< Luke 19 >

1 Yeshua Jericho alut'in, chule akhopi sung chu ajot in ahi.
Jesu sì wọ Jeriko lọ, ó sì ń kọjá láàrín rẹ̀.
2 Mi khat amin Zacchaeus kiti chua chun aume. Ama chu hiche lhang'a dinga kaidong pipu ahin, ahaova haosa ahitai.
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà tí a ń pè ní Sakeu, ó sì jẹ́ olórí agbowó òde kan, ó sì jẹ́ ọlọ́rọ̀.
3 Aman Yeshua chu mutei ding agon, hinlah ama anem behseh jeh chun mihonpi lah'a chun amutheipoi.
Ó sì ń fẹ́ láti rí ẹni tí Jesu jẹ́: kò sì lè rí i, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti nítorí tí òun jẹ́ ènìyàn kúkúrú.
4 Hijeh chun ana malhaijel'in lampi panga theiba phung khat'ah anakal'e, ajeh chu Yeshuan hiche lampi chu aho ding ahi.
Ó sì súré síwájú, ó gun orí igi sikamore kan, kí ó bà lè rí i: nítorí tí yóò kọjá lọ níhà ibẹ̀.
5 Yeshua ahung phat chun, Zacchaeus chu avetouvin chule amin in akouvin, “Zacchaeus! gang'in, hungkum'in! tunia na in'a maljin kahi ding ahi,” ahinti.
Nígbà tí Jesu sì dé ibẹ̀, ó gbé ojú sókè, ó sì rí i, ó sì wí fún un pé, “Sakeu! Yára, kí o sì sọ̀kalẹ̀; nítorí pé èmi yóò wọ ilé rẹ lónìí.”
6 Zacchaeus jong kinloitah in ahung kumlhan, Yeshua chu a'in ah kipah le thanom tah'in apuilut tai.
Ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbà á.
7 Ahivangin miho chu alungphamo uvin, “Michonse chungnung in'ah agalhung taget e,” tin aphunchel tauve.
Nígbà tí wọ́n sì rí i, gbogbo wọn ń kùn, wí pé, “Ó lọ bá ọkùnrin ẹlẹ́ṣẹ̀ náà ní àlejò.”
8 Chuphat chun, Zacchaeus jong Pakai angsungah adingdoh in aseitai, “Pakai, kanei kagou akehkhat mivaicha ho peing'e, chule kai kadon na'a miho lepthol'a kabol aumleh, amaho chu ajatlin nungpeh inge!” ati.
Sakeu sì dìde, ó sì wí fún Olúwa pé, “Wò ó, Olúwa, ààbọ̀ ohun ìní mi ni mo fi fún tálákà; bí mo bá sì fi èké gba ohun kan lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, èmi san án padà ní ìlọ́po mẹ́rin!”
9 Yeshuan adonbut in, “Tunin hiche in'ah huhhingna alhung tai, ajeh chu hiche mipa hin Abraham chapa dihtah ahi akimusah tai.
Jesu sì wí fún un pé, “Lónìí ni ìgbàlà wọ ilé yìí, níwọ̀n bí òun pẹ̀lú ti jẹ́ ọmọ Abrahamu.
10 Ijeh inem itile Mihem Chapa chu amangsa holdoh le huhhing dinga hung'ah ahi,” ati.
Nítorí Ọmọ Ènìyàn dé láti wá àwọn tí ó nù kiri, àti láti gbà wọ́n là.”
11 Mihonpi chun Yeshua thusei jouse chu angailha sohkeiyun ahi. Chule ama Jerusalem anaitoh kilhonin, aman thusim khat, Pathen Lenggam chu kipan pai dinga angaito'u suhdih nadin aseiye.
Nígbà tí wọ́n sì ń gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó sì tẹ̀síwájú láti pa òwe kan, nítorí tí ó súnmọ́ Jerusalẹmu, àti nítorí tí wọn ń rò pé, ìjọba Ọlọ́run yóò farahàn nísinsin yìí.
12 Aman hitin aseiye, “Lengchapate khat mun gamlatah a leng gachanga hung kile kit dingin koudoh in aumin ahi.
Ó sì wí pé, “Ọkùnrin ọlọ́lá kan lọ sí ìlú òkèrè láti gba ìjọba kí ó sì padà.
