< Cei 2 >

1 Pentecost nyn a pha awh hun pynoet awh kutoet na awm boeih uhy.
Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan.
2 Kawlhkalh awh khawhli awi amyihna khan nakawng awi ce law nawh a mingmih ang ngawihnaak ipkhui ce be khyp hy.
Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó.
3 Cawh thlang pynoet qip ak khanawh lai amyihna ak awm mai ce hu uhy.
Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn.
4 Cekkhqi boeih ce Ciim Myihla ing be unawh Myihla ing a pau sak amyihna awihchang na pau uhy.
Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.
5 Cawh khawnghi ak kai awh ak awm Khawsa ak kqih Juda thlangkhqi boeih boeih ce Jerusalem awh awm uhy.
Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu.
6 Cek awi ce a ming zaak awh thlang khawzah cun law unawh, thlang boeih ing ce amik awi pau ce amimah ak awina aming zaak awh amik kawpoekna kyi hy.
Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀.
7 Thlang boeih ing kawpoek kyi ngaihang doena, “Toek lah uh, vawhkaw awikhqi ve Galili awi boeih am nu?
Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́?
8 Ikawtinawh ni thangpyi awi amyihna ning zaak hy voei?
Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀?
9 Thlang vang Parthia khaw, Media ingkaw Elam khaw awhkaw ak awmkhqi; thlang vang taw Mesopotamia, Judah ingkaw Kapadocia, Pontus ingkaw Asia qamawh ak awmkhqi,
Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia.
10 Thlang vang bai taw Phrygia ingkaw Pamphylia, Izip ingkaw Libya qam Cyqene khaw keng awhkaw thlangkhqi, Rom khawawh ak awmkhqi ingkaw
Frigia, àti Pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù
11 (Judakhqi ingkaw Juda phung ak hqutkhqi); Crete ingkaw Arab thlangkhqi na ni awm hlai uhy – Khawsa ak kawpoek kyi ik-oeih sai ve nimah ak awi na ning za boeih thai ve!” ti uhy.
(àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.”
12 Thlang boeih amik kawpoek kyi ing, a kawnglam am zasim thai unawh, “Veve ikawmyih hly hy voei nu? ti unawh doet qu uhy.
Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”
13 Cawh thlang vang ingtaw qaihnakkhqi unawh, “Misur zuk thai ak quikhqi ni,” ti uhy.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.
14 Cehlai Piter taw thlanghqa hlaioet khqi mi dyi unawh, anih ing khawteh na ak awi y nawh awi kqawn hy, “Nangmih Juda khawkthlangkhqi ingkaw Jerusalem awh ak awm thlangkhqi boeih aw, ve ve sim unawh kak kqawn ve ngai lah uh.
Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi.
15 Vekkhqi ve nangmih ing namik poek amyihna, zu am qui uhy. Tuhawh mymcang khawnoek kow ni a law hun hy!
Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí.
16 Vetaw tawngha Joel ing anak kqawn ceni:
Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joẹli wá pé:
17 “Khawnghi a dyt tym awh ce, Khawsa ing, thlang boeih ce kang Myihla ing syp kawng nyng saw, nami capakhqi ingkaw nami canukhqi ing awi khypyi kawm uh. Cadawngkhqi ing hatnaak hu kawm usaw, pacawngkhqi ing mang han kawm uh.
“Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́, Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran, àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá,
18 Ka tamnaa pakhqi ingkaw ka tamnaa nukhqi ak khan awhawm kang Myihla syp kawng nyng saw, ka awi kqawn kawm uh.
àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin, ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀.
19 Khawhii awh kawpoek kyi themkhqi ingkaw, deklai kaiawh hatnaakkhqi ce nim huh kawng nyng; Thi, mai ingkaw maikhu ing dang sak kawng nyng.
Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run, àti àwọn àmì nísàlẹ̀ ilẹ̀; ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;
20 Bawipa a khawnghi bau ingkaw boeimangnaak ce a pha hlanawh, Khawmik ce than kawmsaw, pihla ce thi na thoeng kaw.
A ó sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.
21 Cawh u awm Bawipang ming ak khy boeih taw hulna awm kaw,’ a tice ni.
Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’
22 “Nangmih Israel thlangkhqi aw, ve ve ngai lah uh: Nazareth Jesu ce Khawsa ing dyihpyi nawh nangmih a venawh kawpoek kyi them ing hatnaakkhqi ce sai law sak hy, namimah ingawm sim uhyk ti.
“Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti àmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú.
23 Anih ce Khawsa ing khaw khan oepchoeh nawh a sim oepchoeh hawh amyihna, nangmih a kut awh peek nace awm hy; cawh nangmih ing thlakchekhqi ak bawngnaak ing anih ce thinglam awh khing nawh him uhyk ti.
Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, tí a sì pa á pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú, a kàn mọ́ àgbélébùú.
24 Cehlai anih ce Khawsa ing thihnaak awhkawng thawh sak tlaih nawh, thihnaak ingkaw khy am kqangnaak ak khuiawh kawng loet sak hawh hy, kawtih thihnaak ing anih ce am tu khak thai hy.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú, nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú.
