< Nehemiah 1 >

1 Hakaliah capa Nehemiah ol khaw kum kul Kislev hla vaengah om coeng. Te vaengah kai tah Shushan rhalmah im ah ka om.
Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
2 Te vaengah ka manuca rhoek khuikah pakhat Hanani ha pawk. Amah neh Judah lamkah hlang rhoek khaw om. Amih taengah tamna lamloh aka sueng rhalyong Judah kawng neh Jerusalem kawng te ka dawt.
Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
3 Te vaengah paeng khuikah yoethae len khui neh kokhahnah khuiah tamna lamkah aka sueng, aka sueng rhoek loh kai taengah, “Jerusalem vongtung tim tih a vongka khaw hmai neh a hlup uh coeng,” a ti uh.
Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
4 He ol he ka yaak vaengah ka ngol tih ka rhap. Khohniyung ah ka nguekcoi neh ka om. Vaan Pathen mikhmuh ah ka yaeh tih ka thangthui.
Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
5 Te phoeiah, “Aw, vaan kah Pathen Yahweh, ka om Khohni, Pathen tah len tih rhih om pai. Amah aka lungnah taeng neh a olpaek aka ngaithuen taengah paipi neh sitlohnah a ngaithuen pah.
Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
6 Na sal kah thangthuinah te yaak hamla na hna khui tih na mik aka dai la om laeh. Kai he tihnin ah khaw na sal Israel ca ham khoyin khothaih na mikhmuh ah ka thangthui coeng. Namah taengah ka tholh uh bangla Israel ca kah tholhnah te kam phoe. Kamah neh a pa imkhui khaw ka tholh uh coeng.
Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
7 Na taengah laikoi la ka laikoi uh coeng tih na sal Moses taengah na uen olpaek neh oltlueh khaw, laitloeknah khaw ka ngaithuen uh pawh.
Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
8 Na sal Moses ol na uen tih, “Boe na koek uh dongah nangmih te pilnam lakli ah kan taekyak ni,” na ti nah te thoelh laeh.
“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
9 Tedae kai taengla na mael uh tih ka olpaek he ngaithuen neh na vai atah vaan khobawt la nangmih aka heh te om cakhaw amih te te lamloh ka coi vetih ka ming om sak ham ka coelh hmuen la amih te pahoi ka khuen rhoe ka khuen ni,’ na ti.
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
10 Amih te na sal neh na pilnam ni. Te rhoek te na len thadueng neh, na tlungluen kut neh na lat.
“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
11 Ka Boeipa aw, na sal rhoek kah thangthuinah taengah khaw na ming rhih ham aka omtoem na sal rhoek kah thangthuinah dongah na hna aka khui sak la om laeh. Tihnin kah na sal te khaw thaihtak sak laeh. Anih te hlang mikhmuh ah haidamnah neh pae,” ka ti. Te vaengah kai tah manghai taengah tuitul kung la ka om.
Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

< Nehemiah 1 >