< Ezra 10 >

1 Ezra he a thangthui vaengah khaw a uem vaengah khaw a rhah neh Pathen im hmai ah bakop. A taengah Israel hlangping lamloh tongpa neh huta neh camoe neh uep tingtun uh khungdaeng. Pilnam khaw lungnat neh bungbung rhap uh.
Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
2 Te vaengah Elam kah Elam koca Jehiel capa Shekaniah loh a doo tih Ezra te, “Mamih tah mamih kah Pathen taengah boe n'koek uh dongah khohmuen pilnam lamkah kholong nu neh kho n'sak uh. Te cakhaw Israel ham ngaiuepnah om coeng.
Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
3 Te dongah ka boei rhoek neh mamih kah Pathen olpaek dongah aka thuen rhoek kah cilsuep bangla huta rhoek neh amih kah a cun boeih te tueih hamla mamih kah Pathen taengah paipi saii uh pawn sih lamtah olkhueng bangla vai uh saeh.
Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
4 Olka he namah hut coeng dongah thoo lamtah kaimih khaw nang taengah ka omuh. Thaahuel lamtah saii laeh,” a ti nah.
Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
5 Te dongah Ezra thoo tih a toemngam. Levi khosoih mangpa rhoek neh Israel boeih long khaw te ol bangla saii ham a toemngam uh.
Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
6 Te phoeiah tah Ezra te Pathen im hmai lamloh thoo tih Eliashib capa Jehohanan kah imkhan la cet. Buh te pahoi a paan dae ca pawt tih vangsawn boekoeknah ham a nguekcoi dongah tui khaw o pawh.
Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
7 Te dongah vangsawn koca boeih te Jerusalem la coi ham Judah neh Jerusalem ah ol a pat.
Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
8 Mangpa rhoek neh a hamca rhoek kah cilsuep bangla hnin thum khuiah aka pawk pawt boeih tah a khuehtawn boeih thup pah saeh lamtah anih te vangsawn hlangping lamloh hoep saeh,’ a ti.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
9 Te dongah Judah hlang neh Benjamin, Jerusalem pum tah hla ko hla kah hnin kul vaengah hnin thum khuiah tingtun uh. Te vaengah pilnam pum te Pathen im kah toltung ah ngol uh. Tekah ol neh khonal dong lamloh amih te thuen uh.
Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
10 Te vaengah khosoih Ezra pai tih amih te, “Boe na koek tih Israel kah dumlai te koei hamla kholong nu neh kho na sak uh.
Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
11 Te dongah na pa rhoek kah Pathen BOEIPA taengah tholh phongnah khueh uh laeh. A kolonah te saii uh lamtah khohmuen pilnam taeng lamkah neh kholong nu taeng lamloh hoep uh laeh,” a ti nah.
Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
12 Hlangping pum loh a doo uh tih ol a len la, “Namah ol van tangloeng ni, na ol bangla kaimih taengah saii pai.
Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
13 Tedae pilnam he ping tih khonal tue la om bal. Te dongah tollong ah pai ham thadueng a om moenih. He ol dongah boekoek la a ping dongah bitat he hnin at nen bueng pawt tih hnin nit ah coeng mahpawh.
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
14 Hlangping boeih hamla mamih kah mangpa rhoek he pai mai saeh. Te phoeiah mah kho khuikah kholong nu neh kho aka sa boeih te a caeng tue bangla kun sak saeh. He olka dongah kaimih Pathen kah thintoek thinsa te kaimih lamloh a mael hil amih neh kho, kho kah a hamca rhoek loh laitloek saeh.
Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
15 Asahel capa Jonathan neh Tikvah capa Jahaziah loh he he a tlai thil tih amih rhoi te Levi Meshullam neh Shabbethai loh a bom.
Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
16 Te dongah vangsawn koca rhoek loh a saii uh. Te phoeiah khosoih Ezra loh hlang rhoek te a napa imkhui tarhing ah a napa boeilu neh a boel. A hla rha dongkah hnin lamhmacuek vaengah Amih boeih te a ming neh ol dawt hamla ngol uh.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
17 Lamhmacuek hla kah lamhmacuek khohnin ah kholong nu neh aka om hlang boeih te a khah uh.
ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
18 Te vaengah khosoih koca rhoek khuiah Jeshua koca lamkah Jozadak capa neh amah boeinaphung Maaseiah, Eliezer, Jarib neh Gedaliah tah kholong nu neh kho a sak te a hmuh.
Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
19 Te dongah a yuu rhoek te tueih hamla a kut te a yuh uh tih amamih kah dumlai dongah boiva la tutal a rhaem uh.
Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
20 Te phoeiah Immer koca rhoek lamloh Hanani neh Zebadiah.
Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
21 Harim koca lamloh Maaseiah, Elijah, Shemaiah, Jehiel neh Uzziah.
Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
22 Pashur koca lamloh Elioenai, Maaseiah, Ishmael, Nethanel, Jozabad neh Elasah.
Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
23 Levi lamloh Jozabad, Shimei, Kelaiah, Kelita, Pethahiah, Judah neh Eliezer.
Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
24 Laa sa rhoek lamloh Eliashib, thoh tawt lamloh Shallum, Telem neh Uri.
Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
25 Israel khuiah khaw Parosh koca lamloh Ramiah, Izziah, Malkhiah, Mijamin, Eleazar, Malkhiah neh Benaiah.
Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
26 Elam koca lamloh Mattaniah, Zekhariah, Jehiel, Abdi, Jerimoth neh Elijah.
Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
27 Zattu koca lamloh Elioenai, Eliashib, Mattaniah, Jerimoth, Zabad neh Aziza.
Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
28 Bebai koca lamloh Jehohanan, Hananiah, Zabbai neh Athlai.
Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
29 Bani koca lamloh Meshullam, Mallukh, Adaiah, Jashub, Sheal, Jerimoth neh Ramah.
Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
30 Pahathmoab koca lamloh Adna, Khelal, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Bezalel, Binnui neh Manasseh.
Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
31 Harim koca ah Eliezer, Isshiah, Malkhiah, Shemaiah, Simeon.
Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
32 Benjamin, Mallukh neh Shemariah.
Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
33 Hashum koca lamloh Mattenai, Mattathah, Zabad, Eliphelet, Jeremai, Manasseh neh Shimei.
Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
34 Bani koca lamloh Maadai, Amram neh Uel.
Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
35 Benaiah, Bedeiah neh Keluhi kah Keluhi.
Benaiah, Bediah, Keluhi
36 Vaniah, Meremoth neh Eliashib.
Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
37 Mattaniah, Mattenai neh Jaasau.
Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
38 Bani, Binnui, Shimei.
Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
39 Shelemiah, Nathan neh Adaiah.
Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
40 Macnadebai, Shashai neh Sharai.
Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
41 Azarel, Shelemiah neh Shemariah.
Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
42 Shallum, Amariah neh Joseph.
Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
43 Nebo koca lamloh Jeiel, Mattithiah, Zabad, Zebina, Iddo, Joel neh Benaiah.
Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
44 He rhoek boeih long he kholong nu a loh, a loh uh tih amih a yuu rhoek lamloh camoe a cun uh.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

< Ezra 10 >