< Lucas 7 >

1 Y pur acabó de penar sarias oconas vardas á la sueti, sos junelaba, se chaló andré Capharnaúm.
Nígbà tí ó sì parí gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀ fun àwọn ènìyàn, ó wọ Kapernaumu lọ.
2 Y sinaba oté baribu merdo y casi á la meripen yeque lacró de yeque Centurion; sos sinaba baribu pachibelado de ó.
Ọmọ ọ̀dọ̀ balógun ọ̀rún kan, tí ó ṣọ̀wọ́n fún un, ṣàìsàn, ó sì ń kú lọ.
3 Y pur juneló penar de Jesus, bichabó á ó yeques pures es Chuti, manguelandole, que abillase á chibar lacho á desquero lacró.
Nígbà tí ó sì gbúròó Jesu, ó rán àwọn àgbàgbà Júù sí i, ó ń bẹ̀ ẹ́ pé kí ó wá mú ọmọ ọ̀dọ̀ òun láradá.
4 Y junos, yescotria que abilláron á Jesus, le querelaban barias instancias, penando: Merece que le otorguisareles ocono.
Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n fi ìtara bẹ̀ ẹ́, pé, “Ó yẹ ní ẹni tí òun ìbá ṣe èyí fún.
5 Presas camela á amari rati: y ó amangue ha querdi yeque cangri.
Nítorí tí ó fẹ́ràn orílẹ̀-èdè wa, ó sì ti kọ́ Sinagọgu kan fún wa.”
6 Y Jesus chalaba sat junos. Y pur sinaba sunparal é quer, bichabó á ó el Centurion desqueres monres, penando: Erañó, na ustileles ocona trabajo, que menda na sinelo cabalico de que chales andré de minrio guer.
Jesu sì ń bá wọn lọ. Nígbà tí kò sì jìn sí etí ilé mọ́, balógun ọ̀rún náà rán àwọn ọ̀rẹ́ sí i, pé, “Olúwa, má ṣe yọ ara rẹ lẹ́nu, nítorí tí èmi kò yẹ tí ìwọ ìbá fi wọ abẹ́ òrùlé mi.
7 Por ocono ni aun he penchabado mangue cabalico de nichobelar á orotarte: Tami penlo sat yeque varda, y sinará chibado lacho minrio lacró.
Nítorí náà èmi kò sì rò pé èmi náà yẹ láti tọ̀ ọ́ wá, ṣùgbọ́n sọ ní gbólóhùn kan, a ó sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ mi láradá.
8 Presas menda tambien sinelo manu chitado ostely de las vardas de averes, y terelo jundunares ostely de mangue; y penelo á ocona: Cha, y chala; y al aver; Abillel, y abillela; y al lacro de mangue: Querel ocono, y querela.
Nítorí èmi náà pẹ̀lú jẹ́ ẹni tí a fi sí abẹ́ àṣẹ, tí ó ní ọmọ-ogun lẹ́yìn mi, mo sì wí fún ọ̀kan pé, ‘Lọ,’ a sì lọ; àti fún òmíràn pé, ‘Wá,’ a sì wá; àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ mi pé, ‘Ṣe èyí,’ a sì ṣe é.”
9 Pur Jesus junelo ocono, se zibó: y dicando palal á la sueti, que o plastañaba, penó: Aromali sangue penelo, que ni andré Israel he alachado fé tan bari.
Nígbà tí Jesu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ẹnu sì yà, ó sì yípadà sí ìjọ ènìyàn tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó wí pé, “Mo wí fún yín pé èmi kò rí irú ìgbàgbọ́ ńlá bí èyí nínú àwọn ènìyàn Israẹli.”
10 Y pur junos limbidiáron al quer sos habian sinado bichabados, alacháron sasto al lacró, sos habia sinado merdo.
Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ sì padà sí ilé, wọ́n bá ọmọ ọ̀dọ̀ náà tí ń ṣàìsàn, ara rẹ̀ ti dá.
11 Y anacó despues, que chalaba á yeque foros araquerado Naim: y desqueres discipules chalaban sat ó, y yeque bari plastañi de sueti.
Ní ọjọ́ kejì, ó lọ sí ìlú kan tí a ń pè ní Naini, àwọn púpọ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń bá a lọ àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn.
12 Y pur abilló sunparal de la bundal e foros, he acoi que sicobaban abrí á yeque mulo, chaboro colcoro de sun dai, sos sinaba piuli, y abillaba sat siró baribustri sueti e foros.
