< Lucas 3 >

1 Y andré a berji pansch-decima e imperio de Tiberio Cæsar, sinando Poncio Pilato Chino baro de Judea, y Herodes Tetrarchâ de Galiléa, y desquero plano Philipo Tetrarchâ de Ituréa, y e chim de Trachônite, y Lysanias Tetrarchâ de Abilina,
Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún ìjọba Tiberiu Kesari, nígbà tí Pọntiu Pilatu jẹ́ baálẹ̀ Judea, tí Herodu sì jẹ́ tetrarki Galili, Filipi arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ tetrarki Iturea àti ti Trakoniti, Lisania sì jẹ́ tetrarki Abilene,
2 Sinando Manclayes es erajais Annás y Caiphas, abilló a varda e Erañoró opré Juan, chaboro de Zacharias, andré o desierto.
tí Annasi òun Kaiafa ń ṣe olórí àwọn àlùfáà, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Johanu ọmọ Sekariah wá ní ijù.
3 Y abilló por saro o chim de Jordan garlando o muchobelar de penitencia somia mecos de grecos,
Ó sì wá sí gbogbo ilẹ̀ aginjù Jordani, ó ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀,
4 Sasta sinela randado andré o embéo de las vardas de Isaias Propheta: Gole de yeque garlando andré ó desierto: Aparejad o drun e Erañoró, Querelad bustarias as sendas de ó.
bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah pé, “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ mú ipa ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
5 Saro butron se perelará; y saro bur y plai se pejerá: y o torcido sinará enderezado: y os drunes fragosos allanados:
Gbogbo ọ̀gbun ni a yóò kún, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni a ó tẹ́ pẹẹrẹ. Wíwọ́ ni a ó ṣe ní títọ́, àti ọ̀nà gbọ́ngungbọ̀ngun ni a o sọ di dídán.
6 Y dicará sari maas a golipen de Debél.
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì rí ìgbàlà Ọlọ́run.’”
7 Y penó á os manuces, que abillaban somia que los muchobelase: ¿Rati de birbirechas, coin penó á sangue á najar de la ira que ha de abillar?
Nígbà náà ni ó wí fún ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn tí ó wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ìran paramọ́lẹ̀, ta ni ó kìlọ̀ fún un yín láti sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
8 Querelad pues mibao cabalico de penitencia, y na os chitelais penar: Terelamos por batu á Abraham. Porque sangue penelo, que astisarela Debél de oconas barendañías ardiñar chabores á Abraham.
Nítorí náà kí ẹ̀yin kí ó so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà, kí ẹ má sì ṣe sí í wí nínú ara yín pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Kí èmi kí ó wí fún un yín, Ọlọ́run lè gbé ọmọ dìde fún Abrahamu nínú òkúta wọ̀nyí.
9 Presas acana sinela chibada a tescharí á la raiz es carschtas, pues sari carschta, sos na diñele mibao lacho, sinará velada, y chibada andré a yacque.
Àti nísinsin yìí pẹ̀lú, a fi àáké lé gbòǹgbò igi náà, gbogbo igi tí kò bá so èso rere, a óò ge lulẹ̀, a sì wọ jù sínú iná.”
10 Y le puchababan os manuces, y penaban! ¿Pues qué querelaremos?
Àwọn ènìyàn sì ń bi í pé, “Kí ni kí àwa kí ó ṣe?”
11 Y rudelando les penaba: O manu sos terela duis coneles, díñele al manu sos na terela: y o sos terela que jamar, querele o matejo.
Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹni tí ó bá ní ẹ̀wù méjì, kí ó fi ọ̀kan fún ẹni tí kò ní; ẹni tí ó bá sì ní oúnjẹ, kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
12 Y abilláron tambien á ó os Publicanes, somia que os muchobelase, y le penáron: ¿Duquendio, qué querelaremos?
Àwọn agbowó òde sì tọ̀ ọ́ wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì bi í pé, “Olùkọ́, kí ni àwa ó ha ṣe?”
13 Y ó les penó: Na ustileis butér de ma os sinela penado.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe fi agbára gbà jù bí a ti rán yín lọ mọ́.”
