< 2 Siangpahrang 1 >

1 Ahab duek pacoengah, Moab mah Israel to tuk.
Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
2 Ahaziah loe Samaria vangpui ah ranuih ih thokbuem hoiah krak moe, ngannat pongah, Hae nathaih hoi ngantui let tih maw tiah dueng hanah, Ekron vangpui ih sithaw Baal-Zebub khaeah laicaeh patoeh.
Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
3 Toe Angraeng ih van kami mah Tishbeh acaeng Elijah khaeah, Angthawk loe, Samaria siangpahrang ih laicaehnawk to tongh hanah caeh tahang ah; nihcae khaeah, Israel prae ah Sithaw om ai pongah maw, Ekron sithaw Baal-Zebub khaeah lokdueng hanah na caeh?
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
4 To pongah vaihi Angraeng mah, Nang songhaih ihkhun nui hoiah nang hum mak ai; na dueh tangtang tih boeh, tiah thuih, tiah a naa. To pongah Elijah loe caeh moe, anih mah thuih ih baktih toengah a thuih pae.
Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
5 Laicaehnawk siangpahrang khaeah amlaem o let naah, siangpahrang mah nihcae khaeah, Tipongah nam laem o let loe? tiah a naa.
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
6 Nihcae mah siangpahrang khaeah, Kaicae tongh hanah kami maeto angzoh, anih mah kaicae khaeah, Nangcae patoehkung siangpahrang khaeah amlaem o let ah loe, Angraeng mah, Israel prae ah Sithaw om ai pongah maw Ekron sithaw, Baal-Zebub khaeah lokdueng hanah kami na patoeh? To pongah nang loe angsonghaih ihkhun nui hoiah nang hum mak ai, na dueh tangtang tih boeh, tiah thuih, tiah thui pae oh, tiah ang naa, tiah a thuih pae o.
Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
7 Siangpahrang mah nihcae khaeah, Hae loknawk thuih hanah nangcae tongh kami loe kawbaktih kami maw? tiah a naa.
Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
8 Nihcae mah siangpahrang khaeah, Anih loe nganmui pop kami, kaeng ah moihin qui angzaeng kami ah oh, tiah a naa o. To naah siangpahrang mah, Anih loe Tishbeh acaeng Elijah bae to, tiah a naa.
Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
9 To naah siangpahrang mah misatuh angraeng maeto hoiah anih ih kami quipangatonawk to Elijah khaeah patoeh. Khenah, misatuh angraeng loe mae nuiah kanghnu, Elijah khaeah caeh tahang moe, anih khaeah, Sithaw kami, siangpahrang mah, Angzo tathuk nasoe, tiah a thuih, tiah a naa.
Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
10 Elijah mah misatuh angraeng khaeah, Sithaw kami ah ka oh nahaeloe, van hoi hmai krah tathuk nasoe loe, nangmah hoi nang mah ih kami quipangatonawk to kangh nasoe, tiah a naa. Van hoiah hmai to krak tathuk moe, misatuh angraeng hoiah anih ih kami quipangatonawk to kangh.
Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 To pacoengah siangpahrang mah misatuh angraeng maeto hoi anih ih kami quipangatonawk to patoeh let. Misatuh angraeng mah anih khaeah, Sithaw kami, siangpahrang mah, Karangah angzoh tathuk nasoe, tiah a thuih, tiah a naa.
Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
12 Elijah mah nihcae khaeah, Sithaw kami ah ka oh nahaeloe, van hoiah hmai krah tathuk nasoe loe, nangmah hoi na taengah kaom kami quipangatonawk to kangh nasoe, tiah a naa. To naah van hoiah Sithaw ih hmai to krak tathuk moe, anih hoi anih ih kami quipangatonawk to kangh.
“Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
13 Anih mah thumto haih misatuh angraeng maeto hoi kami qui pangaonawk to patoeh let. Thumto haih misatuh angraeng loe caeh tahang moe, Elijah hmaa ah khokkhu cangkrawn hoi akuep moe, anih khaeah, Sithaw kami, ka hinghaih hoi na tamna quipangatonawk ih hinghaih to na pathlung pae hanah tahmenhaih kang hnik.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
14 Khenah, van hoiah hmai krak tathuk moe, hmaloe ih misatuh kaminawk hoi hnetto haih misatuh angraeng loe hmai mah kangh boih boeh, toe vaihi ka hinghaih na pathlung raeh, tiah a naa.
Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
15 Angraeng ih van kami mah Elijah khaeah, Anih hoi nawnto caeh tathuk ah; anih to zii hmah, tiah a naa. Elijah loe angthawk moe, siangpahrang khaeah anih hoi nawnto caeh tathuk.
Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
16 Anih mah siangpahrang khaeah, Angraeng mah, Israel prae ah lokdueng hanah Sithaw om ai pongah maw, Ekron sithaw Baal-Zebub khaeah lokdueng hanah kami na patoeh? To pongah nang songhaih ihkhun nui hoiah natuek naah doeh nang hum tathuk mak ai, na dueh tangtang tih boeh, tiah a naa.
Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
17 To pongah Angraeng mah Elijah khaeah thuih pae ih lok baktih toengah, anih loe duek. Ahaziah loe capa tawn ai pongah, Judah siangpahrang Jehosaphat capa Jehoram siangpahrang ah ohhaih saning hnetto naah, amnawk Jehoram mah siangpahrang tok to sak.
Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
18 Ahaziah siangpahrang ah oh nathung, a sak ih kalah hmuennawk boih loe Israel siangpahrangnawk ahmin pakuemhaih cabu thungah tarik o na ai maw?
Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?

< 2 Siangpahrang 1 >