< ⲚⲒⲔⲞⲢⲒⲚⲐⲒⲞⲤ Ⲁ ̅ 1 >

1 ⲁ̅ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲠⲀⲠⲞⲤⲦⲞⲖⲞⲤ ⲈⲦⲐⲀϨⲈⲘ ⲚⲦⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲞⲨⲰϢ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲈⲘ ⲤⲰⲤⲐⲈⲚⲎⲤ ⲠⲒⲤⲞⲚ
Paulu, ẹni ti a pé láti jẹ́ aposteli Kristi Jesu nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti Sostene arákùnrin wa,
2 ⲃ̅ ⲚϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲐⲎ ⲈⲦϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲔⲞⲢⲒⲚⲐⲞⲤ ⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲦⲞⲨⲂⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚⲎ ⲈⲦⲐⲀϨⲈⲘ ⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲐⲘⲞⲨϮ ⲈⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠⲈⲚϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ϦⲈⲚⲘⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲦⲰⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲦⲀⲚ.
Sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run ni Kọrinti, sí àwọn ti a sọ di mímọ́ nínú Kristi Jesu àti àwọn ti a pè láti jẹ́ mímọ́ pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ni ibikíbi ti ń pe orúkọ Olúwa wa Jesu Kristi ẹni ti ń ṣe Olúwa tiwọn àti ti àwa náà:
3 ⲅ̅ ⲠϨⲘⲞⲦ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲚⲈⲘ ⲦϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲠⲈⲚⲒⲰⲦ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲚϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti Olúwa wa tí í ṣe Jesu Kristi.
4 ⲇ̅ ϮϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲚ ⲠⲀⲚⲞⲨϮ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲀⲨⲦⲎⲒϤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ.
Nígbà gbogbo ni mo ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tó fi fún un yín nínú Kristi Jesu.
5 ⲉ̅ ϪⲈ ϦⲈⲚϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲢⲀⲘⲀⲞ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦϤ ϦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲈⲘ ⲈⲘⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ
Nítorí nínú rẹ̀ ni a ti sọ yín di ọlọ́rọ̀ nínú ọ̀rọ̀ sísọ yín gbogbo àti nínú ìmọ̀ yín gbogbo.
6 ⲋ̅ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲀ ϮⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲦⲈⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲦⲀϪⲢⲞ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ.
Nítorí ẹ̀rí wa nínú Kristi ni a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nínú yín.
7 ⲍ̅ ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲰⲠⲒ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲀⲦ ⲀⲚ ϦⲈⲚϨⲖⲒ ⲚϨⲘⲞⲦ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϪⲞⲨϢⲦ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲀⲦϨⲎ ⲘⲠⲒϬⲰⲢⲠ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲦⲈⲠⲈⲚϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲤ
Nítorí náà ẹ̀yin kò ṣe aláìní nínú èyíkéyìí ẹ̀bùn ẹ̀mí, bí ẹ̀yin ṣe ń retí ìfarahàn Olúwa wa Jesu Kristi.
8 ⲏ̅ ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲈ ⲈϤⲈⲦⲀϪⲢⲈ ⲐⲎⲚⲞⲨ ϢⲀ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲀⲦⲀⲢⲒⲔⲒ ϦⲈⲚⲠⲈϨⲞⲞⲨ ⲘⲠⲈⲚϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
Òun yóò sì mú yín dúró títí dé òpin, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ́ aláìlábùkù ní ọjọ́ Olúwa wa Jesu Kristi.
9 ⲑ̅ ϤⲈⲚϨⲞⲦ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲐⲀϨⲈⲘ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲘⲈⲦϢⲪⲎⲢ ⲚⲦⲈⲠⲈϤϢⲎⲢⲒ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲠⲈⲚϬⲞⲒⲤ.
Ọlọ́run, nípasẹ̀ ẹni ti a pè yín sínú ìdàpọ̀ pẹ̀lú Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi Olúwa wa, jẹ́ Olóòtítọ́.
10 ⲓ̅ ϮϮϨⲞ ⲞⲨⲚ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠⲈⲚϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϢⲦⲈⲘ ϨⲀⲚⲪⲰⲢϪ ϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲈⲂⲦⲰⲦ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲎⲦ ⲚⲞⲨⲰⲦ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲄⲚⲰⲘⲎ ⲚⲞⲨⲰⲦ.
