< Lucas 17 >

1 Y penó á desqueres discipules: N’astis, que na abillelen escandales: ¡Tami ysna de ocola, por coin abillelén!
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
2 Fetér le sinaria, que le chibasen al querlo bar de asia y le bucharasen andré o moros, que querelar escandalo á yeque de oconas chinores.
Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
3 Diquelad por sangue: si querelare grecos tiro plal contra tucue, corrigele: y si querelare penitencia, ertinale.
Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
4 Y si querelare grecos contra tucue efta begais al chibes, y efta begais al chibes se limbidiare á tucue, penando: He querdi choro, ertinale.
Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
5 Y penáron os Apostoles al Erañó: Din amangue fé butér.
Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
6 Y penó o Érañó: Si terelareis fé, sasta yeque grano de mostaza, y penelareis á ocona moral: Despandate de raiz, y chibelate oté andré o moros: lo querelará.
Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
7 ¿Y coin de sangue terelando yeque lacró, sos randiñela, ó garabela as brajias, pur limbidiela del bur, le penela: Chatucue yescotria, y bestelate á la mensalle?
“Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
8 Y na le penela gres: Chitelame de jamar, y chitelate á servirme, o chiros que jamelo y piyelo; que despues jamarás y piyarás?
Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
9 ¿Pre baji se debisarelan garapatias á ocola lacró presas ocona querela ma le penó?
Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
10 Penchabelo que nanai. Andiar tambien sangue, pur querelareis sarias as buchias que á sangue sinelan penadas, penad: Lacrés sinamos inutiles: Ma debisaramos querelar, querelemos.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
11 Y anacó que chalando ó á Jerusalém, nacó por medio de Samaria, y de Galiléa.
Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
12 Y chalando andré yeque gau, chaláron abrí á ó deque manuces zarapiosos, sos se paráron de dur.
Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
13 Y diñaron goles, penando: Jesus duquendio, terela canrea de amangue.
wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
14 O pur dicó junos, penó: Chalad, somia diquelen sangue os erajais. Y anacó, que o chiros que chalaban, sináron chibados lacho.
Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
15 Y yeque de junos, pur dicó que habia sinado chibado lacho, limbidió diñando chimusolano á Debél á goles bares.
Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
16 Y se bucharó en chiquen, á os pindrés de Jesus, diñando garapatias: y ocona sinaba Samaritano.
Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
17 Y rudeló Jesus, y penó: ¿Pre baji na sinelan deque junos sos sináron chibados lacho? ¿Y os nu averes duque sinelan?
Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
18 ¿Na sinaba yeque sos limbidiase, y diñase chimusolano á Debél, sino ocana gringó?
A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
19 Y le penó: Costunatucue, chatucue, que tiri fé te ha chibado lacho.
Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
20 Y puchabandole os Phariseyes: ¿Pur abillará o chim de Debél? les rudeló, y penó: O chim de Debél na abillará sat simache de abrí;
Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
21 Ni penelarán: helo acoi, o helo oté: presas o chim de Debél sinela andré de sangue.
Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
22 Y penó á desqueres discipules: Abillarán chibeses, pur camelareis dicar yeque chibes e Chaboro e Manu, y na lo dicareis.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
23 Y sangue penarán: Diqueladle acoi, y diqueladle oté. Na cameleis chalar, ni le plastañeis.
Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
24 Presas sasta o maluno, sos diñelando dut andré a region ostely e Charos, voltisarela desde la yeque disde la aver aricata; andiar tambien sinará o Chaboro e manu andré desquero chibes.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
25 Tami jomte brotoboro que ó padezca baribu, y que sinele reprobado de ocona sueti.
Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
26 Y sasta sinaba andré os chibeses de Noé, andiar tambien sinará andré os chibeses e Chaboro e manu.
“Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
27 Jamaban, y piyaban: os manuces ustilaban romias, y as cadchias romes disde o chibes pur Noé chaló andré á Jestari; y abilló a pani bari, y mulabó á sares.
Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
28 Andiarmatejo sasta sinaba andré os chibeses de Lot; jamaban, y piyaban; quinaban, y binaban; chitaban carschtas, y querelaban querés.
“Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
29 Y o chibes, que chaló Lot abrí de Sodoma, peró yaque y azufre de o Charos, y os marabó á sares.
ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
30 Andiar sinará o chibes, pur se mequelará dicar o Chaboro e manu.
“Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
31 André ocola ocana o sos sinare opré o tejado, y terelare desqueres coneles andré o quer, na chale ostely á ustilarlos, y ó sos sinare andré o ortalame, andiar matejo na limbidiele palal.
Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
32 Terelad en fácho a romi de Lot.
Ẹ rántí aya Lọti.
33 O saro sos camelare salvar sun chipen, la najabará; y ó sos la najabará, la alachará.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
34 Sangue penelo, que andré ocola rachi dui sinarán andré yeque cheripen, yéque sinará ustilado, y o aver mequelado.
Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
35 Dui cadchias sinarán nacicando andré a asia catanias; yeque sinará ustilada, a aver mequelada: dui andré l’ortalame; yeque sinará ustilado, y o aver mequelado.
Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
36 Rudeláron, y le penáron: ¿Anduque Erañó?
37 Y ó les penó: Duque sináre o trupos, oté tambien se catanaran as aguilas.
Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”

< Lucas 17 >