< Lucas 18 >

1 Y les penaba tambien ocona parabola: que jomte manguelar gayere, y na desfalecer,
Ó sì pa òwe kan fún wọn láti fi yé wọn pe, ó yẹ kí a máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí a má sì ṣàárẹ̀.
2 Penando: Sinaba yeque Barander andré foros, sos na darañaba á Un-debél, ni querelaba bajin á manu yeque;
Wí pé, “Onídàájọ́ kan wà ní ìlú kan, tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn.
3 Y sinaba andré o matejo foros piuli, sos abillaba á ó y le penaba: Querelame justicia de minrio daschmanu.
Opó kan sì wà ní ìlú náà, ó sì ń tọ̀ ọ́ wá, wí pé, ‘Gbẹ̀san mi lára ọ̀tá mi!’
4 Y ó pre baribu chiros na camelaba. Tami despues de ocono penó andré sí: Aunque ni darañelo á Debél, ni á manu querelo bajin;
“Lákọ̀ọ́kọ́ kò dá a lóhùn, ṣùgbọ́n níkẹyìn ó wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Bí èmi kò tilẹ̀ bẹ̀rù Ọlọ́run, tí èmi kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn,
5 Todavia, presas ocona piuli sinela importuna á mangue, le querelaré justicia, que na abillele tantas begais, que al fin mangue trajatela.
Ṣùgbọ́n nítorí tí opó yìí ń yọ mí lẹ́nu, èmi ó gbẹ̀san rẹ̀, kí ó má ba à fi wíwá rẹ̀ nígbàkígbà dá mi lágara.’”
6 Y penó o Erañó: Junelad ma penela o Barander choro.
Olúwa sì wí pé, “Ẹ gbọ́ bí aláìṣòótọ́ onídàájọ́ ti wí!
7 ¿Pues Un-debél na querelará bajin de desqueres chabores, sos araquerelan á ó á gole chibes y rachi, y terelará orpachirima andré junos?
Ọlọ́run kì yóò ha sì gbẹ̀san àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, tí ń fi ọ̀sán àti òru kígbe pè é, tí ó sì mú sùúrù fún wọn?
8 Sangue penelo, que sigo os listrabará. Tami pur abillará o chaboro e manu, ¿penchabelais que alachará fé andré a sueti?
Mo wí fún yín, yóò gbẹ̀san wọn kánkán! Ṣùgbọ́n nígbà tí Ọmọ Ènìyàn bá dé yóò ha rí ìgbàgbọ́ ní ayé bí?”
9 Y penó tambien ocona parabola á yeques, sos pachibelaban á sí matejos, sasta si sinaban laches, y despreciaban á os averes:
Ó sì pa òwe yìí fún àwọn kan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ara wọn pé, àwọn ni olódodo, tí wọ́n sì ń gan àwọn ẹlòmíràn,
10 Dui manuces ardiñeláron á la cangri á manguelar á Un-debél: o yeque Phariséo y o aver Publicano.
pé, “Àwọn ọkùnrin méjì gòkè lọ sí tẹmpili láti gbàdúrà, ọ̀kan jẹ́ Farisi, èkejì sì jẹ́ agbowó òde.
11 O Phariséo sinando en pindré, manguelaba andré sun suncai de ocona beda: Un-debél, chimusolano te díñelo, presas na sinelo sasta os averes manuces, randes, chores, pirandes; andiar sasta sinela ocona Publicano.
Èyí Farisi dìde, ó sì ń gbàdúrà nínú ara rẹ̀ báyìí pé, ‘Ọlọ́run mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí èmi kò rí bí àwọn ará ìyókù, àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà, aláìṣòótọ́, panṣágà, tàbí bí agbowó òde yìí.
12 Ayunisarelo dui begais sari semana: diñelo diezmos de o saro que terelo.
Èmi ń gbààwẹ̀ lẹ́ẹ̀méjì ní ọ̀sẹ̀, mo ń san ìdámẹ́wàá ohun gbogbo tí mo ní.’
13 Tami o Publicano, sinando muy dur, darañaba aun costunar as aquias al Tarpe: sino que curaba sun chepo, penando: Un-debél, terela canrea de mangue choro!
“Ṣùgbọ́n agbowó òde dúró lókèèrè, kò tilẹ̀ jẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run, ṣùgbọ́n ó lu ara rẹ̀ ní oókan àyà, ó wí pé, ‘Ọlọ́run ṣàánú fún mi, èmi ẹlẹ́ṣẹ̀!’
14 Sangue penelo, que ocono, y ocola nanai, chaló justificado á sun quer: presas saro manu, sos se ardiñela, sinará bucharado ostely: y ó sos se chibele ostely, sinará ardiñelado.
“Mo wí fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀ ní ìdáláre ju èkejì lọ: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, òun ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹni tí ó bá sì rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ òun ni a ó gbéga.”