14 Le puchababan tambien os jundunares, penando: ¿Y mu qué querelaremos? Y les penó: Na queraleis choro á cayque, ni le mareleis, y sineleis lacho sat jiré jayere.
Àwọn ọmọ-ogun sì béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Àti àwa, kí ni àwa ó ṣe?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe hùwà ipá sí ẹnikẹ́ni, kí ẹ má sì ṣe ka ẹ̀sùn èké sí ẹnikẹ́ni; kí òwò ọ̀yà yín tó yín.”
15 Y sasta os manuces creyesen, y os sares penchabasen andré desqueres carlochines, si por ventura Juan sinaba o Christo:
Bí àwọn ènìyàn sì ti ń retí, tí gbogbo wọn sì ń rò nínú ara wọn nítorí Johanu, bí òun ni Kristi tàbí òun kọ́;
16 Rudeló Juan, y penó á os sares: Menda aromali muchobelo sangue andré paní: Tami abillará avér butér silnó que menda, de coin na sinelo cabalico de despandar a correa de desqueres tirajais: ocola muchobelará sangue andré Peniche, y yaque:
Johanu dáhùn ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Lóòótọ́ ni èmi ń fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ẹni tí ó lágbára jù mí lọ ń bọ̀, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú, Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
17 De coin o bieldo sinela andré su baste; y alimpiará desquero era, y chibará ó gi andré su malabai, y la pus jachará sat yaque, que na se bedela.
Ẹni tí àtẹ rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, láti gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ mọ́ tó tó, kí ó sì kó alikama rẹ̀ sínú àká; ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
18 Y andiar anunciaba averias baribustrias buchias á la sueti andré sus exhortaciones.
Johanu lo oríṣìíríṣìí ọ̀rọ̀ púpọ̀ láti gba àwọn ènìyàn níyànjú àti láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
19 Tami Herodes ó Tetrarchâ; sinando reprehendido por ó á causa de Herodias romi de sun planó, y de sarias as buchias chorias que Herodes habia querdi,
Ṣùgbọ́n nígbà ti Johanu bú Herodu tetrarki, tí ó bá wí nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀, àti nítorí ohun búburú gbogbo tí Herodu tí ṣe,
20 Anadio á sares tambien ocona de querelar pandar a Juan andré la estaripel.
Ó fi èyí parí gbogbo rẹ̀ nígbà tí ó fi Johanu sínú túbú.
21 Y anacó, que sasta sari a sueti ustilase o muchobelar, tambien sinaba muchobelado Jesus; y sinando ó manguelando á Debél, se despandó o Tarpe:
Nígbà tí a ṣe ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamitiisi Jesu pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,
22 Y pejó ostely opre ó el Peniche andré trupo, sasta gobaró: y se juneló ocono gole del Tarpe: Tucue sinelas minrió Chaboro camelado; andré tucue menda me alendelo.