13 Achedoh masangin asohte lah'a mi som akoukhom in dangka mina som apen, ‘kachedoh sungin hiche hi nei veikan peh'un’ ati.
Ó sì pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ mẹ́wàá, ó fi owó mina mẹ́wàá fún wọn, ó sì wí fún wọn pé, ‘Ẹ máa ṣòwò títí èmi ó fi dé!’
14 Ahivangin amiten avetnom pouvin, achedoh nungin palai asol'un, ‘Ama hi kalengpau dingin kadei pouve’ tin agasei sah uve.
“Ṣùgbọ́n àwọn ará ìlù rẹ̀ kórìíra rẹ̀, wọ́n sì rán ikọ̀ tẹ̀lé e, wí pé, ‘Àwa kò fẹ́ kí ọkùnrin yìí jẹ ọba lórí wa.’
15 Leng ahung chan jouvin, ahung kilen chule asohte sum apeh sese chu akoukhom tai. Aman aveikan jat'u chu ahetnom ahi.
“Nígbà tí ó gba ìjọba tan, tí ó padà dé, ó pàṣẹ pé, kí a pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ wọ̀nyí tí òun ti fi owó fún wá sọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí kí ó le mọ iye èrè tí olúkúlùkù ti jẹ nínú iṣẹ́ òwò wọn.
16 Soh masapan thu ahinlhut in, ‘Pipu, keiman nasum kaveikan in, neipeh chu ajat som in apunge!’ ati.
“Èyí èkínní sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina mẹ́wàá sí i.’
17 Lengpan adonbut in, ‘Nabol pha'e!’ ati. ‘Nangma sohpha nahi. Nangma themcha kapeh chunga kitah nahi, hijeh a chu natohphat kipaman'a khopi som chunga gamvaipo nahi ding ahi,’ atipeh e.
“Olúwa rẹ̀ sì wí fún un pé, ‘O ṣeun, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere! Nítorí tí ìwọ ṣe olóòtítọ́ ní ohun kínkínní, gba àṣẹ lórí ìlú mẹ́wàá.’
18 Soh anina pan thu ahinlhut kit in, ‘Pipu, nasum kaveikan in neipeh chu ajat ngan kapunsah be'e’ ati.
“Èyí èkejì sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, owó mina rẹ jèrè owó mina márùn.’
19 ‘Nabol aphai!’ tin lengpan adonbut in, ‘Nangma khopi nga chunga vaipo nahi ding ahi’ ati.
“Olúwa rẹ sì wí fún un pẹ̀lú pé, ‘Ìwọ pẹ̀lú joyè ìlú márùn-ún!’
20 Ahivangin soh athumna pan sum amu mama chu ahinchoiyin aseitai, ‘Pipu, keiman nasum chu kasel'in kana koitup peh e.
“Òmíràn sì wá, ó wí pé, ‘Olúwa, wò ó owó mina rẹ tí ń bẹ lọ́wọ́ mi ni mo dì sínú aṣọ pélébé kan;
21 Kakichat nahi ajeh chu nangma mikhel nahin, nanga hilou jong nakilah in, natu lou jong aga nakichomkhom ji'e.’ ati.
nítorí mo bẹ̀rù rẹ, àti nítorí tí ìwọ ṣe òǹrorò ènìyàn, ìwọ a máa mú èyí tí ìwọ kò fi lélẹ̀, ìwọ a sì máa ká èyí tí ìwọ kò gbìn!’
22 ‘Nangma soh gilou!’ tin lengpa ahung eojah in, ‘Nathun themmo nachan ahi. Nangman mikikhel kahi nahet a, keiya hilou kakilah theiya, katulou jong ka-at thei leh,
“Olúwa rẹ sì wí fún un pé, ‘Ní ẹnu ara rẹ náà ni èmi ó ṣe ìdájọ́ rẹ, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, ìwọ mọ̀ pé òǹrorò ènìyàn ni mí, pé, èmi a máa mú èyí tí èmi kò fi lélẹ̀ èmi a sì máa ká èyí tí èmi kò gbìn.
23 ipi dinga sumkoina in'a kasum chu nanakoi louham? Ken athoi themkhat beh kikimu tadinga,’ ati.