15 Y le lanelaban tambien chabores, somia que os pajabase. Y pur lo dicáron os discipules, os chingaraban.
Wọ́n sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn; ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí i, wọ́n ń bá wọn wí.
16 Tami Jesus os araqueró, y penó: Mequelad, que abillelen á mangue os chabores, y na os impidais; presas de oconas sinela o chim de Debél.
Ṣùgbọ́n Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọ kékeré wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má sì ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí tí irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
17 Aromali sangue penelo, que ó sos na ustilase o chim de Debél, sasta chaboro, na chalará andré ó.
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gbà ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò wọ inú rẹ̀ bí ó ti wù kí ó rí.”
18 Y le puchabó yeque tintin baro, penando: Duquendio lacho, ¿qué querelaré somia alachar a chipen que na marela? (aiōnios g166)
Ìjòyè kan sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, wí pé, “Olùkọ́ rere, kín ni èmi ó ṣe tí èmi ó fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
19 Y Jesus le penó: ¿Por qué araquerelas mangue lacho? Cayque sinela lacho, sino Un-debél colcoro.
Jesu wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí bí kò ṣe ẹnìkan, èyí sì ni Ọlọ́run.
20 Chanelas os Mandamientos: Na marelarás: Na pirabarás: Na randelarás: Na penelarás jujana: Pachibela á tiro batu, y á tiri dai?
Ìwọ mọ̀ àwọn òfin: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jẹ́rìí èké, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
21 O penó: Saro ocono he querdi desde que sinaba chinoro.
Ó sì wí pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti pamọ́ láti ìgbà èwe mi wá.”
22 Pur juneló Jesus ocono, le penó: Aun á tucue faltisarela yeque buchi: binela saro que terelas, y dinlo á os chorores, y terelarás manchin andré o Tarpe: y abillel, y plastañamangue.
Nígbà tí Jesu sì gbọ́ èyí, ó wí fún un pé, “Ohun kan ni ó kù fún ọ síbẹ̀: lọ ta ohun gbogbo tí o ní, kí o sì pín in fún àwọn tálákà, ìwọ ó sì ní ìṣúra ní ọ̀run: sì wá, kí o máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
23 Pur ó juneló ocono, se chito charabaro: presas sinaba baribu balbalo.
Nígbà tí ó sì gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, nítorí tí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
24 Y Jesus le penó, pur le dicó charabaro: ¡Quan dificultosamente chalarán andré o chim de Debél junos sos terelan jayere!
Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!
25 Presas buchi butér facil sinela nacar brote pre la aqui de yeque jutia, que chalar manu balbalo andré o chim de Debél.
Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
26 Y penáron junos sos juneláron ocolo: ¿Pues coin astisarela salvarse?
Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
27 Les penó: Ma n’astis para os manuces, astis para Un-debél.
Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
28 Y penó Pedro: Mistos diquelas, que mu terelamos mequelado sarias buchias, y terelamos plastañado tucue.
Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
29 O les penó: Aromali sangue penelo, que cayque sinela, sos terele mequelado quer, ó batuces, ó planes, ó romi, ó chabores pre o chim de Debél,
Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run,
30 Sos na terele de alachar baribu butér andré ocona chiros; y andré o chim que abillele a chipen que na marela. (aiōn g165, aiōnios g166)
tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
31 Y ustiló Jesus aparte á os duideque: y os penó: Diquelad, chalamos á Jerusalém, y sinarán querdas sarias as buchias, que randáron os Prophetas del Chaboro e manu.
Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
32 Presas sinará entreguisarado á os Busnés, y sinará caquerado, y curado, y chotiado.
Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára.
33 Y despues que le curaren, le nicabarán a chipen, y ostinará al trincho chibes.
Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
34 Tami junos na jabilláron chichi de ocono: y ocona varda sinaba pandada á junos; y na jabillaban ma les penaba.
Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn, ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
35 Y anacó, que bigoreando sunparal á Jericho, sinaba yeque perpenta bestelado aligatas del drun, mangando limosna.
Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe.
36 Y pur juneló a chumas e sueti sos nacaba puchabó, qué sinaba ocono.
Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí.
37 Y le penáron, que nacaba Jesus Nazareno.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
38 Y penó á gole gole: Jesus, Chaboro de David, terela canrea de mangue.
Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
39 Y junos sos chalaban anglal le chingaraban, somia que mequelase. Tami ó garlaba baribu butér: Chaboro de David, terela canrea de mangue:
Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
40 Y Jesus parándose, penó que se le lanelasen. Y pur sinaba sunparal, le puchabó,
Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í
41 Penando: ¿Qué camelas que te querele? Y ó rudeló: Erañó, que diquele.
wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?” Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
42 Y Jesus le penó: Diquela, tun fé te ha chibado lacho.
Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
43 Y yescotria dicó, y le plastañaba chimusolanificando á Debél. Y pur dicó ocono sari a sueti, dinó loor á Debél.
Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.

< Lucas 18 >