Ẹ̀mí Mímọ́ sì sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ ní àwọ̀ àdàbà, ohùn kan sì ti ọ̀run wá, tí ó wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ ọmọ mi; ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
23 Y o Jesus comenzaba a terelar sasta de sinebo berjis, chaboro y segun se penelaba, de Joseph, chaboro de Heli, chaboro de Mathat,
Jesu tìkára rẹ̀ ń tó bí ẹni ọgbọ̀n ọdún, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ (bí a ti fi pè) ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Eli,
24 Chaboro de Leví, chaboro de Melchi, chaboro de Janne, chaboro de Joseph,
tí í ṣe ọmọ Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi, tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Janai, tí í ṣe ọmọ Josẹfu,
25 Chaboro de Mathathias, chaboro de Amos, chaboro de Nahum, chaboro de Hesli, chaboro de Nagge,
tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Amosi, tí í ṣe ọmọ Naumu, tí í ṣe ọmọ Esili, tí í ṣe ọmọ Nagai,
26 Chaboro de Mahath, chaboro de Mathathias, chaboro de Semei, chaboro de Joseph, chaboro de Judá,
tí í ṣe ọmọ Maati, tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Ṣimei, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Joda,
27 Chaboro de Joanna, chaboro de Resa, chaboro de Zorobabél, chaboro de Salathiel, chaboro de Neri,
tí í ṣe ọmọ Joana, tí í ṣe ọmọ Resa, tí í ṣe ọmọ Serubbabeli, tí í ṣe ọmọ Ṣealitieli, tí í ṣe ọmọ Neri,
28 Chaboro de Melchi, chaboro de Addí, chaboro de Cosán, chaboro de Helmadan, chaboro de Her,
tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Adi, tí í ṣe ọmọ Kosamu, tí í ṣe ọmọ Elmadamu, tí í ṣe ọmọ Eri,
29 Chaboro de Jesus, chaboro de Eliezer, chaboro de Jorim, chaboro de Mathat, chaboro de Levi,
tí í ṣe ọmọ Joṣua, tí í ṣe ọmọ Elieseri, tí í ṣe ọmọ Jorimu, tí í ṣe Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi,
30 Chaboro de Simeón, chaboro de Júdas, chaboro de Joseph, chaboro de Jonás, chaboro de Eliakim,
tí í ṣe ọmọ Simeoni, tí í ṣe ọmọ Juda, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Jonamu, tí í ṣe ọmọ Eliakimu,
31 Chaboro de Melea, chaboro de Menna, chaboro de Mathatha, chaboro de Nathán, chaboro de David,
tí í ṣe ọmọ Melea, tí í ṣe ọmọ Menna, tí í ṣe ọmọ Mattata, tí í ṣe ọmọ Natani, tí í ṣe ọmọ Dafidi,
32 Chaboro de Jessé, chaboro de Obed, chaboro de Booz, chaboro de Salmon, chaboro de Naasson,
tí í ṣe ọmọ Jese, tí í ṣe ọmọ Obedi, tí í ṣe ọmọ Boasi, tí í ṣe ọmọ Salmoni, tí í ṣe ọmọ Nahiṣoni,
33 Chaboro de Aminadab, chaboro de Arám, chaboro de Esron, chaboro de Pharé, chaboro de Judas,
tí í ṣe ọmọ Amminadabu, tí í ṣe ọmọ Ramu, tí í ṣe ọmọ Hesroni, tí í ṣe ọmọ Peresi, tí í ṣe ọmọ Juda.
34 Chaboro de Jacob, chaboro de Isaac, chaboro de Abraham, chaboro de Thares, chaboro de Nachor,
Tí í ṣe ọmọ Jakọbu, tí í ṣe ọmọ Isaaki, tí í ṣe ọmọ Abrahamu, tí í ṣe ọmọ Tẹra, tí í ṣe ọmọ Nahori,
35 Chaboro de Sarug, chaboro de Regau, chaboro de Phaleg, chaboro de Heber, chaboro de Salé,
tí í ṣe ọmọ Serugu, tí í ṣe ọmọ Reu, tí í ṣe ọmọ Pelegi, tí í ṣe ọmọ Eberi, tí í ṣe ọmọ Ṣela.
36 Chaboro de Cainán, chaboro de Arphaxad, chaboro de Sem, chaboro de Noé, chaboro de Lamech,
Tí í ṣe ọmọ Kainani, tí í ṣe ọmọ Arfaksadi, tí í ṣe ọmọ Ṣemu, tí í ṣe ọmọ Noa, tí í ṣe ọmọ Lameki,
37 Chaboro de Mathusalé, chaboro de Henoch, chaboro de Jared, chaboro de Malaleel, chaboro de Cainan,
tí í ṣe ọmọ Metusela, tí í ṣe ọmọ Enoku, tí í ṣe ọmọ Jaredi, tí í ṣe ọmọ Mahalaleli, tí í ṣe ọmọ Kainani.
38 Chaboro de Henos, chaboro de Seth, chaboro de Adám, sos fué chaboro de Un-debél.
Tí í ṣe ọmọ Enosi, tí í ṣe ọmọ Seti, tí í ṣe ọmọ Adamu, tí í ṣe ọmọ Ọlọ́run.

< Lucas 3 >