Èéha sì ti ṣe tí ìwọ kò fi owó mi pamọ́ sí ilé ìfowópamọ́, pé nígbà tí mo bá dé, èmi ìbá ti béèrè rẹ̀ pẹ̀lú èlé?’
24 Chuin akom avel'a ding ho hengah akiheiyin, hitin thupeh aneitai, ‘Hiche sohpa a kon chun sum chu lahpeh unlang mina som neipa chu petauvin’ ati.
“Ó sì wí fún àwọn tí ó dúró létí ibẹ̀ pé, ‘Ẹ gba owó mina náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí ẹ sì fi í fún ẹni tí ó ní owó mina mẹ́wàá.’
25 ‘Ahin, pipu, aman som aneitai!’ tin ahinsei yuve.
“Wọ́n sì wí fún un pé, ‘Olúwa, ó ní owó mina mẹ́wàá.’
26 Lengpan adonbut in, ahinai, akipe mangthem hochu, kipeh be ding. Amavang imacha bollou ho koma pat, anei sun'u themcha jong chu kilahmang peh ding ahiuve.
“Mo wí fún yín pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní, ni a ó fi fún, àti lọ́dọ̀ ẹni tí kò ní èyí tí ó ní pàápàá a ó gbà á lọ́wọ́ rẹ̀.
27 Chuleh hiche kagalmi ho, lenga kapan ding deilou ho chu–hin puilut unlang ka-angsung tah a hin thatdoh tauvin,” ati.
Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá mi wọ̀nyí, tí kò fẹ́ kí èmi jẹ ọba lórí wọn ẹ mú wọn wá ìhín yìí, kí ẹ sì pa wọ́n níwájú mi!’”
28 Hiche thusim aseijouvin, Yeshua Jerusalem lam jon'in, aseijuite sangin anamasan ahi.
Nígbà tí ó sì ti wí nǹkan wọ̀nyí tan, ó lọ síwájú, ó ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
29 Ama Bethphage le Bethany khopiho Olive molchung lang ahung gei phat in, aseijui mini asol masan,
Ó sì ṣe, nígbà tí ó súnmọ́ Betfage àti Betani ní òkè tí a ń pè ní òkè olifi, ó rán àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
30 “Hiche kho a khun galut lhonin lang” tin aseipeh in, “Nalut lhon tengleh, sangan nou kihen koiman atouna nailou namu lhon ding ahi. Hin sutlha lhon in lang hilang'ah hinkai lhon in.
Wí pé, “Ẹ lọ sí ìletò tí ó kọjú sí yín; nígbà tí ẹ̀yin bá wọ̀ ọ́ lọ, ẹ̀yin ó rí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan tí a so, tí ẹnikẹ́ni kò gùn rí, ẹ tú u, kí ẹ sì fà á wá.
31 Khattouvin ahindoh'a, ‘Ipibol'a hiche sangan nou chu nasut lhah lhon ham’ atileh, hitin seilhon'in, ‘Pakaiyin aman nom'e’ tilhon'in” ati.
Bí ẹnikẹ́ni bá sì bi yín pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tú u?’ Kí ẹ̀yin wí báyìí pé, ‘Olúwa ń fẹ́ lò ó.’”
32 Chutichun amani jong achelhon in, Yeshua sei bangin sangan nou chu agamu lhon tai.
Àwọn tí a rán sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó ti wí fún wọn.
33 Chule atahbah'in, asutlhon laiyin aneipan ahin adong lhon in, “Ipi bol'a hiche sangan nou chu nasutlhon ham?” ahin ti.
Bí wọ́n sì ti ń tú ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, àwọn Olúwa rẹ̀ bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń tu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà?”
34 Chule seijuite ni chun bailam tah in adonbut lhon in, “Pakaiyin aman nom'e” atilhone.
Wọ́n sì wí pé, “Olúwa fẹ́ lò ó.”
35 Hiti chun sangan nou chu Yeshua hengah ahin kaiyun chule aponsil hou chu achungah atouna dingin aphapeh un ahi.
Wọ́n sì fà á tọ Jesu wá, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sí ẹ̀yìn ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà, wọ́n sì gbé Jesu kà á.
36 Chutia ahung tou phei laiyin, mipihon lampi ah aponsil hou anaphauvin ahi.
Bí ó sì ti ń lọ wọ́n tẹ́ aṣọ wọn sí ọ̀nà.
