< Amos 9 >

1 Nakita ko ang Ginoo nga nagtindog kilid sa halaran, ug miingon siya, “Hampaka ang tumoy sa mga haligi sa templo aron nga matay-og ang mga patukuranan. Dugmoka ang templo aron mahulog sa ilang mga ulo, ug patyon ko ang nahibilin kanila pinaagi sa espada. Walay usa kanila ang makalingkawas ug walay usa kanila nga makaikyas.
Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé: “Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn kí àwọn òpó kí ó lè mì fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa, ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé, ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
2 Bisan pa ug mokalot sila paingon sa Seol, kuhaon ko gihapon sila sa akong mga kamot. Bisan pa ug mosaka sila sa langit, pakanaogon ko gihapon sila. (Sheol h7585)
Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú, láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀. (Sheol h7585)
3 Bisan pa ug motago sila sa tumoy sa bukid sa Carmel, pangitaon ko sila didto ug kuhaon. Bisan pa ug motago sila gikan sa akong panan-aw ngadto sa kinahiladman sa dagat, mandoan ko didto ang mga bitin ug mopaak kini kanila.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli, èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀. Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun, láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
4 Bisan pa ug pangbihagon sila, sa ilang mga kaaway nga naggukod kanila, mandoan ko ang mga espada, ug mopatay kini kanila. Itutok ko ang akong mga mata kanila alang sa kadaotan ug dili sa kaayohan.”
Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa. “Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí, kì í sì í ṣe fún rere.”
5 Gihikap ni Yahweh nga Ginoo nga labawng makagagahom ang yuta ug natunaw kini; nagbangotan ang tanang nagpuyo niini; motungha ang tanan niini sama sa suba, ug mokunhod pag-usab sama sa suba sa Ehipto.
Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
6 Siya kining nagbuhat sa iyang hagdanan sa kalangitan, ug nagbuhat sa iyang lawak sa kalibotan. Gitawag niya ang mga tubig sa kadagatan, ug gibubo kini ibabaw sa kalibotan, Yahweh ang iyang ngalan.
Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé, Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé Olúwa ni orúkọ rẹ̀.
7 “Dili ba alang kanako sama man kamo sa katawhan sa Etiopia, kamong Israelita? — mao kini ang pahayag ni Yahweh. Dili ba gipalingkawas ko man ang Israel gikan sa yuta sa Ehipto, ang mga Filistihanon gikan sa Crete ug ang Sirianhon gikan sa Kir?
“Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?” ni Olúwa wí. “Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori àti àwọn ará Aramu láti Kiri?
8 Tan-awa, nagbantay ang mga mata sa Ginoo nga si Yahweh sa makasasala nga gingharian, ug laglagon ko kini gikan sa kalibotan, gawas lamang sa banay ni Jacob nga dili ko laglagon sa hingpit — mao kini ang pahayag ni Yahweh.
“Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀. Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀. Síbẹ̀, Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,” ni Olúwa wí.
9 Tan-awa, magmando ako, ug tay-ogon ko ang puluy-anan sa Israel taliwala sa tanang kanasoran, sama sa pag-ayag sa trigo sa ayagan, aron nga walay mahulog bisan labing gamay nga bato ngadto sa yuta.
“Nítorí Èmi yóò pàṣẹ, Èmi yóò sì mi ilé Israẹli ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀ tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
10 Mamatay ang tanang makasasala nga akong katawhan pinaagi sa espada, kadtong miingon nga, ''Ang katalagman dili gayod modangat.'
Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi ni yóò ti ipa idà kú gbogbo àwọn ti ń wí pé, ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’
11 Nianang mga adlawa tukuron ko ang tolda ni David nga napukan, ug ayohon ang mga kota niini. Tukuron ko ang mga nagun-ob, ug tukuron ko kini pag-usab sama sa nangaging mga adlaw,
“Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró, Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya, Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè, Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
12 Aron nga ilang maangkon ang nahibilin sa Edom, ug ang tanang nasod nga gitawag sa akong ngalan — mao kini ang pahayag ni Yahweh— gihimo niya kini.
kí wọn le jogún ìyókù Edomu àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,” ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
13 Tan-awa, moabot ang mga adlaw—mao kini ang pahayag ni Yahweh — Sa dihang ang magdadaro makaapas sa mangangani, ug ang mga tigpuga sa bino makaapas kaniya nga nagpugas sa binhi. Motulo ug tam-is nga bino sa kabukiran ug modagayday kini sa tanang kabungtoran.
“Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí, “tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá. Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá. Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀, tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèké.
14 Dad-on ko pagbalik gikan sa pagkabihag ang akong katawhan sa Israel. Tukoron nila ang nagun-ob nga mga siyudad ug puy-an kini, magtanom sila ug mga paras ug manginom sa mga bino niini, ug maghimo sila ug mga tanaman ug mangaon sa mga bunga niini.
Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀. “Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn. Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn.
15 Itanom ko sila sa ilang mga kayutaan, ug dili na gayod sila pagaibton pa gikan sa yuta nga akong gihatag kanila,” nag-ingon si Yahweh nga imong Ginoo.
Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀. A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,” ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.

< Amos 9 >