< Лука 17 >

1 И рече на учениците Си: Не е възможно да не дойдат съблазните; но горко на онзи, чрез когото дохождат!
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
2 По-добре би било за него да се окачи един голям воденичен камък на врата му и да бъде хвърлен в морето, а не да съблазни един от тия малките.
Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
3 Внимавайте на себе си. Ако прегреши брат ти, смъмри го; и ако се покае прости му.
Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
4 И седем пъти на ден ако ти сгреши, и седем пъти се обърне към тебе и каже: Покайвам се, прощавай му.
Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
5 И апостолите рекоха на Господа: Придай ни вяра.
Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
6 А Господ рече: Ако имате вяра колкото синапово зърно, казали бихте на тая черница: Изкорени се и насади се в морето, и тя би ви послушала.
Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
7 А кой от вас, ако има слуга да му оре или да му пасе, ще му рече веднага, щом си дойде от нива: Влез да ядеш?
“Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
8 Напротив, не ще ли му рече: Приготви нещо да вечерям, стегни се та ми пошетай, докато ям и пия, и подир това ти ще ядеш и пиеш?
Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
9 Нима ще благодари на слугата за дето е извършил каквото е било заповядано? [Не вярвам].
Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
10 Също така и вие, когато извършите все що ви е заповядано, казвайте: Ние сме безполезни слуги; извършихме само това, което бяхме длъжни да извършим.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
11 И в пътуването Си към Ерусалим Той минаваше границата между Самария и Галилея.
Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
12 И като влизаше в едно село, срещнаха Го десетина прокажени, които, като се спряха отдалеч,
Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
13 извикаха със силен глас, казвайки: Исусе наставниче, смили се за нас!
wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
14 И като ги видя, рече им: Идете покажете се на свещениците. И като отиваха, очистиха се.
Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
15 И един от тях, като видя, че изцеля, върна се и със силен глас славеше Бога,
Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
16 и падна на лице при нозете на Исуса и му благодареше. И той бе самарянин.
Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
17 А Исус в отговор му рече: Нали се очистиха десетимата? А где са деветимата?
Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
18 Не намериха ли се други да се върнат и въздадат слава на Бога, освен тоя иноплеменник?
A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
19 И рече му: Стани и си иди; твоята вяра те изцели.
Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
20 А Исус, попитан от фарисеите, кога ще дойде Божието царство, в отговор им каза: Божието царство не иде така щото да се забелязва:
Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
21 нито ще рекат: Ето тук е! Или: Там е! Защото, ето Божието царство е всред вас.
Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
22 И рече на учениците: Ще дойдат дни, когато ще пожелаете да видите поне един от дните на Човешкия Син, и няма да видите.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
23 И като ви рекат: Ето, тук е! Да не отидете, нито да тичате подрие им.
Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
24 Защото, както светкавицата, когато блесне от единия край на хоризонта, свети до другия край на хоризонта, така ще бъде и Човешкият Син в Своя ден.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
25 Но първо Той трябва да пострада много и да бъде отхвърлен от това поколение.
Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
26 И както стана в Ноевите дни, така ще бъде и в дните на Човешкия Син;
“Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
27 ядяха, пиеха, женеха се и се омъжваха до деня, когато Ное влезе в ковчега, и дойде потопът ги погуби всички.
Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
28 Така също, както стана в Лотовите дни; ядяха, пиеха, купуваха, продаваха, садяха и градяха,
“Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
29 а в деня, когато Лот излезе от Содом, огън и сяра наваляха от небето и ги погубиха всички,
ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
30 подобно на това ще бъде и в деня, когато Човешкият Син ще се яви.
“Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
31 В оня ден, който се намери на къщния покрив, ако вещите му са в къщи, да не слиза да ги вземе; също и който е на нива, да не се връща назад.
Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
32 Помнете Лотовата жена!
Ẹ rántí aya Lọti.
33 Който иска да спечели живота(Или: Душата.) си, ще го изгуби; а който го изгуби, ще го опази.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
34 Казвам ви, в онази нощ двама ще бъдат на едно легло; единият ще се вземе, а другият ще се остави.
Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
35 Две жени ще мелят заедно; едната ще се вземе, а другата ще се остави.
Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
36 Двама ще бъдат на нива; единият ще се вземе, а другият ще се остави].
37 Отговарят му, казвайки: Къде, Господи? А Той им рече: Гдето е трупът, там ще се съберат и орлите.
Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”

< Лука 17 >