< Lucas 2 >

1 André ocolas chibeses anacó, que chaló abrí yeque edicto de Cæsar Augusto, somia que sari a sueti sinara jinada.
Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àṣẹ ti ọ̀dọ̀ Kesari Augustu jáde wá pé, kí a kọ orúkọ gbogbo ayé sínú ìwé.
2 Ocola brotoboro jinamiento sinaba querdi por Cyrino, Chino-baro de Syria.
(Èyí ni ìkọ sínú ìwé èkínní tí a ṣe nígbà tí Kirene fi jẹ baálẹ̀ Siria.)
3 Y chalaban os sares á libanarse os naos cata yeque á desquero foros.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì lọ láti kọ orúkọ wọn sínú ìwé, olúkúlùkù sí ìlú ara rẹ̀.
4 Y ardiñó tambien Joseph del foros de Nazareth, á Judea, al foros de David, sos se heta Bethlehém: presas sinaba del quer y de la rati de David,
Josẹfu pẹ̀lú sì gòkè láti Nasareti ni Galili, sí ìlú Dafidi ní Judea, tí à ń pè ní Bẹtilẹhẹmu; nítorí ti ìran àti ìdílé Dafidi ní í ṣe,
5 Somia libanarse o nao sat desqueri romi Maria, sos sinaba cambri.
láti kọ orúkọ rẹ̀, pẹ̀lú Maria aya rẹ̀ àfẹ́sọ́nà, tí oyún rẹ̀ ti tó bí.
6 Y sinando oté, anacó, que se pereláron os chibeses andré que terelaba de chindar.
Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n wà níbẹ̀, ọjọ́ rẹ̀ pé tí òun yóò bí.
7 Y minchabó a desquero Chaboro broto-chindado, y lo chibó andré diclés, y lo chitó andré yeque olibar: presas na sinaba lugar por junos andré a mesuna.
Ó sì bí àkọ́bí rẹ̀ ọmọkùnrin, ó sì fi ọ̀já wé e, ó sì tẹ́ ẹ sínú ibùjẹ ẹran; nítorí tí ààyè kò sí fún wọn nínú ilé èrò.
8 Y sinaba yeques durotunes andré ocola comarca, sos sinaban velando, y nacando as ocanas e rachí opré desquerias brajias.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn ń bẹ tí wọ́n ń gbé ní ìlú náà, wọ́n ń ṣọ́ agbo àgùntàn wọn ní òru ní pápá tí wọ́n ń gbé.
9 Y he acoi se childó sunparal á junos yeque Manfariel e Erañoró, y a dut de Debél os cercó de yacque, y tereláron baro dal.
Angẹli Olúwa sì yọ sí wọn, ògo Olúwa sì ràn yí wọn ká, ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi.
10 Y les penó o Manfariel: nacangueleis: presas he acoi anuncio á sangue gosuncho baro, sos sinará á sari a sueti.
Angẹli náà sì wí fún wọn pé, “Má bẹ̀rù: sá wò ó, mo mú ìyìnrere ayọ̀ ńlá fún yín wá, tí yóò ṣe ti ènìyàn gbogbo.
11 Que sejonia sinela chindado a sangue o Salvador, sos sinela o Christo Erañó, andré o foros de David.
Nítorí a ti bí Olùgbàlà fún yín lónìí ní ìlú Dafidi, tí í ṣe Kristi Olúwa.
12 Y ocona sinará á sangue o simache: Alachareis o Chaboro chibado andré dicles; y chitado andré yeque olibar.
Èyí ni yóò sì ṣe àmì fún yín; ẹ̀yin yóò rí ọmọ ọwọ́ tí a fi ọ̀já wé, ó dùbúlẹ̀ ní ibùjẹ ẹran.”
13 Y yescotria se mecó dicar sat o Manfariel butrés manuces es jundunares e Tarpe, sos majarificaban a Debél, y penaban:
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun ọ̀run sì darapọ̀ mọ́ angẹli náà ní òjijì, wọ́n ń yin Ọlọ́run, wí pé,
14 Chimusolano á Debél andré o Tárpe, y andré a phu paz á os sares de lachi suncái.
“Ògo ni fún Ọlọ́run lókè ọ̀run, àti ní ayé àlàáfíà, ìfẹ́ inú rere sí ènìyàn.”
