< Amos 1 >

1 Tekoa kah saelhung boei rhoek khuikah aka om Amos ol. Judah manghai Uzziah tue neh Israel manghai Joash capa Jeroboam tue, lingluei hmai kah kum vaengah Israel ham a hmuh pah.
Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
2 BOEIPA tah Zion lamloh kawk tih Jerusalem lamloh a ol a huel tih a thui. Te vaengah boiva aka dawn kah rhamtlim te nguekcoi tih Karmel lu rhae coeng.
Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
3 BOEIPA loh he ni a thui. Damasku kah boekoeknah pathum neh pali dongah anih te ka rhael mahpawh. Gilead te thi vueituk neh a boh.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
4 Te dongah Hazael im ah hmai ka tueih vetih Benhadad impuei a hlawp ni.
Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5 Damasku thohkalh te ka khaem vetih kolbawn lamkah khosa rhoek khaw, Betheden kah caitueng aka pom khaw ka thup ni. Aram kah pilnam te Kir la a poelyoe uh ni tila BOEIPA loh a thui.
Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
6 BOEIPA loh he ni a thui. Gaza kah boekoeknah pathum phoeikah pali dongah anih ka rhael mahpawh. Amih hlangsol a poelyoe tih Edom taengah rhuemtuet la a det.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7 Gaza vongtung soah hmai ka tueih vetih a impuei khaw a hlawp pah ni.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
8 Ashdod kah khosa neh Ashkelon kah caitueng aka pom rhoek khaw ka thup ni. Ekron taengah ka kut ka thuung vetih Philisti kah a meet rhoek khaw milh uh ni tila Boeipa Yahovah loh a thui.
Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 BOEIPA loh he ni a thui. Tyre kah boekoeknah pathum neh pali dongah anih te ka rhael mahpawh. Hlangsol te Edom taengah rhuemtuet la a det tih manuca kah paipi te poek uh pawh.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
10 Te dongah Tyre vongtung soah hmai ka tueih vetih a impuei khaw a hlawp pah ni.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11 BOEIPA loh he ni a thui. Edom kah boekoeknah pathum ham neh pali ham te anih ka rhael mahpawh. A manuca te cunghang neh a hloem tih a haidamnah khaw a porhak sak. A thintoek a yoeyah la a paem tih a thinpom te a ngaithuen yoeyah.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
12 Te dongah Teman soah hmai ka tueih vetih Bozrah impuei khaw a hlawp pah ni.
Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
13 BOEIPA loh he ni a thui. Ammon ca rhoek kah boekoeknah pathum ham neh pali ham te anih ka rhael mahpawh. Amamih kah khorhi dangka hamla Gilead bungvawn rhoek te a boe uh.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Te dongah hmai tah Rabbah vongtung dongah ka hlup pah vetih a impuei khaw a hlawp pah ni. Caemtloek hnin ah tamlung neh cangpalam hnin kah hlipuei.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Amih kah manghai amah neh a mangpa rhoek vangsawn la rhenten cet ni tila BOEIPA loh a thui.
Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.

< Amos 1 >