37 Olive mol'a pat a lampi chesuh kipatna aphah chun, anungjui jousen kholhang asam un, ache toh lasah akop un, Pathen in thil kidang abolho amujal un avahchoiyuve.
Bí ó sì ti súnmọ́ etí ibẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè olifi, gbogbo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn bẹ̀rẹ̀ sí í yọ̀, wọ́n sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run, nítorí iṣẹ́ ńlá gbogbo tí wọ́n ti rí,
38 “Pakai min'a hung'ah lengpa chu anunnom e! Van ah cham leng hen, chule van sangpena jong loupi hen!” atiuve.
wí pé, “Olùbùkún ni ọba tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa!” “Àlàáfíà ní ọ̀run, àti ògo ni òkè ọ̀run!”
39 Ahivangin mihonpi lah'a Pharisee ho phabep khatchun aseiyun, “Houhil, nanungjui hon hitobang thuho aseiyu khu phohthip'in!” atiuve.
Àwọn kan nínú àwọn Farisi nínú àwùjọ náà sì wí fún un pé, “Olùkọ́ bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ wí.”
40 Aman adonbut in, “Amaho athipbeh uleh, lampam'a songho kipah'a hung eodoh diu ahi!” ati.
Ó sì dá wọn lóhùn, ó wí fún wọn pé, “Mo wí fún yín, bí àwọn wọ̀nyí bá pa ẹnu wọn mọ́, àwọn òkúta yóò kígbe sókè.”
41 “Ama Jerusalem ahung naijep'a khopi chu amuphat in akap pan tai.
Nígbà tí ó sì súnmọ́ etílé, ó síjú wo ìlú náà, ó sọkún sí i lórí,
42 Iti kadeisah nahi hitam tunikhon mijouse lah'a nangman chamna lampi hi kihet tave lechun. Ahinlah, tun ageisang tan, chamna hi namit mua kona kisel ahitai.
Ó ń wí pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ̀, lónìí yìí, àní ìwọ, ohun tí í ṣe tí àlàáfíà rẹ! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n pamọ́ kúrò lójú rẹ.
43 Sot louva nagalmi teu vin nakul pam'a pansatna akisem diu, amai lang jousea na umchin todiu ahi.
Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ fún ọ, tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò mọ odi bèbè yí ọ ká, àní tí wọn yóò sì yí ọ ká, wọn ó sì ká ọ mọ́ níhà gbogbo.
44 Amahon tol'a nachil thang diu, chule nachateu jong chutia abol diu. Nagalmi teu vin song khatcha aumna a aumsah louding ahi, ajeh chu huhhingna dinga phat kilemchang nasan loujeh ahi,” ati.
Wọn ó sì wó ọ palẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ; wọn kì yóò sì fi òkúta kan sílẹ̀ lórí ara wọn; nítorí ìwọ kò mọ ọjọ́ ìbẹ̀wò rẹ.”
45 Chuin Yeshua houin alut in, kilhaina ding gancha joh ho ahin nodoh pan tai.
Ó sì wọ inú tẹmpili lọ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lé àwọn tí ń tà nínú rẹ̀ sóde;
46 Aman amaho jah'a, “Pathen Lekhabun hitin aseiye, Ka in chu taona in kiti ding ahi, ahin nanghon gucha michom ho kokhuh in nasem tauve” ati.
Ó sì wí fún wọn pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ilé mi yóò jẹ́ ilé àdúrà?’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti sọ ọ́ di ihò àwọn ọlọ́ṣà.”
47 Chujou chun, aman niseh leh houin ah thu ahiljin, ahin thempuho, hou danthu hil ho chule adang mipi lamkai hon ama chu iti tha ding ham ti thilgon akisem pat un ahi.
Ó sì ń kọ́ni lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ṣùgbọ́n àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, àti àwọn olórí àwọn ènìyàn ń wá ọ̀nà láti pa á.
48 Ahivangin ima dang ageldoh chom pouve, ajeh chu mijousen athuhil apomchah jeh chun.
Wọn kò sì rí nǹkan kan tí wọn ìbá ṣe; nítorí gbogbo ènìyàn ṣù mọ́ ọn láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.

< Luke 19 >