15 Y anacó, que yescotria que os Manfarieles chaláron de junos al Tarpe, os durotunés penaban os yeques a os averes: Chalemos disde Bethlehém, y diquelemos ma ha anacado, ma o Erañó, ha diado á amangue.
Ó sì ṣe, nígbà tí àwọn angẹli náà padà kúrò lọ́dọ̀ wọn lọ sí ọ̀run, àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà bá ara wọn sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ tààrà sí Bẹtilẹhẹmu, kí á lè rí ohun tí ó ṣẹ̀, tí Olúwa fihàn fún wa.”
16 Y chaláron singó, y alacháron á Maria, y á Joseph, y al chaboro chitado andré o olibar.
Wọ́n sì wá lọ́gán, wọ́n sì rí Maria àti Josẹfu, àti ọmọ ọwọ́ náà, ó dùbúlẹ̀ nínú ibùjẹ ẹran.
17 Y pur ocono dicáron, jabilláron ma se les habia penado acerca de ocola Chaboró.
Nígbà tí wọ́n sì ti rí i, wọ́n sọ ohun tí a ti wí fún wọn nípa ti ọmọ yìí.
18 Y os sares sos lo juneláron, se zibáron: y tambien de ma os durotunés les habian penado.
Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ sí nǹkan wọ̀nyí tí a ti wí fún wọn láti ọ̀dọ̀ àwọn olùṣọ́-àgùntàn wá.
19 Tami Maria aracateaba sarias ocolas buchias, estongerandolas andré desquero carló.
Ṣùgbọ́n Maria pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́, ó ń rò wọ́n nínú ọkàn rẹ̀.
20 Y se limbidiáron os durotunés chimusolanificando y majarificando á Debél por sarias as buchias, ma habian junelado y dicado, andiar sasta les habia sinado penado.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn sì padà lọ, wọ́n ń fi ògo fún Ọlọ́run, wọ́n sì yìn ín, nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti gbọ́ àti tí wọ́n ti rí, bí a ti wí i fún wọn.
21 Y despues que sináron nacados os otor chibeses somia chinar o postin e quilen al Chaboro, araqueráron desquero nao Jesus, sasta le habia araquerado o Manfariel, gres que sinaba concebido andré o trupo.
Nígbà tí ọjọ́ mẹ́jọ sì pé láti kọ ọmọ náà nílà, wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu, bí a ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀ láti ọ̀dọ̀ angẹli náà wá kí á tó lóyún rẹ̀.
22 Y pur sináron nacados os chibeses e purificacion de Maria, segun la eschastra de Moyses, lo lligueráron á Jerusalém somia presentarlo al Erañoró,
Nígbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nù Maria sì pé gẹ́gẹ́ bí òfin Mose, Josẹfu àti Maria gbé Jesu wá sí Jerusalẹmu láti fi í fún Olúwa
23 Sasta sinela randado andré la Eschastra e Erañoró: que o saro manu sos despandase beo, sinará majarificado al Erañó.
(bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Olúwa pé, “Gbogbo ọmọ ọkùnrin tí ó ṣe àkọ́bí, òun ni a ó pè ní mímọ́ fún Olúwa”),
24 Y somia diñar a ofrenda sasta sinela penado andré a Eschastra e Erañoró, yeque par de gobareyes, o dui custañias.
àti láti rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí nínú òfin Olúwa: “Àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì.”
25 Y sinaba al chiros andré Jerusalém gachó sos se hetó Simeón, y ocola manu lacho y daraño de Debél, ujarando a consolacion de Israel, y o Peniche sinaba andré ó.
Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan wà ní Jerusalẹmu, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Simeoni; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́ àti olùfọkànsìn, ó ń retí ìtùnú Israẹli, Ẹ̀mí mímọ́ sì bà lé e.