Mo bẹ̀ yín ẹ̀yin ara, ní orúkọ Olúwa wa Jesu Kristi, pé kí gbogbo yín fohùn ṣọ̀kan kí ó máa ṣe sí ìyapa láàrín yín, àti pé kí a lè ṣe yín pé ní inú àti ìmọ̀ kan náà.
11 ⲓ̅ⲁ̅ ⲀⲨⲦⲀⲘⲞⲒ ⲄⲀⲢ ⲈⲐⲂⲈ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲚⲀⲤⲚⲎ ⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲚⲀⲬⲖⲞⲎⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ϨⲀⲚϢϬⲚⲎⲚ ϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ.
Ẹ̀yin ará mi, àwọn kan láti ilé Kloe sọ di mí mọ̀ fún mi pé ìjà ń bẹ́ láàrín yín.
12 ⲓ̅ⲃ̅ ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ϮϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲘⲈⲚ ⲀⲚⲞⲔ ⲪⲀ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲪⲀ ⲀⲠⲞⲖⲖⲰ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲪⲀ ⲔⲎⲪⲀ ⲀⲚⲞⲔ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲔ ⲪⲀ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
Ohun tí mo ń sọ ní pé, olúkúlùkù yín ń wí pé, “Èmí tẹ̀lé Paulu”; “Èmi tẹ̀lé Apollo”; òmíràn wí pé, “Èmi tẹ̀lé Kefa, Peteru”; àti ẹlòmíràn wí pé, “Èmi tẹ̀lé Kristi.”
13 ⲓ̅ⲅ̅ ⲀⲨⲪⲈϢ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲘⲎ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲀⲨⲀϢϤ ⲈϪⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲒⲈ ⲀⲚ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϬⲒⲰⲘⲤ ⲈⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ.
Ǹjẹ́ a ha pín Kristi bí? Ṣé a kan Paulu mọ́ àgbélébùú fún un yín bí? Ǹjẹ́ a tẹ̀ yín bọ omi ní orúkọ Paulu bí?
14 ⲓ̅ⲇ̅ ϮϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ϪⲈ ⲘⲠⲒϮⲰⲘⲤ ⲚϨⲖⲒ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲔⲢⲒⲤⲠⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲄⲀⲒⲞⲤ.
Inú mi dún púpọ̀ pé èmi kò tẹ ẹnikẹ́ni nínú yín bọ omi yàtọ̀ sí Krisipu àti Gaiusi.
15 ⲓ̅ⲉ̅ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϢⲦⲈⲘ ⲞⲨⲀⲒ ϪⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϬ ⲒⲰⲘⲤ ⲈⲠⲀⲢⲀⲚ.
Nítorí náà kò sí ẹni tí ó lè sọ pé òun ṣe ìtẹ̀bọmi ní orúkọ èmi fúnra ara mi.
16 ⲓ̅ⲋ̅ ⲀⲒϮⲰⲘⲤ ⲆⲈ ⲘⲠⲔⲈⲎⲒ ⲚⲤⲦⲈⲪⲀⲚⲀ ⲖⲞⲒⲠⲞⲚ ⲚϮⲈⲘⲒ ⲀⲚ ϪⲈ ⲀⲚ ⲀⲒϮⲰⲘⲤ ⲚⲔⲈⲞⲨⲀⲒ.
(Bẹ́ẹ̀ ni, mo tún tẹ ìdílé Stefana bọ omi; lẹ́yìn èyí, èmí kò rántí pé mo tẹ ẹnikẹ́ni bọ omi mọ́ níbikíbi).
17 ⲓ̅ⲍ̅ ⲚⲈⲦⲀϤⲦⲀⲞⲨⲞⲒ ⲄⲀⲢ ⲀⲚ ⲚϪⲈⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈϮⲰⲘⲤ ⲀⲖⲖⲀ ⲈϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲂⲰ ⲚⲤⲀϪⲒ ⲀⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤϢⲦⲈⲘϢⲰⲠⲒ ⲈϤϢⲞⲨⲒⲦ ⲚϪⲈⲠⲒⲤⲦⲀⲨⲢⲞⲤ ⲚⲦⲈⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ.
Nítorí Kristi kò rán mi láti máa ṣe ìtẹ̀bọmi, ṣùgbọ́n ó rán mi láti máa wàásù ìyìnrere: kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn, kí a máa ṣe sọ àgbélébùú Kristi dí aláìlágbára.