Bí ó sì ti súnmọ́ ẹnu ibodè ìlú náà, sì kíyèsi i, wọ́n ń gbé òkú ọkùnrin kan jáde, ọmọ kan ṣoṣo náà tí ìyá rẹ̀ bí, ó sì jẹ́ opó: ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ìlú náà sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
13 Yescotria que la dicó o Erañó, perelalo de canrea por siró, le penó: Na orobeles.
Nígbà tí Olúwa sì rí i, àánú rẹ̀ ṣe é, ó sì wí fún un pé, “Má sọkún mọ́.”
14 Y chaló sunparal, y pajabó á la jestarí e muló. Y junos sos lo lligueraban, se sustiláron. Y penó: Bédoro, á tucue penelo, costunatucue.
Ó sì wá, ó sì fi ọwọ́ tọ́ pósí náà: àwọn tí ń rù ú dúró jẹ́. Ó sì wí pé, “Ọ̀dọ́mọkùnrin, mo wí fún ọ, dìde!”
15 Y se bejeló ó sos habia sinado muló, y se chibó á chamuliar, y le diñó á sun dai.
Ẹni tí ó kú náà sì dìde jókòó, ó bẹ̀rẹ̀ sí i fọhùn. Ó sì fà á lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́.
16 Y tereláron os sares dal baro, y majarificaban á Debél, penando; Propheta baro se ha ardiñado andré amangue; y Debél ha abillado á sun sueti.
Ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn: wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, pé, “Wòlíì ńlá dìde nínú wa,” àti pé, “Ọlọ́run sì wá bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò!”
17 Y o chimusolano de ocona zibo voltisaró por sari Judéa, y por sari a pu.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo Judea, àti gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
18 Y penáron á Juan desqueres discipules sarias oconas buchias.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un.
19 Y Juan araqueró dui es discipules de ó, y os bichabó á Jesus, penando: ¿Sinelas tucue ó sos ha de abillar, ó ujaramos á aver?
Nígbà tí Johanu sì pe àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó rán wọn sọ́dọ̀ Olúwa, wí pé, “Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
20 Y sasta abillasen á ó oconas manuces, le penáron; Juan o Bautista ha bichabado amangue á tucue, y penela; ¿Sinelas tucue ó sos ha de abillar, ó ujaramos á aver.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé, “Johanu onítẹ̀bọmi rán wa sọ́dọ̀ rẹ, pé, ‘Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?’”
21 Y Jesus andré ocola matejo chiros chibó lacho á baribustrés de merdipénes, y de llagas, y de bengues chores, y diñó vista á butrés perpentas.
Ní wákàtí náà, ó sì ṣe ìmúláradá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn nínú àìsàn, àti ààrùn, àti ẹ̀mí búburú; ó sì fi ìríran fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn afọ́jú.
22 Y despues os rudeló, penando: Chalad, y penad á Juan, ma habeis junelado y dicado: Que os perpentas diquelan, os langues pirelan, os zarapiosos sinelan chibados lacho, os cajuques junelan, os mules ardiñelan, á os chorores sinela pucanado o Evangelio.
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ, ẹ ròyìn nǹkan tí ẹ̀yin rí, tí ẹ̀yin sì gbọ́ fún Johanu: àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a sọ àwọn adẹ́tẹ̀ di mímọ́, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, àti fún àwọn òtòṣì ni à ń wàásù ìyìnrere.
23 Y majaró sinela ó, sos na sinare escandalizado andré mangue.
Alábùkún fún sì ni ẹnikẹ́ni tí kò kọsẹ̀ lára mi.”
24 Y pur hubieron chalado os discipules de Juan, se chibó á penar á la sueti de Juan: ¿Qué chalasteis á dicar andré o desierto? ¿salchuyo chalabeado del bear?
Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ Johanu padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ìjọ ènìyàn ní ti Johanu pé, “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ sí ijù lọ wò? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mì?
25 ¿Tami qué chalasteis abrí á dicar? ¿Manu chito de coneles laches? Aromali junos sos chibelan coneles laches, y se parbarelan andré delicias, andré os querés es Crallises sinelan.
Ṣùgbọ́n kín ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ní aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́? Wò ó, àwọn tí á wọ̀ ní aṣọ ògo, tí wọ́n sì ń jayé, ń bẹ ní ààfin ọba!
