvili, dobřeť jsou mluvili.
Olúwa ń gbọ́ nígbà tí ẹ̀yin ń bá mi sọ̀rọ̀, Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti gbọ́ ohun tí àwọn ènìyàn yí sọ fún ọ. Gbogbo ohun tí wọ́n sọ dára,
29 Ó kdyby bylo jejich srdce takové, aby se báli mne a ostříhali přikázaní mých po všeliký čas, aby jim dobře bylo i synům jejich na věky!
ìbá ti dára tó, bí ọkàn wọn bá lè bẹ̀rù mi, tí ó sì ń pa gbogbo òfin mi mọ́ nígbà gbogbo, kí ó bá à lè dára fún wọn, àti àwọn ọmọ wọn láéláé.
30 Jdi, rci jim: Navraťte se k stanům vašim.
“Lọ sọ fún wọn kí wọn padà sínú àgọ́ wọn.
31 Ty pak stůj tuto při mně, a oznámím tobě všecka přikázaní, ustanovení i soudy, kterýmž je učiti budeš, aby je činili v zemi, kterouž já dávám jim, aby jí dědičně vládli.
Ṣùgbọ́n ìwọ túbọ̀ dúró síbí pẹ̀lú mi, kí n bá à lè fún ọ ní àwọn àṣẹ tí o gbọdọ̀ fi kọ́ wọn láti máa tẹ̀lé ní ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún wọn láti ní.”
32 Hleďtež tedy, abyste činili, jakž přikázal vám Hospodin Bůh váš; neuchylujte se na pravo ani na levo.
Torí èyí, ẹ ṣọ́ra láti máa ṣe ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín tí pa ní àṣẹ fún un yín; ẹ má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì.
33 Po vší té cestě, kterouž vám přikázal Hospodin Bůh váš, choditi budete, abyste živi byli, a dobře bylo vám, a abyste prodlili dnů na zemi, kterouž dědičně obdržíte.
Ẹ rìn ní gbogbo ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ bá à le yè, kí ó sì dára fún un yín, kí ọjọ́ ọ yín bá à lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin yóò gbà.

< 5 Mojžišova 5 >