< Jeremiah 7 >

1 BOEIPA taeng lamkah ol te Jeremiah taengla pawk tih,
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 'BOEIPA im kah vongka ah pai lamtah he ol he pahoi doek laeh. Te vaengah BOEIPA taengah thothueng ham he kah vongka la aka pawk Judah pum te, 'BOEIPA ol he ya uh,’ ti nah,” a ti.
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Israel Pathen caempuei BOEIPA loh, “Na longpuei neh na khoboe tlaih uh laeh. Te daengah ni hekah hmuen ah nangmih te om sak eh.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Nangmih loh a hong ol dongah pangtung uh boeh. BOEIPA kah bawkim, BOEIPA kah bawkim, BOEIPA kah bawkim,” a ti uh.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Na longpuei neh na khoboe te na tlaih la na tlaih atah, hlang laklo neh a hui laklo ah tiktamnah na saii la, na saii uh atah,
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 Yinlai, cadah neh nuhmai hnaemtaek uh boel lamtah he hmuen ah ommongsitoe thii kingling uh boeh, nangmih aka thae sak pathen tloe rhoek hnukah na pongpa pawt atah,
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 Na pa rhoek taengah khosuen lamloh kumhal duela ka paek khohmuen kah he hmuen ah nangmih kang om sak ni.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Nangmih tah namamih ham aka hoeikhang pawh a hong ol dongah ni na pangtung uh te.
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 Huen ham, ngawn ham neh samphaih ham nim a honghi neh na toemngam uh? Baal taengah na phum uh tih ming pawt pathen tloe rhoek hnukah na pongpa uh.
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 Kai ming la a khue he im khuikah ka mikhmuh la na pawk uh tih na pai uh vaengah, “He rhoek kah tueilaehkoi he boeih n'saii uh akhaw n'huul uh,” na ti uh.
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Ka ming aka phuei im he nangmih mik ah dingca kah lungko la poeh coeng a? Tedae kai loh kam hmuh coeng he,” a ti. He tah BOEIPA kah olphong ni.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 Te dongah Shiloh kah ka hmuen te paan uh laeh. Te ah tah ka ming om lamhma coeng dae ka pilnam Israel kah boethae kongah anih soah ka saii te hmuh uh lah.
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 Te bibi te boeih na saii coeng dongah BOEIPA kah olphong bangla nang taengah kan thui. Na thoh hang vaengah ka thui dae na yaak moenih. Nangmih te kang khue dae nan doo uh moenih.
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 Ka ming la a khue tih nangmih a khuiah na pangtung thil im te ka saii pueng ni. Nangmih taeng neh na pa rhoek taengah kam paek tangtae hmuen pataeng Shiloh taengkah bangla ka saii coeng.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 Na manuca rhoek boeih neh Ephraim tiingan boeih khaw ka voeih bangla ka mikhmuh lamloh nangmih te kam voeih ni.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Te dongah nang tah he pilnam yueng thangthui boeh, amih ham tamlung neh thangthuinah khaw ludoeng pah boeh. Kai he nan doo pawt dongah nang ol aka ya la kai ka om moenih.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Judah loh khopuei neh Jerusalem tollong ah amih loh mebang a saii khaw na hmuh moenih a?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Ca rhoek loh thing a coi uh tih a napa rhoek loh hmai a toih uh. Manu rhoek loh vaan boeinu kah rhaibuh la saii pah ham vaidamtlam a nook uh. Kai aka veet hamla pathen tloe rhoek taengah tuisi a bueih.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Amih nim kai aka veet rhoek te. BOEIPA kah olphong ni he. A maelhmai ah yahpohnah aka om ham amih moenih a?
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 Te dongah ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Ka thintoek neh ka kosi tah he hmuen sokah hlang so neh rhamsa soah, khohmuen thingkung so neh diklai thaihtae soah bo coeng. Te long te a dom vetih thi mahpawh.
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Israel Pathen caempuei BOEIPA loh, “Na hmueihhlutnah neh na hmueih te koei lamtah a saa te ca nawn.
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Na pa rhoek te Egypt kho lamloh a khuen la ka khuen khohnin vaengah hmueihhlutnah neh hmueih kawng dongah amih te ol ka uen moenih.
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 Tedae amih te hekah ol he lat ka uen tih, “Ka ol he hnatun uh lamtah nangmih kah Pathen la ka om bitni. Nangmih khaw ka pilnam la om uh. Nangmih kang uen longpuei ah boeih pongpa uh lamtah nangmih taengah voelphoeng van saeh,” ka ti.
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Tedae hnatun uh pawt tih a hna te kaeng uh pawh. A lungbuei boethae kah thinthahnah dongah cilkhih te a paan uh tih a hnuk a hmai pawt ah khaw om uh.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 Egypt kho lamkah na pa rhoek aka pawk uh hnin lamloh tihnin duela nangmih taengah ka sal rhoek boeih kan tueih. Tonghma rhoek te hnin takhuem a thoh hang neh kan tueih coeng.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 Tedae kai ol te ya uh pawt tih a hna te kaeng uh pawh. A rhawn a mangkhak sak uh tih a napa rhoek lakah thae uh ngai.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 He kah ol he amih taengah boeih na thui dae nang ol te a yaak uh moenih. Amih te na khue akhaw nang te n'doo uh moenih.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 Te dongah amih taengah “Namtom long he a Pathen BOEIPA ol te hnatun uh pawt tih thuituennah khaw doe uh pawh. Amih kah ka lamkah tah uepomnah khaw moelh tih talh coeng,” ti nah.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Na rhuisam bawt lamtah voei laeh. Caphoei cuk ah rhahlung khuen laeh. BOEIPA loh a hnawt tih a thinpom kah cadilcahma khaw a phap coeng lah ko.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 Judah ca rhoek loh ka mikhmuh ah boethae ni a saii uh. BOEIPA kah olphong ni he. Im ah a sarhingkoi te a khueh uh tih ming aka poeih rhung la ka ming a phoei.
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Topheth hmuensang te a khoeng uh tih kolrhawk kah hmai dongah a canu, a capa rhoek te a hoeh uh. Te te ka uen pawt tih ka lungbuei ah khaw a kun moenih.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 Te dongah BOEIPA kah olphong ha phawk tarha nah hnin ah tah Topheth neh kolrhawk te koep phoei voel mahpawh. Tedae ngawnnah kolrhawk lakah Topheth ah ni hmuen a om pawt hil a up uh eh.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 Te vaengah pilnam kah a rhok he vaan kah vaa neh diklai rhamsa ham maeh la a om pah vetih aka hawt khaw om mahpawh.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 Judah khopuei rhoek khui neh Jerusalem tollong kah omngaihnah ol neh kohoenah ol khaw, yulo kah ol neh vasa ol khaw ka duem sak ni. Diklai te imrhong la om ni.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.

< Jeremiah 7 >