25 David ing ak awi kqawn nawh, “Ka haiawh Bawipa ce hu poepa nyng. Ka ngai ama hangnaak aham kak tang benawh awm hy.
Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé: “‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí, nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi, a kì ó ṣí mi ní ipò.
26 Cedawngawh kak kawlung ve zeel nawh kam lai ve ak kaw zeel hy; Ka pum awm ngaih-unaak ing hqing kaw,
Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.
27 Ikawtih nang ing phyi khuiawh am nik khawng hyt kawm tiksaw, Nak thlang ciim ce thuh zip aham am ngaih kawp ti. (Hadēs g86)
Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs g86)
28 Nang ing hqingnaak lam ce nani sim sak hawh a dawngawh; Na haiawh zeelnaak ing ni be sak kawp ti,” tinawh kqawn hy.
Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè, ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’
29 Koeinaakhqi, pakdam David a kawng ve ak kqih kanaa nami venawh kqawn law nyng; anih ce thi nawh, phyi khui byihna awm hawh hy, ak phyi awm tuhdy ni venawh awm poe hy.
“Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí.
30 Anih taw tawngha na awm nawh, Khawsa ing a venawh awikam nawh amah a ngawihdoelh awh a cadil thlang pynoet ngawih sak kaw tinawh awi a taak ce sim hy.
Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
31 Ni hai benawh ak awm law hly kawi ik-oeih ce a sim oepchoeh a dawngawh, anih ce phyi khuiawh am khawng hyt kawmsaw, a pum awm am thu kaw, tinawh Khrih a thawh tlaihnaak akawng ce anak kqawn oepchoeh hawh hy. (Hadēs g86)
Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs g86)
32 Cawhkaw Jesu ce Khawsa ing thawh sak tlaih nawh, cawhkaw ik-oeih ak simpyikung dyihthing na kaimih ve awm unyng.
Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí.
33 Pa ak tang benawh zoeksangna awm nawh, Pa ing awi ataak Ciim Myihla ce hu hawh hy, nami huh naming zaak ve ing syypna awm nawh ni.
A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta.
34 David ce khawk khan na am kaai hy, anih qoe ing, “Bawipa ing ka Bawipa venawh: 'Kak tang benawh ngawi lah.
Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé, “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
35 Na qaalkhqi ce na khawtloeng na ka taak hlan dy,” tinawh anak kqawn hy.
títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.”’
36 Cedawngawh Israel thlangkhqi boeih ing ve ve sim lah uh: Nangmih ing thinglam awh nami taai Jesu ce Khawsa ing Boei ingkaw Khrih na sai hawh hy,” tinak khqi hy.
“Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé, Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”
37 Thlangkhqi ing ce ak awi ce a ming zaak awh, amik kawlung awh sun amyihna za unawh, Piter ingkaw ceityihkhqi venawh, “Koeinaakhqi ikawmyihna nu ka mi ti kaw?” tinawh doet uhy.
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”
38 Piter ing, “Thawlh zut unawh taw, thawlh qeenkhaw ngainaak aham, Jesu Khrih ang ming awh baptisma hu boeih uh. Cawhtaw Ciim Myihla themzoe peek ce hu kawm uk ti.
Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́.
39 Vawhkaw awikamnaak vetaw na mimah aham, nami cakhqi ham ingkaw ak hla nakaw ak awm thlangkhqi boeih – Bawipa nangmih a Khawsa ing ak khy thlangkhqi boeih aham ni,” tinak khqi hy.
Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”
40 Awih chang khawzah ing a mingmih a venawh ngaihtaaknaak awi kqawn pek khqi hy; a mingmih a venawh, “Vawhkaw ak plam cadilkhiq anglak awhkawng na mimah ingkaw na mimah ce hul qu lah uh,” tinawh kqawncaih pek khqi hy.
Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.”
41 Anih ak awih kqawn ak dokhqi boeih ing baptisma ce hu uhy, ce a nyn awh ce thlang thong thum ing sap khqi hy.
Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.
42 Ceityihkhqi a cawngpyinaak awi ce ngai unawh pawlnengnaak ce ta uhy, phaihpi thek unawh cykcah uhy.
Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà.
43 Thlang boeih kqihnaak ing be unawh ceityihkhqi ing kawpoek kyi hatnaakkhqi ce sai uhy.
Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe.
44 Ak cangnaak thlangkhqi boeih ing them pynoet na cuut uhy.
Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn;
45 Ami khawhthemkhqi ce zawi unawh, ak voethlauh thlangkhqi ce pe uhy.
Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí.
46 Myngawi na bawkim awh cun poepa uhy. Im awh phaihpi ce teei unawh kawlung kutoet cana zeelnaak ing ai haih uhy,
Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn.
47 Khawsa ce a mim kyihcah coengawh thlang boeih ak kawngaih na khaw sa uhy. Hulnaak ak hukhqi ing Bawipa ing a mingmih ce myngawi na sap khqi hy.
Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.

< Cei 2 >