18 ⲓ̅ⲏ̅ ⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲄⲀⲢ ⲚⲦⲈⲠⲒⲤⲦⲀⲨⲢⲞⲤ ⲚⲦⲈⲚ ⲚⲎ ⲘⲈⲚ ⲈⲐⲚⲀⲦⲀⲔⲞ ⲞⲨⲘⲈⲦⲤⲞϪ ⲠⲈ ⲚⲀⲚ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲚ ϦⲀ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀⲚⲞϨⲈⲘ ⲞⲨϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲠⲈ.
Nítorí pé òmùgọ̀ ni ọ̀rọ̀ àgbélébùú jẹ́ sí àwọn tí ń ṣègbé, ṣùgbọ́n fún àwa tí a ń gbàlà ó jẹ́ agbára Ọlọ́run.
19 ⲓ̅ⲑ̅ ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲄⲀⲢ ϪⲈ ϮⲚⲀⲦⲀⲔⲞ ⲚⲦⲤⲞⲪⲒⲀ ⲚⲦⲈⲚⲒⲤⲀⲂⲈⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈⲘⲒ ⲚⲦⲈⲚⲒⲔⲀⲦϨⲎ ⲦϮⲚⲀϢⲞϢϤ.
Nítorí a tí kọ ọ́ pé: “Èmi yóò pa ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n run, òye àwọn olóye ni Èmi yóò sọ di asán.”
20 ⲕ̅ ⲀϤⲐⲰⲚ ⲞⲨⲤⲀⲂⲈ ⲀϤⲐⲰⲚ ⲞⲨⲤⲀϦ ⲀϤⲐⲰⲚ ⲞⲨⲢⲈϤϦⲞⲦϦⲈⲦ ⲚⲦⲈⲠⲀⲒⲈⲚⲈϨ ⲘⲎ ⲘⲠⲈ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲢ ⲦⲤⲞⲪⲒⲀ ⲘⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲚⲤⲞϪ. (aiōn g165)
Àwọn ọlọ́gbọ́n náà ha dá? Àwọn akọ̀wé náà ha dà? Àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ ayé yìí ha dà? Ọlọ́run kò ha ti sọ ọgbọ́n ayé yìí di aṣiwèrè? (aiōn g165)
21 ⲕ̅ⲁ̅ ⲈⲠⲒⲆⲎ ⲄⲀⲢ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲤⲞⲪⲒⲀ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲠⲈ ⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲤⲞⲨⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ϮⲤⲞⲪⲒⲀ ⲀϤϮⲘⲀϮ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ϮⲘⲈⲦⲤⲞϪ ⲚⲦⲈⲠⲒϨⲒⲰⲒϢ ⲈⲚⲞϨⲈⲘ ⲚⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ.
Nítorí pé, nínú ọgbọ́n Ọlọ́run, ayé kò le mọ̀ òun nípa ọgbọ́n àti ìṣeféfé wọn. Ó sì gba gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́ là nípa ìwàásù tí àwọn aráyé pè ní òmùgọ̀ àti ọ̀rọ̀ ọ yẹ̀yẹ́.
22 ⲕ̅ⲃ̅ ⲈⲠⲒⲆⲎ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲤⲈⲈⲢⲈⲦⲒⲚ ⲚϨⲀⲚⲘⲎⲒⲚⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ ⲤⲈⲔⲰϮ ⲚⲤⲀϮⲤⲞⲪⲒⲀ.
Nítorí pé àwọn Júù ń béèrè àmì, àwọn Helleni sí ń ṣàfẹ́rí ọgbọ́n,
23 ⲕ̅ⲅ̅ ⲀⲚⲞⲚ ⲆⲈ ⲦⲈⲚϨⲒⲰⲒϢ ⲘⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈⲀⲨⲀϢϤ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲤⲔⲀⲚⲆⲀⲖⲞⲚ ⲚⲰⲞⲨ ⲠⲈ ⲚⲒⲈⲐⲚⲞⲤ ⲆⲈ ⲞⲨⲘⲈⲦⲤⲞϪ ⲠⲈ.
ṣùgbọ́n àwa ń wàásù Kristi ti a kàn mọ́ àgbélébùú, òkúta ìkọ̀sẹ̀ àwọn Júù àti òmùgọ̀ fún àwọn kèfèrí.
24 ⲕ̅ⲇ̅ ⲚⲀⲚ ⲆⲈ ⲀⲚⲞⲚ ϦⲀ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀⲚⲞϨⲈⲘ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲞⲨϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲠⲈ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
Ṣùgbọ́n sí àwọn tí Ọlọ́run tí pè, àti àwọn Júù àti àwọn Giriki, Kristi ni agbára Ọlọ́run, àti ọgbọ́n Ọlọ́run.