26 Y chanelaba del Peniche, que ó na dicaria meripen, bi dicar grés al Christo e Erañoró.
A sì ti fihàn án láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ náà wá pé, òun kì yóò rí ikú, kí ó tó rí Kristi Olúwa.
27 Y abilló por ochi á la cangri, y lanelando os batuces al Chaboro Jesus, somia querelar segun la beda e Eschastra sat ó:
Ó sì ti ipa Ẹ̀mí wá sínú tẹmpili. Nígbà tí àwọn òbí rẹ̀ sì gbé Jesu wá, láti ṣe fún un bí ìṣe òfin.
28 Entonces lo ustiló andré sus murcias, y majarificó á Debél, y penó:
Nígbà náà ni Simeoni gbé e ní apá rẹ̀, ó fi ìbùkún fún Ọlọ́run, ó ní:
29 Acana, Erañó, mequeles á tun lacró chalar en paz, segun tiri varda:
“Olúwa Olódùmarè, nígbà yìí ni ó tó jọ̀wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ lọ́wọ́ lọ, ní àlàáfíà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
30 Presas han dicado minrias aquias tun golipen,
Nítorí tí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ ná,
31 Sos has aparejado antela chiché de sari la sueti;
tí ìwọ ti pèsè sílẹ̀ níwájú ènìyàn gbogbo;
32 Dut somia sinar revelada á os Busnés, y somia chimusolano de Israel tiri sueti.
ìmọ́lẹ̀ láti mọ́ sí àwọn aláìkọlà, àti ògo Israẹli ènìyàn rẹ̀.”
33 Y desquero batu y dai sinaban maravillados de ocolas buchías que se penelaban de ó.
Ẹnu sì ya Josẹfu àti ìyá rẹ̀ sí nǹkan tí a ń sọ sí i wọ̀nyí.
34 Y os majarificó Simeón, y penó á Maria desqueri dai: He acoi que ocona Chaboro sinela sinchitó somia querelar perar, y somia ardiñar á baribustres andré Israel; y somia simáche á os sares sos contrapenarán:
Simeoni sì súre fún wọn, ó sì wí fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “Kíyèsi i, a gbé ọmọ yìí kalẹ̀ fún ìṣubú àti ìdìde ọ̀pọ̀ ènìyàn ní Israẹli; àti fún àmì tí a ń sọ̀rọ̀-òdì sí;
35 Y un estuche velará tiro bucos de tun mateja, somia que sinelen chanelados os pensamientos de sares carlochines
(idà yóò sì gún ìwọ náà ní ọkàn pẹ̀lú) kí á lè fi ìrònú ọ̀pọ̀ ọkàn hàn.”
36 Y sinaba yeque chuan jañí, araquerada Ana, dugida de Phanuel, e tribu de Aser: ocona ya terelaba butrés chibeses, y habia socabado eñia berjis sat desquero rom desde su pachi.
Ẹnìkan sì ń bẹ, Anna wòlíì, ọmọbìnrin Penueli, nínú ẹ̀yà Aṣeri: ọjọ́ ogbó rẹ̀ pọ̀, ó ti bá ọkọ gbé ní ọdún méje láti ìgbà wúńdíá rẹ̀ wá;
37 Y siró sinaba piulí, sasta de otorenta y star berjis; y na chalaba abrí de la cangri, sirviendo chibes y rachí andré ayunos y ocanagimias.
Ó sì ṣe opó títí ó fi di ẹni ọdún mẹ́rìnlélọ́gọ́rin, ẹni tí kò kúrò ní tẹmpili, ṣùgbọ́n ó ń fi àwẹ̀ àti àdúrà sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru.
38 Y sasta siró bigorease andré a mateja ocana, majarificaba al Eraño: y penaba de ó á os sares sos ujaraban la mestepé de Israel.
Ó sì wólẹ̀ ní àkókò náà, ó sì dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pẹ̀lú, ó sì sọ̀rọ̀ rẹ̀ fún gbogbo àwọn tí ó ń retí ìdáǹdè Jerusalẹmu.
39 Y pur tereláron querdi o saro, conforme a lá Eschastra e Erañoró, se limbidiáron a Galiléa á desquero foros de Nazareth.
Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe nǹkan gbogbo tán gẹ́gẹ́ bí òfin Olúwa, wọ́n padà lọ sí Galili, sí Nasareti ìlú wọn.
40 Y o chaboro se queró baro y silno, sinando perelalo de chanelería, y a gracia de Debél sinaba andré ó.
Ọmọ náà sì ń dàgbà, ó sì ń lágbára, ó sì kún fún ọgbọ́n: oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sì ń bẹ lára rẹ̀.
41 Y desqueres batuces chaláron sarias as berjis á Jerusalém andré o chibes de la Ciria.
Àwọn òbí rẹ̀ a sì máa lọ sí Jerusalẹmu ní ọdọọdún sí àjọ ìrékọjá.
42 Y pur tereló duideque berjis, ardiñaron á Jerusalém, segun a beda e chibes baro.
Nígbà tí ó sì di ọmọ ọdún méjìlá, wọ́n gòkè lọ sí Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ìṣe àjọ náà.
43 Y acabados os chibeses, pur se limbidiaban, se quedisaró o chaboro Jesus andré Jerusalém, bi que desqueres batuces lo chanelasen.
Nígbà tí ọjọ́ wọn sì pé bí wọ́n ti ń padà bọ̀, ọmọ náà, Jesu dúró lẹ́yìn ní Jerusalẹmu; Josẹfu àti ìyá rẹ̀ kò mọ̀.
44 Y penchabando que sinaba sat os averes de la plastañí, chaláron drun de yeque chibes, y le orotáron enré os parientes, y os monres.
Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe bí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ èrò, wọ́n rin ìrìn ọjọ́ kan; wọ́n wá a kiri nínú àwọn ará àti àwọn ojúlùmọ̀ wọn.
45 Y pur na le rachelasen, se limbidiáron á Jerusalém, orotándole.
Nígbà tí wọn kò sì rí i, wọ́n padà sí Jerusalẹmu, wọ́n ń wá a kiri.
46 Y anacó que trin chibeses despues le alacháron andré á cangrí, bestelando en medio es Chandés, junandolos, y puchabandolos.
Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta wọ́n rí i nínú tẹmpili ó jókòó ní àárín àwọn olùkọ́ni, ó ń gbọ́ tiwọn, ó sì ń bi wọ́n léèrè.
47 Y os sares sos le junelaban, se pasmaban, de desqueri chaneleria y de las respuestas de ó.
Ẹnu sì ya gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún òye àti ìdáhùn rẹ̀.
48 Y pur le dicáron, se zibáron, y le penó desqueri dai: chaboro presas has querdi andiar sat amangue? dicá sasta tun batu y menda emposunó te orotabamos,
Nígbà tí wọ́n sì rí i, háà ṣe wọ́n, ìyá rẹ̀ sì bi í pé, “Ọmọ, èéṣe tí ìwọ fi ṣe wá bẹ́ẹ̀? Sá wò ó, baba rẹ̀ àti èmi ti ń fi ìbànújẹ́ wá ọ kiri.”
49 Y les rudeló: ¿Para qué orotabais mangue? ¿Na chanelabais, que me jomte sinar andré as buchias que sinelan de minrio Dadá?
Ó sì dáhùn wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá mi kiri? Ẹ̀yin kò mọ̀ pé èmi kò lè ṣàìmá wà níbi iṣẹ́ Baba mi?”
50 Tami junos na jabilláron a varda, que les penó.
Ọ̀rọ̀ tí o sọ kò sì yé wọn.
51 Y se guilló ostely sat junos, y abilló á Nasareth: y sinaba sugeto á junos. Y sun dai aracateaba sarias ocolas buchias andré su carló.
Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí Nasareti, sì fi ara balẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ pa gbogbo nǹkan wọ̀nyí mọ́ nínú ọkàn rẹ̀.
52 Y Jesus se queró baro andré chaneleria, y andré berjis, y andré furuné anglal de Debél y es manuces.
Jesu sì ń pọ̀ ní ọgbọ́n, sì ń dàgbà, ó sì wà ní ojúrere ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́run àti ènìyàn.

< Lucas 2 >