< 诗篇 130 >

1 上行之诗。 耶和华啊,我从深处向你求告!
Orin fún ìgòkè. Láti inú ibú wá ni èmi ń ké pè é ọ́ Olúwa
2 主啊,求你听我的声音! 愿你侧耳听我恳求的声音!
Olúwa, gbóhùn mi, jẹ́ kí etí rẹ kí o tẹ́ sílẹ̀ sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
3 主—耶和华啊,你若究察罪孽, 谁能站得住呢?
Olúwa, ìbá ṣe pé kí ìwọ máa sàmì ẹ̀ṣẹ̀, Olúwa, tá ni ìbá dúró.
4 但在你有赦免之恩, 要叫人敬畏你。
Nítorí ìdáríjì wà lọ́dọ̀ rẹ, kí a lè máa bẹ̀rù rẹ.
5 我等候耶和华,我的心等候; 我也仰望他的话。
Èmi dúró de Olúwa, ọkàn mi dúró, àti nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni èmi ń ṣe ìrètí.
6 我的心等候主, 胜于守夜的,等候天亮, 胜于守夜的,等候天亮。
Ọkàn mi dúró de Olúwa, ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ, àní ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ.
7 以色列啊,你当仰望耶和华! 因他有慈爱,有丰盛的救恩。
Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti Olúwa: nítorí pé lọ́dọ̀ Olúwa ni àánú wà, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdáǹdè wà.
8 他必救赎以色列脱离一切的罪孽。
Òun ó sì dá Israẹli ní ìdè kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ gbogbo.

< 诗篇 130 >