26 Tami qué chalasteis abrí á dicar? Propheta? Aromali sangue penelo, y fetér que Propheta:
Ṣùgbọ́n kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Wòlíì? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ!
27 Ocona sinela, del que sinela randado: He acoi bichabelo minrio Manfariel anglal de tun chiche, sos julabará tun drun anglal de tucue.
Èyí yìí ni ẹni tí a ti kọ̀wé nítorí rẹ̀ pé: “‘Wò ó, èmi yóò rán oníṣẹ́ mi síwájú rẹ; ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
28 Presas menda penelo sangue, que andré os chindados de romias, na sinela fetér Propheta, que Juan o Bautista; tami o mendesquero andré o chim de Debél, sinela fetér que ó.
Mo wí fún yín nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí wòlíì tí ó pọ̀ ju Johanu Onítẹ̀bọmi lọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kéré jùlọ ní ìjọba Ọlọ́run, ó pọ̀jù ú lọ.”
29 Y sari a sueti, y os Publicanes, sos le juneláron, diñáron chimusolano á Debél, junos sos habian sinado muchobelados sal o bautismo de Juan.
(Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó gbọ́ àti àwọn agbowó òde, wọ́n dá Ọlọ́run láre, nítorí tí a fi ìtẹ̀bọmi Johanu tẹ̀ wọn bọ mi.
30 Tami os Phariseyes, y os Chandes de la Eschastra gireláron o consejo de Debél andré sí matejos, ocolas sos na habian sinado muchobelados por ó.
Ṣùgbọ́n àwọn Farisi àti àwọn amòfin kọ ète Ọlọ́run fún ara wọn, a kò bamitiisi wọn lọ́dọ̀ rẹ̀.)
31 Y penó o Erañó: Pues á coin penaré, que se semejan os manuces de ocona rati, y á coin se nichobelan?
Jesu sì wí pé, “Kí ni èmi ìbá fi àwọn ènìyàn ìran yìí wé? Kí ni wọ́n sì jọ?
32 Semejantes sinelan á os chabores, sos sinelan bejelados andré ó masquero chamuliando andré sí, y penando: A sangue hemos giyabelado sat pajandias, y na quelasteis: á sangue hemos endechado, y na orobasteis.
Wọ́n dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ó jókòó ní ibi ọjà, tí wọ́n sì ń kọ sí ara wọn, tí wọ́n sì ń wí pé, “‘Àwa fọn fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó, àwa sì ṣọ̀fọ̀ fún yín, ẹ̀yin kò sọkún!’
33 Presas abilló Juan o Bautista, sos na jamaba manro, ni piyaba mol, y penelais: Bengui terela.
Nítorí Johanu Onítẹ̀bọmi wá, kò jẹ àkàrà, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu ọtí wáìnì, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù?’
34 Abilló o Chaboro e manu, sos jamela, y piyela, y penelais: He acoi manu jamador, y matogaro, monro de Publicanes y chorés.
Ọmọ ènìyàn dé, ó ń jẹ, ó sì ń mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Wò ó, ọ̀jẹun, àti ọ̀mùtí, ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀!’
35 Tami a chaneleria ha sinado justificada por sares desqueres chabores.
Ṣùgbọ́n ọgbọ́n ni a dá láre nípasẹ̀ ọmọ rẹ.”
36 Y le mangaba yeque Phariséo, que chalase á jamar sat ó: y habiendo chalado andré o quer e Phariséo, se bejeló á la mensalle.
Farisi kan sì rọ̀ ọ́ kí ó wá bá òun jẹun, ó sì wọ ilé Farisi náà lọ ó sì jókòó láti jẹun.
37 Y yeque cadchi chumasconá, sos sinaba andré o foros, chanelando que sinaba á la mensalle andré o quer e Phariséo, lligueró yeque pigote de alabastro, perelalo de ampio lacho:
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà ní ìlú náà, ẹni tí i ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀, nígbà tí ó mọ̀ pé Jesu jókòó, ó ń jẹun ní ilé Farisi, ó mú ṣágo kékeré alabasita òróró ìkunra wá,
38 Y sinchitandose á desqueres pindrés palal de ó, se chibó á muchobelarle sat la pani de sus aquias os pindrés, y os enjugaba sat o bal de desquero jeró, y le chupendiaba os pindrés, y os ampiaba sat o ampio.