25 ⲕ̅ⲉ̅ ϪⲈ ϮⲘⲈⲦⲤⲞϪ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲤⲞⲒ ⲚⲤⲀⲂⲈ ⲈϨⲞⲦⲈ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲞⲨⲞϨ ϮⲘⲈⲦⲀⲤⲐⲎⲚⲎⲤ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲤⲞⲒ ⲚϪⲰⲢⲒ ⲈϨⲞⲦⲈ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ.
Nítorí pé òmùgọ̀ Ọlọ́run jù ọgbọ́n ènìyàn lọ; àti aláìlera Ọlọ́run ni agbára jù ìlera ènìyàn lọ.
26 ⲕ̅ⲋ̅ ⲀⲚⲀⲨ ⲄⲀⲢ ⲈⲠⲈⲦⲈⲚⲐⲰϨⲈⲘ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲤⲀⲂⲈ ⲔⲀⲦⲀ ⲤⲀⲢⲜ ⲘⲘⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϪⲰⲢⲒ ⲘⲘⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲈⲨⲄⲈⲚⲎⲤ.
Ará, ẹ kíyèsi ohun tí ẹ jẹ́ nígbà tí a pè yín. Kì í ṣe ọ̀pọ̀ yín jẹ ọlọ́gbọ́n nípa àgbékalẹ̀ ti ènìyàn, tàbí ọ̀pọ̀ nínú yín jẹ́ ènìyàn pàtàkì, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ọ̀pọ̀ nínú yín jẹ́ ọlọ́lá nípa ibi tí a gbé bí i.
27 ⲕ̅ⲍ̅ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲒⲤⲞϪ ⲚⲦⲈⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲀϤⲤⲞⲦⲠⲞⲨ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤϮϢⲒⲠⲒ ⲚⲚⲒⲤⲀⲂⲈⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲘⲈⲦϪⲰⲂ ⲚⲦⲈⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲀϤⲤⲞⲦⲠⲞⲨ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤϮϢⲒⲠⲒ ⲚⲚⲒϪⲰⲢⲒ.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tí yàn àwọn òmùgọ̀ ayé láti fi dààmú àwọn ọlọ́gbọ́n; Ọlọ́run sì ti yàn àwọn ohun aláìlera ayé láti fi dààmú àwọn ohun tí ó ni agbára.
28 ⲕ̅ⲏ̅ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲘⲈⲦⲀⲄⲈⲚⲎⲤ ⲚⲦⲈⲠⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦϢⲞϢϤ ⲀϤⲤⲞⲦⲠⲞⲨ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦⲈⲚⲤⲈϢⲞⲠ ⲀⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲔⲞⲢϤ ⲚⲚⲎ ⲈⲦϢⲞⲠ.
Àti àwọn ohun tí ayé tí kò ní ìyìn, àti àwọn ohun tí a kẹ́gàn, ni Ọlọ́run sì ti yàn, àní àwọn ohun tí kò sí, láti sọ àwọn ohun tí ó wà di asán.
29 ⲕ̅ⲑ̅ ϨⲞⲠⲰⲤ ⲚⲦⲈϢⲦⲈⲘ ⲤⲀⲢⲜ ⲚⲒⲂⲈⲚ ϢⲞⲨϢⲞⲨ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲘⲠⲈⲘⲐⲞ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ.
Nítorí kí ó má ba à sí ẹnìkan tí yóò ṣògo níwájú rẹ̀.
30 ⲗ̅ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲞϤ ϨⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚⲀⲚ ⲚⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲦⲞⲨⲂⲞ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲤⲰϮ.
Nítorí rẹ̀ ni ẹ̀yin ṣe wà nínú Kristi Jesu ẹni ti ó jásí ọgbọ́n fún wa láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run—èyí ń ni, òdodo, ìwà mímọ́ àti ìràpadà wa.
31 ⲗ̅ⲁ̅ ϨⲒⲚⲀ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲠⲈⲦϢⲞⲨϢⲞⲨ ⲘⲘⲞϤ ⲘⲀⲢⲈϤϢⲞⲨϢⲞⲨ ⲘⲘⲞϤ ϦⲈⲚⲠϬⲞⲒⲤ.
Nítorí náà, bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹni ti ó bá ń ṣògo kí ó máa ṣògo nínú Olúwa.”

< ⲚⲒⲔⲞⲢⲒⲚⲐⲒⲞⲤ Ⲁ ̅ 1 >