Ó sì dúró tì í lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀ lẹ́yìn, ó ń sọkún, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí i fi omijé wẹ̀ ẹ́ ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ nù ún nù, ó sì ń fi ẹnu kò ó ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi òróró kùn wọ́n.
39 Y pur ocono dicó o Phariséo, sos le terelaba convidado, penó andré sí matejo: Si ocona manu sinaba Propheta, chanelaria mistos ma, y coin sinela a cadchi, sos le pajabela; presas sinela chori.
Nígbà tí Farisi tí ó pè é sì rí i, ó wí nínú ara rẹ̀ pé, “Ọkùnrin yìí ìbá ṣe wòlíì, ìbá mọ ẹni àti irú ẹni tí obìnrin yìí jẹ́ tí ń fi ọwọ́ kàn an, nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni.”
40 Y Jesus le rudeló, penando: Simón, camelo penar á tucue yeque buchi. Y ó rudeló: Duquendio, pen.
Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “Simoni, Mo ní ohun kan sọ fún ọ.” Ó sì dáhùn pé, “Olùkọ́ máa wí.”
41 Dui debisaráron jayere á yeque manu: o yeque le debisaró pansch cientos calés, y o aver cincuenta.
“Ayánilówó kan wà tí ó ní ajigbèsè méjì: ọ̀kan jẹ ẹ́ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta owó idẹ, èkejì sì jẹ ẹ́ ní àádọ́ta.
42 Tami sasta na terelasen chichi de que plasararle, se los estomó á os dui. ¿Pues cual es dui le camela fetér?
Nígbà tí wọn kò sì ní ohun tí wọn ó san, ó dáríjì àwọn méjèèjì. Wí nínú àwọn méjèèjì, ta ni yóò fẹ́ ẹ jù?”
43 Rudeló Simón, y penó: Penchabelo, que ocola, á coin estomó butér. Y Jesus le penó: Mistos has penchabado.
Simoni dáhùn wí pé, “Mo ṣe bí ẹni tí ó dáríjì jù ni.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti dájọ́ náà dáradára.”
44 Y voltañandose acia a cadchi, penó á Simón: ¿Diquelas ocona cadchi? Menda me chalé andré tun quer, na diñaste mangue pani somia os pindrés: tami ocona sat a pani de desquerias aquias ha muchobelado minrés pindrés, y os ha enjugado sat desqueres bales.
Ó sì yípadà sí obìnrin náà, ó wí fún Simoni pé, “Wo obìnrin yìí? Èmi wọ ilé rẹ, ìwọ kò fi omi wẹ ẹsẹ̀ fún mi: ṣùgbọ́n, omijé rẹ̀ ni ó fi ń rọ̀jò sí mi lẹ́sẹ̀ irun orí ni ó fi ń nù wọ́n nù.
45 Na diñaste mangue chupendi: tami ocona, desde que abilló andré, na ha mucado de chupendarme os pindrés.
Ìwọ kò fi ìfẹnukonu fún mi: ṣùgbọ́n òun, nígbà tí mo ti wọ ilé, kò dẹ́kun ẹnu fífi kò mí lẹ́sẹ̀.
46 Na ampiaste minrio jeró sat ampio; tami ocona sat ampio lacho ha ampiado minres pindrés.
Ìwọ kò fi òróró pa mí lórí, ṣùgbọ́n òun ti fi òróró pa mí lẹ́sẹ̀.
47 Pre o matejo penelo; que estomados le sinelan os baribustres grecos de siró, presas cameló baribu. Tami al que mendesquero se estoma, mendesquero camela.
Ǹjẹ́ mo wí fún ọ, A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀ jì í: nítorí tí ó ní ìfẹ́ púpọ̀: ẹni tí a sì dárí díẹ̀ jì, òun náà ni ó ní ìfẹ́ díẹ̀.”
48 Y penó á siró: Estomados á tucue sinelan os grecos.
Ó sì wí fún un pé, “A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́!”
49 Y ocolas sos jamelaban oté, se chibáron á penar enré si: ¿Coin sinela ocona, sos aun os grecos estoma?
Àwọn tí ó bá a jókòó jẹun sì bẹ̀rẹ̀ sí í rò nínú ara wọn pé, “Ta ni èyí tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni pẹ̀lú?”
50 Y penó á la cadchi: Tun fé ha chibado tucue sasti: Chatucue andré paz.
Ó sì dáhùn wí fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ rẹ gbà ọ́ là, máa lọ ní àlàáfíà.”

< Lucas 7 >